< 1 Samuel 14 >

1 Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
Na i tetahi o aua ra ka mea a Honatana, tama a Haora, ki te taitama e mau ana i ana patu, Haere mai, taua ka whiti atu ki nga hoia pupuri a nga Pirihitini i tawahi ra. Otiia kihai i korerotia e ia ki tona papa.
2 Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
A i tera pito o Kipea a Haora e noho ana i raro i tetahi pamekaranete i Mikirono: tata tonu ana tangata ki te ono nga rau;
3 lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
Me Ahia ano hoki, tama a Ahitupu, tuakana o Ikaporo, tama a Pinehaha, tama a Eri tohunga a Ihowa i Hiro, ko te kaikakahu ia o te epora. Na kihai te iwi i mohio kua riro a Honatana.
4 Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
Na, i waenga o nga whitinga i whai ai a Honatana kia whiti atu ki nga hoia pupuri a nga Pirihitini, tera tetahi pari kohatu i tetahi taha, he pari kohatu hoki i tetahi taha: ko te ingoa o tetahi ko Potete, ko te ingoa o tetahi ko Henehe.
5 Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
I te raki tetahi pari e tu ana, i te ritenga atu o Mikimaha; i te tonga tetahi, i te ritenga atu o Kipea.
6 Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
Na ka mea a Honatana ki te taitama e mau ana i ana patu, Haere mai, taua ka haere ki nga hoia o enei kokotikore: tera pea a Ihowa e mahi mo taua: kahore he aha ki a Ihowa kia riro ma te tokomaha, ma te tokoiti ranei e whakaora.
7 Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
Ano ra ko te kaimau o ana patu ki a ia, Meatia nga mea katoa e paingia ana e tou ngakau: anga atu, tenei ahau hei hoa mou, hei pera me ta tou ngakau e pai ai.
8 Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
Ano ra ko Honatana, Nana, me haere atu taua ki nga tangata ra, me whakaputa atu hoki ki a ratou.
9 Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
Ki te penei mai ta ratou ki a taua, Tu marie, kia tae atu ra ano matou ki a korua; na me tu taua i to taua turanga, e kore ano e piki ki a ratou.
10 Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
Engari ki te penei ta ratou ki, Piki ake ki a matou, ko reira taua piki atu ai; no te mea kua homai ratou e Ihowa ki o taua ringa: a ko tenei hei tohu ki a taua.
11 Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
Na ka puta raua tokorua ki nga hoia pupuri a nga Pirihitini: a ka mea nga Pirihitini, Nana, ko nga Hiperu e puta mai ana i roto i nga rua i piri ai ratou.
12 Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
Na ka oho nga hoia pupuri ki a Honatana raua ko tana kaimau patu, ka mea, Piki ake ki a matou kia whakakitea ai tetahi mea e matou ki a korua. Na ka mea a Honatana ki te kaimau o ana patu, Piki ake i muri i ahau; kua homai hoki ratou e Ihowa ki te ringa o Iharaira.
13 Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Na ka piki atu a Honatana, he mea ngoki atu, me tana kaimau patu i muri i a ia: na hinga ana ratou i a Honatana, me te patu ano te kaimau patu i muri i a ia.
14 Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
Na, ko te patunga tuatahi i patu ai a Honatana raua ko tana kaimau patu, tata tonu ki te rua tekau nga tangata: ko te nui o taua wahi, me te mea kei te hawhe eka whenua.
15 Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
Na ka pa te wiri ki te puni, ki era i te parae, ki te iwi katoa ano hoki: ko nga hoia, me nga kaipahua, i wiri ano hoki ratou; i ru ano te whenua: nui rawa te wiri.
16 Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
A ka titiro nga tutei a Haora i Kipea o Pineamine; na, kua papahoro te ope, me te haere ano ratou, kopiko atu, kopiko mai.
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
Katahi a Haora ka mea ki te iwi i reira, i a ia, Tatauria tatou kia kitea ko wai kua riro. A, no ka tatauria e ratou, na kahore a Honatana raua ko tana kaimau patu i reira.
18 Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
Na ka mea a Haora ki a Ahia, Kawea mai te aaka a te Atua. I nga tama hoki a Iharaira te aaka a te Atua i taua wa.
19 Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
A, i a Haora e korero ana ki te tohunga, ka tino nui haere te ngangau i te puni o nga Pirihitini: na ka ki a Haora ki te tohunga, Pepeke ake tou ringa.
20 Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
Na ka huihui a Haora ratou ko tona nuinga, a haere ana ki te whawhai: na e anga mai ana tera te hoari a tetahi, a tetahi, ki tona hoa, ki tona hoa: nui atu te pokaikaha.
21 Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
Na ko nga Hiperu i roto i nga Pirihitini i mua atu, i haere tahi atu nei me ratou ki te puni i te whenua i tetahi taha, i tetahi taha; na huri ana ano hoki ratou ki te taha i a Iharaira, ki nga hoa o Haora raua ko Honatana.
22 Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
Na pera ano nga tangata katoa o Iharaira i piri nei ki te whenua pukepuke o Eparaima, i to ratou rongonga kua whati nga Pirihitini, na kei te whai haere ano hoki i a ratou i roto i te pakanga.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
Heoi whakaorangia ana a Iharaira, i taua ra e Ihowa: a puta ke ana te whawhai ki Peteawene.
24 Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
A i hemanawa nga tangata o Iharaira i taua ra: i whakaoati hoki a Haora i te iwi, i mea, Ki te kai tetahi tangata i te kai a ahiahi noa, ka kanga ia, kia whai utu ra ano ahau i oku hoariri. Na reira kihai tetahi o te iwi i anga ki te kai.
25 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
Na ko te haerenga o nga tangata katoa o te whenua ki tetahi ngahere; a he honi kei runga i te whenua.
26 Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
A, no te taenga o te iwi ki te ngahere, na e turuturu iho ana te honi; otiia kihai i pa te ringa o tetahi tangata ki tona waha; i wehi hoki te iwi i te oati.
27 Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
Ko Honatana ia kihai i rongo i te whakaoati a tona papa i te iwi: na ka kokiritia e ia te pito o te tokotoko i tona ringa, a toua ana ki roto ki te honikoma, whakahokia ana e ia tona ringa ki tona waha, a ka marama ona kanohi.
28 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
Katahi ka oho tetahi o te iwi, a ka mea, I tino whakaoatitia te iwi e tou papa; i mea ia, Kia kanga te tangata e kai ana i tetahi kai aianei; a e hemo ana te iwi.
29 Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
Katahi a Honatana ka mea, Raru ana te whenua nei i toku papa: titiro hoki, kua marama oku kanohi, noku i kai i tetahi wahi iti o te honi nei.
30 Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
Tera noa ake mehemea pea i kai noa atu te iwi inaianei i nga mea i pahuatia mai i o ratou hoariri i tupono atu ai ratou? ko tenei kahore i rahi te parekura o nga Pirihitini.
31 Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
Na patua iho e ratou nga Pirihitini i taua rangi i Mikimaha atu a tae noa ki Aitarono: a e tino hemo ana te iwi.
32 Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
Na ko te rerenga atu o te iwi ki nga taonga; ka mau ki nga hipi, ki nga kau, ki nga kuao kau, patua iho ki te whenua, kainga tahitia ana e te iwi me nga toto.
33 Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
Katahi ka korerotia ki a Haora ka meatia, Nana, kua hara te iwi ki a Ihowa, e kainga tahitia ana ta ratou kai me nga toto. Na ka mea ia, He mahi hianga ta koutou: hurihia mai he kohatu nui ki ahau aianei.
34 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
Ka mea ano a Haora, Tomotomo atu koutou ki roto ki te iwi mea atu hoki ki a ratou, Kawea mai ki ahau, e tera, e tera, tana kau, tana hipi, ka patu ai ki konei hei kai ma koutou; kaua hoki e hara ki a Ihowa, e kai i te toto. Katahi ka kawea mai e te iwi katoa i taua po te kau a tena, a tena, a patua iho ana ki reira.
35 Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
Na ka hanga e Haora he aata ma Ihowa. Koia tenei ko te aata tuatahi i hanga e ia ma Ihowa.
36 Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
Na ka mea a Haora, Tatou ka haere ki raro, ka whai i nga Pirihitini i te po, ka pahua i a ratou a marama noa te ata; kaua ano e waiho tetahi tangata o ratou. Na ka mea ratou, Meatia ra nga mea katoa e pai ana ki tou whakaaro. Na ka mea ake te to hunga, Kia whakatata tatou ki a Ihowa.
37 Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
Na ka tono whakaaro a Haora i te Atua, Me haere ranei ahau ki raro, ki te whai i nga Pirihitini? e homai ranei ratou e koe ki te ringa o Iharaira? Otiia kahore he kupu i whakahokia ki a ia i taua ra.
38 Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
Na ka mea a Haora, Neke mai, e nga rangatira katoa o te iwi: kia mohio ai, kia kite ai koutou no hea tenei hara i tenei ra.
39 Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
Ta te mea, e ora ana a Ihowa e whakaora nei i a Iharaira, ahakoa no taku tama, no Honatana, ka mate ia, mate rawa. Otiia kahore he tangata o te iwi katoa hei whakahoki kupu ki a ia.
40 Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
Katahi ia ka mea ki a Iharaira katoa, Hei tetahi taha koutou, hei tetahi taha maua ko taku tama, ko Honatana. Na ka mea te iwi ki a Haora, Meatia ra te mea e pai ana ki tou whakaaro.
41 Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
Katahi a Haora ka mea ki a Ihowa, ki te Atua o Iharaira, Kia tika te homaitanga o te rota. Na ka mau ko Honatana raua ko Haora; i mawhiti hoki te iwi.
42 Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
Na ka mea a Haora, maka te rota mo maua ko taku tama, ko Honatana. Na ka mau ko Honatana.
43 Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
Katahi ka mea a Haora ki a Honatana, Whakaaturia mai ki ahau, i aha koe. Katahi ka whakaaturia e Honatana ki a ia, ka mea, He tika i whakamatau kau atu ahau i tetahi wahi iti o te honi ki te pito o te tokotoko i toku ringa; na, ka mate nei ahau.
44 Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
Ano ra ko Haora, Kia meatia tenei e te Atua, tera atu ano hoki; ka mate rawa hoki koe, e Honatana.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
Na ka mea te iwi ki a Haora, Kia mate a Honatana nana nei tenei whakaoranga nui i roto i a Iharaira? Kahore ra hoki. E ora ana a Ihowa, e kore e taka tetahi makawe o tona matenga ki te whenua; i te mahi tahi nei hoki ia me te Atua i tenei ra. He oi whakaorangia ana a Honatana e te iwi, a kihai i mate.
46 Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
Katahi ka hoki a Haora i te whai i nga Pirihitini; a haere ana nga Pirihitini ki to ratou na wahi.
47 Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
A, no ka riro i a Haora te kingitanga o Iharaira, ka whawhai ia ki ona hoariri katoa i tetahi taha, i tetahi taha, ki a Moapa, ki nga tama a Amona, ki a Eroma, ki nga kingi ano o Topa, ki nga Pirihitini, a he ana ratou i a ia i nga wahi katoa i tahuri ai ia.
48 Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
A i puta tona toa, a patua ana nga Amareki, a ora ake i a ia a Iharaira i te ringa o ona kaipahua.
49 Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
Na ko nga tama a Haora, ko Honatana, ko Ihui, ko Marikihua; a, ko nga ingoa enei o ana tamahine tokorua, ko te ingoa o te matamua ko Merapa, ko te ingoa o to muri ko Mikara.
50 Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
A, ko te ingoa o te wahine a Haora ko Ahinoama, he tamahine na Ahimaata: ko te ingoa hoki o te rangatira o tana ope ko Apanere, tama a Nere matua keke o Haora.
51 Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
Ko Kihi hoki te papa o Haora; a he tama na Apiere a Nere papa o Apanere.
52 Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.
A he nui te whawhai ki nga Pirihitini i nga ra katoa o Haora; a ka kite a Haora i tetahi marohirohi, i tetahi maia, na ka tangohia e ia mana.

< 1 Samuel 14 >