< 1 Samuel 14 >

1 Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
Aa teo ty andro te nanao ty hoe amy mpinday fikala’ey t’Io­natane ana’ i Saole: Antao hitsake mb’ ampirai-lia’ o nte-Pilisty an-kalo’ o e hoekeo mb’eo. F’ie tsy nampandrendrek’ an-drae’e.
2 Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
Nihene­kenek’ añ’ ila’ i Gibeà añe t’i Saole ambane’ i ampongabendañitse e Mig­roney; va’e enen-jato t’indaty nirekets’ ama’e
3 lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
naho i Ahiià, ana’ i Ahitobe, rahalahi’ Ikabode, Ana’ i Pinekase, ana’i Elý mpisoro’ Iehovà e Silò ao, nisikiñe i kitambey. Le tsy napota’ ondatio te tsy teo t’Ionatane.
4 Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
Añivo’ i hebam-bohitse nipaia’ Ionatane hitsahañe mb’ amy firimboñam-Pilistiy mb’eoy ty tevañe vatoeñe añ’ ila’e raike naho ty tevam-bato añ’ila’e ka; i Bozeze ty añara’ ty raike, naho Seneke ty añara’ ty raike.
5 Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
Nionjoñ’ añ’ila’e avaratse tandrife i Mikmase ty tevañe raike naho atimo tandrife i Geba ty ila’e.
6 Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
Le hoe t’Ionatane amy ajalahy ninday o fikala’eoy: Antao, hitsake mb’ amy mpirai-lia’ o tsy sinavatseoy hera hañolotse antika t’Iehovà amy te tsy sebañeñe t’Iehovà handrombake he ami’ty maro ke ami’ty tsy ampe.
7 Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
Le hoe i mpinday fikala’ey: Anò iaby ze añ’arofo’o; mitoliha, hehe te ama’o iraho, ndra ino ty satrin’ arofo’o.
8 Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
Aa le hoe t’Ionatane, Inao! hitsake mb’ am’ ondaty reo tika, hiatreatre iareo.
9 Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
Aa naho anoe’ iareo ty hoe, Ey avao ampara’ te pok’ ama’ areo eo zahay; le hijohañe eo avao tika, fa tsy hiañambone mb’ ama’e.
10 Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
F’ie manao ty hoe: Mionjona mb’ ama’ay mb’atoy. Le hionjomb’eo tika, fa tinolo’ Iehovà an-tañan-tika; izay ty ho viloñe aman-tika.
11 Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
Le nivotrak’ amy mpirai-liam-Pilistiy, iereo roe; le hoe ty asa’ o nte-Pilistio: Hehe te mipororoake boak’ an-koboñe fipalira’e ao o nte-Evreo.
12 Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
Aa le hoe ty asa’ ondati’ i mpirai-liaio am’ Ionatane naho i mpitàm-pikala’ey: Mionjona mb’ ama’ay mb’etoa, hanoroa’ay raha. Aa le hoe t’Ionatane amy mpitàm-pikala’ey, Oriho iraho te hionjoñe; fa natolo’ Iehovà am-pità’ Israele iereo.
13 Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Aa le nanganike mb’eo am-pitàñe naho am-pandia t’Ionatane, le nañorike aze i mpinday fikala’ey; vaho nikorovoke aolo’ Ionatane iereo; le namono am-boho’e eo i mpinday fikala’ey.
14 Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
Va’e roapolo ty zinama’ Ionatane naho i mpitàm-pikala’ey amy valoha’e zay, an-tampan-tonda mete ho folahe’ ty katràka roe an-dasarý.
15 Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
Inay ty fihondrahondràñe an-tobe ao naho an-kivoke ey, naho am’ ondaty iabio; i mpirai-liay naho o mpijoio songa nititititike vaho nanginikinike i taney; aa le nionjo ho firevendreveñañe aman’ Añahare.
16 Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
Tinalake’ o mpijilo’ i Saole e Gibeate-Beniamineo; le hehe te nitranak’ añe i valobohòkey nifanjevoñe avao.
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
Le hoe t’i Saole am’ondaty nirekets’ ama’eo: Volilio henaneo, haharendreke te ia ty nienga antika. Aa ie namolily, inao tsy eo t’Ionatane naho i mpinday fikala’ey.
18 Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
Aa le hoe t’i Saole amy Akià: Endeso mb’etoa ty vatam-pañinan’ Añahare. Amy te tamo ana’ Israeleo i vatam-pañinan’ Añaharey henane zay.
19 Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
Ie amy zao, naho nisaontsy amy mpisoroñey t’i Saole le nitolom-pivalitaboak’ an-tobe’e ao avao o nte-Pilistio vaho niindra; le nanao ty hoe amy mpisoroñey t’i Saole. Ahankaño o fità’oo.
20 Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
Nifanontoñe eo rekets’ i valobohò’ey t’i Saole naho nionjom-ban-kotakotake mb’eo vaho nizoeñe te songa nifanjamañe am-pibara o mpirañetseo, nifamalitsikotake.
21 Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
Ie amy zao nitolike hirekets’ amo ana’ Israele mpiamy Saole naho Ionataneo o nte-Evre niharo amo nte-Pilisty nimpindre fionjo ama’e mb’an-tobe ao boak’ am-pariparitse añe taoloo.
22 Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
Hambañe amy zay, o hene ondati’ Israele nietak’ am-bohibohi’ i Efraimeo; ie nahajanjiñe te nivoratsake mb’eo o nte-Pilistio, le nihoridà’ iareo fatratse am-pifandraparapahañe.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
Aa le rinomba’ Iehovà t’Israele amy andro zay, vaho nivelatse pak’ e Bete-avene i hotakotakey.
24 Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
Toe ni-ampoheke ondati’ Israeleo amy andro zay; ty amy fetse natao’ i Saole am’ondatio an-titike ty hoe: Fàtse t’indaty mikama ze atao haneñe am-para’ te hariva, hañondrohako an-drafelahiko ty avake. Aa le tsy eo ty nitsopeke mahakama.
25 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
Hene nitandroake mb’amy alay o an-tane eio, ie an-tane eo ty tantele.
26 Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
Naho nizilik’ amy alay ondatio, hehe te nitsopetsopehen-tanteley, fa leo raik’ am’ondatio tsy nanao fitàñe am-palie amy fihembaña’ iareo i fetseiy.
27 Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
Fe tsy napota’ Ionatane i fantok’ am-pàtse nanoen-drae’e am’ondatio; aa le natoho’e mb’eo ty kobay am-pità’e naho najo’e amy papi-tanteley, naho nanoe’e am-palie i fità’ey, vaho nahiratse o fihaino’eo.
28 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
Aa le hoe ty asa’ ty raik’ am’ ondatio: Fa nafanton-drae’o am-pànta te: Fàtse ze ondaty mitsopeke mahakama anito; fe midazidazìtse ondatio.
29 Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
Le hoe t’Ionatane: Nanolo-tsotry amo taneo ty raeko: Hehe fa mahiratse o masokoo, ie nitsopeke amo tanteleo,
30 Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
antsake te songa nidada am-pikamañe o raha kinopake nitendrek’ amo rafelahi’eoo ondatio. Tsy ho nimaro hao ty nizamañe amo nte-Pilistio?
31 Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
Aa le linafa’ iareo o nte-Pilistio boake Mikmase pak’ Aialone añe; fe toe nikolempa ondatio.
32 Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
Niam­botrak’ amy kinopakey ondatio, nandrambe añondry naho añombe naho sarake, naho linenta’ iareo an-tane, vaho nikama’ ondatio ie mbe aman-dio.
33 Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
Aa le natalily amy Saole, ty hoe: Inao! manao hakeo am’ Iehovà ondatio, mikama reke-dio. Le hoe re: Nandilatse nahareo: Amariño vato jabajaba amako aniany.
34 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
Le hoe t’i Saole: Tsitsiho ondatio le anò ty hoe: Songa mindesa vosy mb’ amako mb’etoa ondatio, sindre mindesa ty añondri’e ho lentaeñe etoa vaho ho kamae’e fa ko manao hakeo am’ Iehovà am-pikamàñ’ aze aman-dio. Aa le fonga ninday ty añombe’e mb’eo ondatio vaho nandenta aze eo.
35 Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
Le namboatse kitrely am’Iehovà t’i Saole, toe ie ty kitrely valoha’e niranjie’e am’Iehovà.
36 Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
Le hoe t’i Saole: Antao hizotso mb’ amo nte-Pilistio mb’eo haleñe hikopake ampara’ te porea’ ty maraindray, vaho tsy hapon-tika leo raik’ am’ondati’eo. Le hoe iereo: Ano ze satri’ ty arofo’o. Fa hoe i mpisoroñey, antao hey hañarine aman’ Añahare.
37 Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
Aa le nihalaly fanoroañe aman’ Añahare t’i Saole: Hizotso mb’ amo nte-Pilistio hao iraho? Hatolo’o am-pità’ Israele hao? Fe tsy natoi’e amy andro zay.
38 Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
Le hoe t’i Saole: Miharinea iaby ry mpiaolo’ ondatio; itsikaraho ty nametsahañe i hakeo anindroaniy.
39 Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
Aa kanao veloñe t’Iehovà mpandrombake Israele, ndra t’ie am’ Ionatane ana-dahikoy, le toe havetrake. Fe leo raik’ am’ ondaty iabio tsy nanoiñe.
40 Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
Aa le hoe re amy Israele iaby: Añ’ila’e nahareo, vaho añ’ ila’e atoy iraho naho Ionatane anakoy. Le hoe ondatio amy Saole: Ano ze atao’o ho soa.
41 Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
Le hoe t’i Saole amy Iehovà Andrianañahare’ Israele: Taroño ty hato. Jinoboñe an-kitsapak’ amy zao t’Ionatane naho i Saole; le nivo­tsotse i màroy.
42 Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
Aa hoe t’i Saole: Ano an-tsapake ka, izaho naho Ionatane anako. Nivoa t’Ionatane.
43 Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
Aa hoe t’i Saole am’ Ionatane: Atalilio ahiko o nanoe’oo. Le natalili’ Ionatane ama’e ty hoe: Toe nitsopeke tantele tsy ampe añ’ ilan-kobaiko an-tañako; intoy, izaho ty hikenkañe.
44 Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
Le hoe t’i Saole: Ehe hanoan’ Añahare amako naho mandikoatse izay naho tsy hihomake irehe Ionatane.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
Fe hoe ondatio amy Saole: Havetrake hao t’Ionatane, ie nañeneke fandrombahañe jabajaba e Israele atoa? Lavits’ aze izay; Kanao veloñe t’Iehovà, leo raik’ amo maròy añ’ambone’eo tsy hihintsañe an-tane; amy t’ie nitoloñe an’ Andrianañahare anindroany. Aa le navotso’ ondati­reo t’Ionatane tsy hihomake,
46 Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
le nienga tsy nañorike o nte-Pilistio ka t’i Saole; vaho nimpoly mb’an-toe’e mb’eo o nte-Pilistio.
47 Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
Aa le rinambe i Saole ty fifeheañe Israele, naho nialia’e iaby mb’atia mb’eroa o rafelahi’eo; e Moabe naho amo ana’ i Amoneo, Edome naho amo mpanjaka’ i Tsobao, vaho amo nte-Pilistio; aa ndra aia ty nitoliha’e le nampisotrie’e.
48 Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
Nanontoñe lahialen-dre le zinevo’e o nte Amalekeo vaho navotso’e am-pità’ o mpikopake iareoo t’Israele.
49 Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
Zao o ana-dahi’ i Saoleo, Ionatane, naho Isvý vaho i Malki-soà; le ty añara’ ty anak’ ampela’e roe: i Merabe ty zoke’e, naho Mikale ty zai’e;
50 Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
naho ty tahinan-tañanjomba’ i Saole: i Akinoame, ana’ i Akimàtse; ty tahina’ i mpifeleke i valobohò’eiy: i Abnere, ana’ i Nere, anan-drahalahin-drae’ i Saole.
51 Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
I Kise ty rae’i Saole; vaho ana’ i Abiele t’i Nere rae’ i Abnere.
52 Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.
Nitolom-pialy amo nte-Pilistio nainai’e t’i Saole amo hene andro’eo, aa ndra mb’ia nahaisake fanalolahy t’i Saole, le rinambe’e ho ama’e.

< 1 Samuel 14 >