< 1 Samuel 14 >

1 Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
A I kekahi la, olelo aku la o Ionatana ke keiki a Saula ike kanaka ui, nana i hali kana mea kaua, Ea, e hele kaua i ka pakaua o ko Pilisetia ma kela aoao. Aka, aole ia i hai aku i kona makuakane.
2 Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
Noho iho la o Saula ma ka aoao mamao loa o Gibea, malalo o ka laau pomegerane ma Migerona: a o na Kanaka me ia, aono paha haneri lakou;
3 lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
A o Ahia, ke keiki a Ahituba, a ke kaikuaana o Ikaboda, ke keiki a Pinehasa, ke keiki a Eli, ke kahuna a Iehova ma Silo, ua hookomoia ka epoda. Aole i ike na kanaka, ua hala o Ionatana.
4 Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
A ma ke ala a Ionatana i imi ai e hele i ka poe koa o ko Pilisetia, he pohaku oi ma keia aoao, a he pohaku oi ma kela aoao: o Bozeza ka inoa o kekahi, a o Sene ka inoa o kekahi.
5 Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
A o ka mea oi o kekahi, ua kiekie ia ma ke kukuluakau e ku pono ana i Mikemasa, a o kekahi ma ke kukuluhema e ku pono ana i Gibea.
6 Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
Olelo aku la o Ionatana i ke kanaka ui, nana i hali kana mea kaua, Ea, e hele kaua i kahi paa o ua poe la i okipoepoe ole ia: e hana mai paha o Iehova no kaua; no ka mea, aohe mea keakea ia Iehova, ke hoola ma ka poe nui, a ma ka poe uuku.
7 Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
I mai la ka mea nana i hali kana mea kaua ia ia, E hana oe i ka mea a pau maloko o kou naau: o hele; aia hoi, owau pu kekahi me oe e like me kou manao.
8 Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
Olelo aku la o Ionatana, Aia hoi, e hele kaua i ua poe kanaka la, a e hoike ia kaua iho ia lakou.
9 Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
Ina e olelo mai lakou ia kaua peneia, E noho malie olua a hiki aku makou io olua la; alaila ku malie kaua ma ko kaua wahi, aole e pii aku io lakou la.
10 Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
Aka, i olelo mai lakou ia kaua peneia, E pii mai olua io makou nei; alaila e pii aku kaua: no ka mea, ua hoolilo mai o Iehova ia lakou i ko kaua lima; a oia ka hoailona no kaua.
11 Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
Hoike aku la laua ia laua iho i ka poe koa o ko Pilisetia: i ae la ko Pilisetia, E nana i ka poe Hebera e hele mai ana mailoko mai o na lua a lakou i pee ai.
12 Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
Olelo mai la na kanaka o ka poe koa ia Ionatana, a me ka mea nana i hali kana mea kaua, i mai la, E pii mai olua io makou nei, a e hoike aku makou ia olua i kekahi mea. I aku la Ionatana i ka mea nana i hali kana mea kaua, E pii mai oe mahope o'u; no ka mea, ua hoolilo mai o Iehova ia lakou iloko o ka lima o ka Iseraela.
13 Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Pii ae la o Ionatana ma kona lima, a ma kona wawae, a o ka mea nana i hali kana mea kaua mahope ona: a haule lakou imua o Ionatana; a o ka mea nana i hali kana mea kaua pepehi aku la ia mahope ona.
14 Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
A o ka pepehi mua ana a Ionatana a me ka mea nana i hali kana mea kaua, he iwakalua paha kanaka ia, ma kahi kokoke, e like paha me ka hapalua o ka eka aina hookahi.
15 Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
He haalulu iwaena o ka poe koa ma ke kula, a iwaena o na kanaka a pau; a o ka poe kaua, a o ka poe luku, haalulu iho la lakou, nauwe ka aina; a he haalulu nui.
16 Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
Nana aku la ka poe kiai o Saula ma Gibea o Beniamina; aia hoi, ua hee aku la ka poe nui, a holo lakou, a hele liilii aku.
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
Olelo aku la o Saula i na kanaka me ia, E helu ano, i ike kakou i ka mea i hele ae mai o kakou aku. Helu aku la lakou, aia hoi, aole o Ionatana, a me ka mea nana i hali kana mea kaua.
18 Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
I aku la o Saula ia Ahia, E lawe mai maanei i ka pahu o ke Akua: no ka mea, i kela manawa, aia no ka pahu o ke Akua me na mamo a Iseraela.
19 Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
A ia Saula i kamailio ai me ke kahuna, ua nui loa ka haunaele iwaena o ka poe koa o ko Pilisetia; i aku la o Saula i ke kahuna, E hoi hou mai i kou lima.
20 Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
Houluuluia'e la o Saula me na kanaka a pau me ia, a hele aku i ke kaua: aia hoi, ua ku e ka pahikaua a kela kanaka keia kanaka i kona hoa, a ua nui loa ka pioloke.
21 Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
A o ka poe Hebera i noho ai me ko Pilisetia mamua, a i hele pu ai me lakou i kahi hoomoana'i, mai kela wahi keia wahi, o lakou kekahi i hui pu ai me ka Iseraela me Saula a me Ionatana.
22 Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
A o na kanaka a pau o ka Iseraela i pee ai ma ka mauna o Eperaima, ia lakou i lohe ai, ua holo ko Pilisetia, o lakou no hoi kekahi i hahai mahope o lakou i ke kaua.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
A hoopakele mai o Iehova i ka Iseraela ia la: a hele aku la ke kaua ma Betavena.
24 Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
A ua pilikia na kanaka o ka Iseraela ia la: no ka mea, ua hoohiki aku o Saula i na kauaka, i aku la, Poino ke kanaka, ke ai ia i ka ai a hiki i ke ahiahi, i hoopai aku ai au i ko'u poe enemi. Nolaila, aole i ai na kanaka i ka ai.
25 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
A hele na kanaka a pau ma ka ululaau; a he meli maluna o ka aina.
26 Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
A hiki na kanaka ma ka ululaau, aia hoi, e kahe ana o ka meli, aole ka lima o kekahi kanaka i hoopa aku i kona waha: no ka mea, makau na kanaka i ka hoohiki ana.
27 Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
Aka, aole i lohe o Ionatana i ke kauoha a kona makuakane i na kanaka i ka hoohiki ana; nolaila, o aku la ia i ke kookoo ma kona lima, a hou iho la iloko o ka waihona meli, a hoopa kona lima i kona waha, a hoomalamalamaia kona mau maka.
28 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
Alaila, olelo mai la kekahi o na kanaka, i mai la, Ua kauoha ikaika mai kou makuakane i na kanaka me ka hoohiki, i mai la, Poino ke kanaka, ke ai i ka ai i keia la. A ua nawaliwali na kanaka.
29 Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
Olelo aku la o Ionatana, i aku la, Ua hoopilikia ko'u makuakane i ka aina: ke noi aku nei au ia oukou, e nana, ua hoomalamalamaia ko'u mau maka, no kuu hoao ana i kauwahi uuku o keia meli.
30 Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
Aole anei he nui aku, ina paha ua ai nui na kanaka i keia la i ka mea o ko lakou poe enemi i loaa ai ia lakou? Aole anei he nui aku ka luku iwaena o ko Pilisetia?
31 Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
A luku aku la lakou i ko Pilisetia ia la, mai Mikemasa a hiki i Aialona: a ua nawaliwali loa na kanaka.
32 Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
Lalau aku la na kanaka i ka waiwai pio, a lawe i na hipa, a me na bipi, a me na bipikeiki, a pepehi iho la ma ka aina; a ai iho la na kanaka me ke koko.
33 Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
Hai aku la lakou ia Saula, i aku la, Aia hoi, ke hana hewa nei na kanaka ia Iehova, i ka lakou ai ana me ke koko. I mai la kela, Ua hana pono ole oukou: e olokaa mai i pohaku nui io'u nei i keia la.
34 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
Olelo aku la o Saula, E hele oukou iwaena o na kanaka, e i aku ia lakou, E lawe mai io'u nei kela kanaka keia kanaka i kana bipi a me kana hipa, a e pepehi maanei, a ai iho; a mai hana hewa ia Iehova i ka ai ana me ke koko. A lawe mai la na kanaka a pau, o kela kanaka keia kanaka i kana bipi, me ia ia po, a pepehi iho la malaila.
35 Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
Hana aku la o Saula i kuahu no Iehova, oia ke kuahu ana i hoomaka ai e hana no Iehova.
36 Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
I aku la o Saula, E hahai aku kakou i ko Pilisetia i ka po, a e luku aku ia lakou a hiki i ka malamalama o ke ao, a mai waiho kakou i kekahi kauaka o lakou. I mai la lakou, E hana oe i ka mea pono i kou maka. I mai la ke kahuna, E hookoke mai nei kakou i ke Akua.
37 Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
Ninau aku la o Saula i ke Akua, E hahai aku anei au i ko Pilisetia? e hoolilo mai anei oe ia lakou i ka lima o ka Iseraela? Aka, aole ia i olelo mai ia ia ia la.
38 Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
Olelo aku la o Saula, E hookokoke mai oukou ia nei, e na alakai o na kanaka; i ike pono kakou i ka mea o keia hewa i keia la.
39 Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
No ka mea, ma ke ola o Iehova nana i hoola i ka Iseraela, ina paha iloko o Ionatana ka'u keiki keia mea, e make io no ia. Aole kekahi kanaka iwaena o ka Iseraela i olelo mai ia ia.
40 Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
Olelo aku la ia i ka Iseraela a pau, O oukou ma kekahi aoao, a owau a me Ionatana kuu keiki, ma kekahi aoao. I mai la na kanaka ia Saula, E hana oe i ka mea pono i kou maka.
41 Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
Olelo aku la o Saula ia Iehova ke Akua o ka Iseraela, E hoike mai i ka oiaio. A ua laweia o Saula a me Ionatana: a pakele na kanaka.
42 Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
I aku la o Saula, E hailona iwaena o maua a me Ionatana kuu keiki. A ua laweia o Ionatana.
43 Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
Alaila i aku la o Saula ia Ionatana, E hai mai oe ia'u i kau mea i hana'i. Hai aku la o Ionatana, i aku la, Ua hoao iho au i kahi meli uuku wale no me ke kookoo ma kuu lima, aia hoi, e make ana au.
44 Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
I aku la o Saula, Pela ke Akua e hana mai ai, pela io hoi, no ka mea, e make io no oe, e Ionatana.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
Olelo mai la na kanaka ia Saula, E make anei o Ionatana, nana i hana keia ola nui iwaena o ka Iseraela? Aole loa, ma ke ola o Iehova, aole e haule iho ma ka honua kekahi lauoho o kona poo; no ka mea, ua hana pu aku ia me ke Akua i keia la. A hoopakele aku la na kanaka ia Ionatana, aole ia i make.
46 Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
Haalele aku la o Saula i ka hahai ana i ko Pilisetia: a hoi aku la ko Pilisetia i ko lakou wahi.
47 Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
A lawe ae la o Saula i ke aupuni o ka Iseraela, a kana aku la i kona poe enemi a pau, ma na aoao a pau i ko Moaba, a me na mamo a Amona, a me ka Edoma, a me na'lii o Zoba, a me ko Pilisetia, a ma na wahi a pau ana i huli ae, ua lanakila ia.
48 Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
Hana ikaika aku la ia, a luku aku la i ka Ameleka, a hoopakele i ka Iseraela i ka lima o ka poe i luku mai ia lakou.
49 Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
Eia na keiki a Saula, o Ionatana, o Isui a me Melekisua: a o ka inoa o kana mau kaikamahine elua, o Meraba ka inoa o ke kaikuaana, a o Mikala ka inoa o ke kaikaina.
50 Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
A o Ahinoama ka inoa o ka wahine a Saula, ke kaikamahine a Ahimaaza; a o ka inoa o kona alihikaua, o Abenera, ke keiki a Nera, kahi makua o Saula.
51 Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
A o Kisa ka makuakane o Saula: a o Nera ka makuakane o Abenera, ke keiki a Abiela.
52 Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.
A ua nui ke kaua ana i ko Pilisetia i na la a pau o Saula: a ike aku la o Saula i ke kanaka ikaika, a i ke kanaka koaka, lawe aku la kela ia ia nona.

< 1 Samuel 14 >