< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Și Samuel a spus întregului Israel: Iată, am dat ascultare vocii voastre în tot ce mi-ați spus și am pus un împărat peste voi.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
Și acum, iată, împăratul umblă înaintea voastră; și eu sunt bătrân și încărunțit; și, iată, fiii mei sunt cu voi și eu am umblat înaintea voastră din copilăria mea până în această zi.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Iată-mă, mărturisiți împotriva mea înaintea DOMNULUI și înaintea unsului său; al cui bou l-am luat? Sau al cui măgar l-am luat? Sau pe cine am escrocat? Sau pe cine am oprimat? Sau din mâna cui am primit vreo mită cu care să îmi orbesc ochii? Și vă voi da înapoi.
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
Și ei au spus: Nu ne-ai escrocat, nici nu ne-ai oprimat, nici nu ai luat ceva din mâna vreunui om.
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
Iar el le-a zis: DOMNUL este martor împotriva voastră și unsul său este martor în această zi, că nu ați găsit ceva în mâna mea. Și ei au spus: El este martor.
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
Și Samuel a spus poporului: DOMNUL este cel care a rânduit pe Moise și pe Aaron și care a scos pe părinții voștri din țara Egiptului.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
De aceea acum, stați să mă judec cu voi înaintea DOMNULUI de toate faptele drepte ale DOMNULUI, pe care vi le-a făcut el, vouă și părinților voștri.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Când Iacob a venit în Egipt și părinții voștri au strigat către DOMNUL, atunci DOMNUL a trimis pe Moise și pe Aaron, care au scos pe părinții voștri din Egipt și i-au făcut să locuiască în locul acesta.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Și când ei au uitat pe DOMNUL Dumnezeul lor, el i-a vândut în mâna lui Sisera, căpetenie a oștirii Hațorului și în mâna filistenilor și în mâna împăratului Moabului și ei au luptat împotriva lor.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Și ei au strigat către DOMNUL și au spus: Am păcătuit, pentru că am părăsit pe DOMNUL și am servit Baalilor și Astarteelor; dar acum eliberează-ne din mâna dușmanilor noștri și îți vom servi.
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Și DOMNUL a trimis pe Ierub-Baal și pe Bedan și pe Iefta și pe Samuel și v-a eliberat din mâna dușmanilor voștri, de fiecare parte, și voi ați locuit în siguranță.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Și când ați văzut că Nahaș, împăratul copiilor lui Amon, a venit împotriva voastră, mi-ați spus: Nu; ci un împărat să domnească peste noi; când DOMNUL Dumnezeul vostru era împăratul vostru.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
De aceea acum, iată, pe împăratul pe care l-ați ales și pe care l-ați dorit. Și, iată, DOMNUL a pus un împărat peste voi.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Dacă vă veți teme de DOMNUL și îi veți servi și veți asculta de vocea lui și nu vă veți răzvrăti împotriva poruncii DOMNULUI, atunci atât voi cât și împăratul care domnește peste voi veți continua să urmați pe DOMNUL Dumnezeul vostru;
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Dar dacă nu veți asculta de vocea DOMNULUI, ci vă veți răzvrăti împotriva poruncii DOMNULUI, atunci mâna DOMNULUI va fi împotriva voastră, precum era împotriva părinților voștri.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
De aceea acum, stați în picioare și vedeți acest lucru mare, pe care îl va face DOMNUL înaintea ochilor voștri.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Nu este astăzi secerișul grâului? Eu voi striga către DOMNUL și el va trimite tunete și ploaie; ca să pricepeți și să vedeți că stricăciunea voastră, pe care ați făcut-o în ochii DOMNULUI, cerând pentru voi un împărat, este mare.
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Astfel Samuel a strigat către DOMNUL; și DOMNUL a trimis tunete și ploaie în acea zi; și tot poporul s-a temut mult de DOMNUL și de Samuel.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
Și tot poporul a spus lui Samuel: Roagă-te pentru servitorii tăi DOMNULUI Dumnezeul tău, ca să nu murim, pentru că am adăugat la toate păcatele noastre acest rău, de a cere pentru noi un împărat.
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Și Samuel a spus poporului: Nu vă temeți; ați făcut toată această stricăciune; numai nu vă abateți de la a-l urma pe DOMNUL, ci serviți DOMNULUI cu toată inima voastră;
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
Și nu vă abateți, pentru că atunci ați merge după lucruri deșarte, care nu folosesc, nici nu eliberează, pentru că acestea sunt deșertăciune.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Pentru că DOMNUL nu va uita pe poporul său, pentru numele său cel mare; deoarece i-a plăcut DOMNULUI să vă facă poporul său.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Mai mult, cât despre mine, nicidecum nu voi păcătui împotriva DOMNULUI, încetând să mă rog pentru voi; ci vă voi învăța calea cea bună și dreaptă;
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Numai temeți-vă de DOMNUL și serviți-i în adevăr, cu toată inima voastră; luați aminte ce lucruri mari a făcut cu voi!
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Dar, dacă vă veți purta cu stricăciune, veți fi mistuiți, deopotrivă voi și împăratul vostru.

< 1 Samuel 12 >