< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Och Samuel sade till hela Israel: "Se, jag har lyssnat till edra ord och gjort allt vad I haven begärt av mig; jag har satt en konung över eder.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
Nu är det eder konung som skall vara eder ledare, nu då jag är gammal och grå; I haven ju redan mina söner ibland eder. Hittills är det jag som har varit eder ledare, från min ungdom ända till denna dag.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Se har står jag, vittnen nu mot mig inför HERREN och inför hans smorde. Har jag tagit någons oxe, eller har jag tagit någons åsna? Har jag förtryckt någon eller övat våld mot någon? Har jag tagit mutor av någon, för att jag skulle se genom fingrarna med honom? Jag vill då giva eder ersättning därför."
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
De svarade: "Du har icke förtryckt oss, du har icke övat våld mot oss; och från ingen människa har du tagit något."
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
Då sade han till dem: "HERREN vare vittne mot -- eder, och hans smorde vare ock vittne denna dag, att I icke haven funnit något i min hand." De svarade: "Ja, vare det så."
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
Samuel sade till folket: "Ja, HERREN vare vittne, han som lät Mose och Aron uppstå och förde edra fäder upp ur Egyptens land.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Så träden nu fram, för att jag må gå till rätta med eder inför HERREN angående allt gott som HERREN i sin rättfärdighet har gjort mot eder och mot edra fäder.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
När Jakob hade kommit fram till Egypten, ropade edra fäder till HERREN, och HERREN sände Mose och Aron, som förde edra fäder ut ur Egypten och läto dem bosätta sig här i landet.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Men när de glömde HERREN, sin Gud, sålde han dem i Siseras hand, härhövitsmannens i Hasor, och i filistéernas hand och i Moabs konungs hand, och dessa stridde mot dem.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Men då ropade till HERREN och sade: 'Vi hava syndat, ty vi hava övergivit HERREN och tjänat Baalerna och Astarterna; men rädda oss nu från våra fienders hand, så vilja vi tjäna dig.'
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Då sände HERREN Jerubbaal och Bedan och Jefta och Samuel och räddade eder från edra fienders hand runt omkring, så att I fingen bo i trygghet.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Men när I sågen att Nahas, Ammons barns konung, kom emot eder, saden I till mig: 'Nej, en konung måste regera över oss', fastän det är HERREN, eder Gud, som är eder konung.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Och se, här är nu den konung I haven utvalt, den som I haven begärt; se, HERREN har satt en konung över eder.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Allenast man I nu frukta HERREN och tjäna honom och höra hans röst och icke vara gensträviga mot HERRENS befallning. Ja, både I och den konung som regerar över eder mån följa HERREN, eder Gud.
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Men om I icke hören HERRENS röst, utan ären gensträviga mot HERRENS befallning, då skall HERRENS hand drabba eder likasom edra fäder.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
Träden nu ock fram och sen det stora under som HERREN skall göra inför edra ögon.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Nu är ju tiden för veteskörden; men jag vill ropa till HERREN att han må låta det dundra och regna. Så skolen I märka och se huru mycket ont I haven gjort i HERRENS ögon genom eder begäran att få en konung."
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Och Samuel ropade till HERREN, och HERREN lät det dundra och regna på den dagen. Då betogs allt folket av stor fruktan för HERREN och för Samuel.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
Och allt folket sade till Samuel: "Bed för dina tjänare till HERREN, din Gud, att vi icke må dö, eftersom vi till alla våra andra synder ock hava lagt det onda att vi hava begärt att få en konung."
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Samuel sade till folket: "Frukten icke. Väl haven I gjort allt detta onda; men viken nu blott icke av ifrån HERREN, utan tjänen HERREN av allt edert hjärta.
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
Viken icke av; ty då följen I tomma avgudar, som varken kunna hjälpa eller rädda, eftersom de äro allenast tomhet.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Ty HERREN skall icke förskjuta sitt folk, för sitt stora namns skull, eftersom HERREN har behagat att göra eder till sitt folk.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Vare det ock fjärran ifrån mig att jag skulle så synda mot HERREN, att jag upphörde att bedja för eder! Jag vill fastmer lära eder den goda och rätta vägen.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Allenast frukten HERREN och tjänen honom troget av allt edert hjärta. Ty sen vilka stora ting han har gjort med eder!
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Men om I gören vad ont är, så skolen både I och eder konung förgås."

< 1 Samuel 12 >