< 1 Samuel 14 >

1 Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
Un jour, Jonathan, fils de Saül, dit au jeune homme qui portait son armure: « Viens! Allons vers la garnison des Philistins qui est de l'autre côté. » Mais il ne le dit pas à son père.
2 Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
Saül resta à l'extrémité de Guibea, sous le grenadier qui est à Migron, et le peuple qui était avec lui était d'environ six cents hommes,
3 lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
dont Achija, fils d'Achitub, frère d'Ichabod, fils de Phinées, fils d'Eli, prêtre de Yahvé à Silo, portant un éphod. Le peuple ne savait pas que Jonathan était parti.
4 Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
Entre les cols par lesquels Jonathan cherchait à passer à la garnison des Philistins, il y avait un rocher d'un côté et un rocher de l'autre côté; le nom de l'un était Bozez, et le nom de l'autre Seneh.
5 Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
L'un des rochers s'élevait au nord, en face de Michmash, et l'autre au sud, en face de Guéba.
6 Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
Jonathan dit au jeune homme qui portait son armure: « Viens! Allons voir la garnison de ces incirconcis. Il se peut que Yahvé travaille pour nous, car rien n'empêche Yahvé de sauver par beaucoup ou par peu. »
7 Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
Le porteur de l'armure lui dit: « Fais tout ce que tu as dans le cœur. Va, et voici, je suis avec toi selon ton cœur. »
8 Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
Jonathan dit alors: « Voici, nous allons passer devant les hommes et nous nous montrerons à eux.
9 Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
S'ils nous disent: « Attendez que nous venions à vous », nous resterons à notre place et nous ne monterons pas vers eux.
10 Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
Mais s'ils nous disent: « Montez vers nous », nous monterons, car l'Éternel les a livrés entre nos mains. Ce sera pour nous un signe. »
11 Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
Tous deux se révélèrent à la garnison des Philistins, et les Philistins dirent: « Voici les Hébreux qui sortent des trous où ils s'étaient cachés! »
12 Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
Les hommes de la garnison répondirent à Jonathan et à son porteur d'armure en disant: « Venez vers nous, nous allons vous montrer quelque chose! ». Jonathan dit à son porteur d'armes: « Monte après moi, car l'Éternel les a livrés entre les mains d'Israël. »
13 Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Jonathan monta sur ses mains et sur ses pieds, et le porteur de ses armes le suivit; ils tombèrent devant Jonathan, et le porteur de ses armes les tua après lui.
14 Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
Cette première tuerie, que Jonathan et le porteur de ses armes firent, concernait environ vingt hommes, soit la moitié de la longueur d'un sillon dans un acre de terre.
15 Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
Il y eut un tremblement dans le camp, dans les champs et parmi tout le peuple; la garnison et les pillards tremblèrent aussi; la terre trembla, et il y eut un très grand tremblement.
16 Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
Les sentinelles de Saül, à Guibea de Benjamin, regardèrent; et voici que la foule se fondit et se dispersa.
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
Alors Saül dit au peuple qui était avec lui: « Comptez maintenant, et voyez qui manque parmi nous. » Quand ils eurent compté, voici que Jonathan et le porteur de son armure n'étaient pas là.
18 Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
Saül dit à Achija: « Amène ici l'arche de Dieu. » Car l'arche de Dieu était en ce temps-là avec les enfants d'Israël.
19 Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
Pendant que Saül parlait au prêtre, le tumulte qui régnait dans le camp des Philistins continuait et augmentait; Saül dit au prêtre: « Retire ta main! »
20 Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
Saül et tout le peuple qui était avec lui se rassemblèrent et vinrent au combat; et voici, ils se frappaient tous avec leurs épées dans une très grande confusion.
21 Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
Les Hébreux qui étaient auparavant avec les Philistins et qui étaient montés avec eux dans le camp de tous les côtés, se tournèrent aussi vers les Israélites qui étaient avec Saül et Jonathan.
22 Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
De même, tous les hommes d'Israël qui s'étaient cachés dans la montagne d'Ephraïm, ayant appris la fuite des Philistins, les suivirent de près dans la bataille.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
L'Éternel sauva Israël ce jour-là, et la bataille passa près de Beth Aven.
24 Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
Ce jour-là, les hommes d'Israël furent dans l'angoisse, car Saül avait adressé au peuple cette injonction: « Maudit soit l'homme qui mangera quelque chose jusqu'au soir, et je serai vengé de mes ennemis. » Ainsi, aucun des membres du peuple ne goûta de nourriture.
25 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
Tout le peuple entra dans la forêt; et il y avait du miel sur le sol.
26 Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
Quand le peuple fut arrivé dans la forêt, voici que du miel coulait, mais personne ne mit la main à sa bouche, car le peuple craignait le serment.
27 Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
Mais Jonathan n'entendit pas quand son père donna l'ordre au peuple de prêter serment. Il sortit donc l'extrémité de la verge qu'il tenait à la main, la trempa dans le rayon de miel et porta la main à sa bouche; et ses yeux s'illuminèrent.
28 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
Alors l'un des membres du peuple prit la parole et dit: « Ton père a donné un ordre direct au peuple, avec serment, en disant: « Maudit soit l'homme qui mange aujourd'hui. » Alors, le peuple s'évanouit.
29 Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
Jonathan dit alors: « Mon père a troublé le pays. Voyez comme mes yeux se sont éclaircis parce que j'ai goûté un peu de ce miel.
30 Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
Combien plus, si le peuple avait mangé aujourd'hui du butin de ses ennemis qu'il a trouvé? Car il n'y a pas eu de grand carnage chez les Philistins. »
31 Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
Ce jour-là, ils frappèrent les Philistins depuis Michmash jusqu'à Ajalon. Le peuple était très affaibli.
32 Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
Le peuple se jeta sur le butin, prit des moutons, des bœufs et des veaux, les tua à terre, et le peuple les mangea avec le sang.
33 Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
On en informa Saül, en disant: « Voici que le peuple pèche contre l'Éternel, en mangeant de la viande avec le sang. » Il a dit: « Tu as été déloyal. Fais-moi rouler une grosse pierre aujourd'hui! »
34 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
Saül dit: « Dispersez-vous parmi le peuple, et dites-leur: « Que chacun m'amène ici son bœuf et que chacun amène son mouton, que vous les tuiez ici, et que vous mangiez; et ne péchez pas contre Yahvé en mangeant de la viande avec le sang. » Tout le peuple amena chacun son bœuf cette nuit-là, et les tua là.
35 Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
Saül bâtit un autel à Yahvé. Ce fut le premier autel qu'il construisit à l'Éternel.
36 Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
Saül dit: « Descendons après les Philistins pendant la nuit, et faisons du pillage parmi eux jusqu'à la lumière du matin. Ne laissons pas un seul homme parmi eux. » Ils ont dit: « Fais ce qui te semble bon. » Alors le prêtre a dit: « Approchons-nous ici de Dieu. »
37 Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
Saül demanda conseil à Dieu: « Dois-je descendre après les Philistins? Les livreras-tu entre les mains d'Israël? » Mais il ne lui répondit pas ce jour-là.
38 Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
Saül dit: « Approchez ici, vous tous, chefs du peuple, et sachez et voyez en qui ce péché a été commis aujourd'hui.
39 Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
Car l'Éternel est vivant, lui qui sauve Israël, et si c'est en Jonathan, mon fils, qu'il a péché, il mourra. » Mais il n'y eut pas un homme parmi tout le peuple qui lui répondit.
40 Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
Alors il dit à tout Israël: « Vous serez d'un côté, et moi et Jonathan, mon fils, nous serons de l'autre côté. » Le peuple dit à Saul: « Fais ce qui te semble bon. »
41 Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
Saül dit à Yahvé, le Dieu d'Israël: « Montre la droite. » Jonathan et Saul ont été choisis, mais le peuple s'est échappé.
42 Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
Saül dit: « Jetez le sort entre moi et Jonathan, mon fils. » Jonathan a été sélectionné.
43 Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
Alors Saül dit à Jonathan: « Dis-moi ce que tu as fait! » Jonathan lui en fit part et dit: « J'ai certainement goûté un peu de miel avec le bout de la verge qui était dans ma main; et voici que je dois mourir. »
44 Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
Saül dit: « Que Dieu fasse ainsi et plus encore, car tu vas mourir, Jonathan. »
45 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
Le peuple dit à Saül: « Jonathan va-t-il mourir, lui qui a opéré ce grand salut en Israël? Loin de là! Yahvé est vivant, il ne tombera pas à terre un seul cheveu de sa tête, car il a travaillé avec Dieu aujourd'hui! ». Le peuple sauva donc Jonathan, et il ne mourut pas.
46 Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
Puis Saül cessa de suivre les Philistins, et les Philistins s'en allèrent chez eux.
47 Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
Lorsque Saül eut pris le pouvoir sur Israël, il combattit tous ses ennemis de toutes parts: contre Moab, contre les enfants d'Ammon, contre Édom, contre les rois de Tsoba et contre les Philistins. Partout où il se tournait, il les battait.
48 Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
Il fit preuve de vaillance, frappa les Amalécites et délivra Israël des mains de ceux qui le pillaient.
49 Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
Les fils de Saül étaient Jonathan, Ishvi et Malkishua; et les noms de ses deux filles étaient les suivants: le nom de l'aînée Merab, et le nom de la cadette Mical.
50 Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
Le nom de la femme de Saül était Ahinoam, fille d'Ahimaaz. Le nom du chef de son armée était Abner, fils de Ner, oncle de Saül.
51 Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
Kish était le père de Saül, et Ner, père d'Abner, était le fils d'Abiel.
52 Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.
Il y eut une guerre sévère contre les Philistins pendant toute la durée de Saül; et quand Saül voyait un homme fort ou un homme vaillant, il le prenait à son service.

< 1 Samuel 14 >