< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Samuel disse a todo Israel: “Eis que escutei a tua voz em tudo o que me disseste e fiz um rei sobre ti.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
Agora, eis que o rei caminha diante de vós. Eu estou velho e de cabeça cinzenta. Eis que meus filhos estão contigo. Caminhei diante de vós desde a minha juventude até os dias de hoje.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Aqui estou eu. Testemunhai contra mim diante de Javé e diante de seu ungido. De quem eu tomei o boi? De quem jumento eu peguei? A quem defraudei? A quem eu oprimi? De quem eu aceitei um suborno para me cegar os olhos? Eu o devolverei a você”.
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
Eles disseram: “Você não nos defraudou, nem nos oprimiu, nem tirou nada da mão de ninguém”.
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
Ele lhes disse: “Yahweh é testemunha contra você, e seu ungido é testemunha hoje, que você não encontrou nada na minha mão”. Eles disseram: “Ele é testemunha”.
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
Samuel disse ao povo: “Foi Javé quem nomeou Moisés e Arão, e que tirou seus pais da terra do Egito”.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Agora, portanto, fiquem quietos, para que eu possa pleitear com vocês perante Iavé a respeito de todos os atos justos de Iavé, o que ele fez com vocês e com seus pais.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
“Quando Jacó chegou ao Egito, e seus pais gritaram a Javé, então Javé enviou Moisés e Arão, que trouxeram seus pais do Egito, e os fizeram habitar neste lugar.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Mas eles esqueceram Yavé seu Deus; e ele os vendeu na mão de Sísera, capitão do exército de Hazor, e na mão dos filisteus, e na mão do rei dos moabitas; e eles lutaram contra eles.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Eles gritaram a Javé, e disseram: 'Nós pecamos, porque abandonamos Javé e servimos aos Baal e aos Ashtaroth; mas agora livrai-nos da mão de nossos inimigos, e nós vos serviremos'.
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Yahweh enviou Jerubbaal, Bedan, Jefthah e Samuel, e os libertou da mão de seus inimigos de todos os lados; e vocês viveram em segurança.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
“Quando você viu que Naash, o rei dos filhos de Amon, veio contra você, você me disse: 'Não, mas um rei reinará sobre nós', quando Yahweh, seu Deus, era seu rei.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Agora, portanto, veja o rei que você escolheu e a quem você pediu”. Eis que Javé estabeleceu um rei sobre você.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Se temerdes a Javé, e o servirdes, e ouvirdes sua voz, e não vos rebelardes contra o mandamento de Javé, então tanto vós como o rei que reina sobre vós sois seguidores de Javé, vosso Deus.
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Mas se você não ouvir a voz de Iavé, mas se rebelar contra o mandamento de Iavé, então a mão de Iavé estará contra você, como foi contra seus pais.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
“Agora, portanto, fique parado e veja esta grande coisa, o que Yahweh fará diante de seus olhos.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Não é a colheita do trigo hoje? Eu chamarei Javé, para que ele envie trovões e chuva; e você saberá e verá que sua maldade é grande, o que você fez aos olhos de Javé, ao pedir um rei”.
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Então Samuel ligou para Javé, e Javé enviou trovões e chuva naquele dia. Então todas as pessoas temiam muito a Iavé e Samuel.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
Todo o povo disse a Samuel: “Rogai por vossos servos a Javé vosso Deus, para que não morramos; pois acrescentamos a todos os nossos pecados este mal, para pedir um rei”.
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Samuel disse ao povo: “Não tenha medo”. Você realmente fez todo este mal; no entanto, não se afaste de seguir a Javé, mas sirva a Javé com todo o seu coração”.
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
Não se afaste para ir atrás de coisas vãs que não podem lucrar ou entregar, pois elas são vãs.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Pois Javé não abandonará seu povo por causa de seu grande nome, porque agradou a Javé fazer de você um povo para si mesmo.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Além disso, quanto a mim, longe de mim que eu deva pecar contra Iavé ao deixar de rezar por você; mas eu o instruirei da maneira boa e correta.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Somente temam a Iavé e o servem de verdade com todo o coração; pois considerem as grandes coisas que ele fez por vocês.
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Mas se você continuar fazendo o mal, você será consumido, tanto você como seu rei”.

< 1 Samuel 12 >