< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
USamuyeli wathi kubo bonke abako-Israyeli, “Ngikuzwile konke elikukhulumileyo kimi njalo sengilibekele inkosi.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
Khathesi selilenkosi engumkhokheli wenu. Mina sengiluphele lenwele sezimpunga, lamadodana ami lilawo khonapha. Kade ngingumkhokheli wenu kusukela ebutsheni bami kuze kube lamhla.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Ngikhonapha. Fakazani okubi ngami phambi kukaThixo logcotshiweyo wakhe. Ngubani engake ngathatha inkabi yakhe na? Ngubani engake ngathatha ubabhemi wakhe na? Ngubani engake ngamqilibezela? Ngubani engake ngamncindezela na? Kukwezikabani izandla engake ngamukela isivalamlomo ukuba ngivale amehlo ami na? Nxa ngake ngenza okunye kwalokhu, ngizakubuyisela.”
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
Baphendula bathi, “Kawuzange usiqilibezele loba usincindezele. Kawuthathanga lutho esandleni somuntu.”
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
USamuyeli wasesithi kubo, “Uthixo ungufakazi umelane lani, logcotshiweyo wakhe ungufakazi ngalelilanga, ukuthi kalitholanga lutho esandleni sami.” Bona bathi, “Yena ungufakazi.”
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
USamuyeli wasesithi ebantwini, “NguThixo owakhetha uMosi lo-Aroni wakhupha oyihlomkhulu eGibhithe.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Khathesi-ke, manini khonapha, ngoba ngizamelana lani ngobufakazi phambi kukaThixo ngazozonke izenzo ezilungileyo uThixo owazenzela lina laboyihlo.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Emva kokuba uJakhobe esefikile eGibhithe, bakhalela usizo kuThixo, uThixo wasethuma uMosi lo-Aroni, abakhupha okhokho benu eGibhithe bazabahlalisa kule indawo.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Kodwa bamkhohlwa uThixo uNkulunkulu wabo; ngakho wabanikela esandleni sikaSisera, umlawuli webutho laseHazori, lasezandleni zamaFilistiya kanye lasenkosini yamaMowabi, balwa labo.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Bakhala kuThixo bathi, ‘Sonile, simdelile uThixo sakhonza oBhali labo-Ashithorethi. Kodwa khathesi ake usikhulule ezandleni zezitha zethu, sizakukhonza.’
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Lapho-ke uThixo wathuma uJerubhi-Bhali, loBhedani, loJeftha kanye loSamuyeli, walikhulula ezandleni zezitha zenu inxa zonke, yikho lahlala livikelekile.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Kodwa kwathi lapho libona ukuthi uNahashi inkosi yama-Amoni wayesizalihlasela, lathi kimi, ‘Hatshi, sifuna inkosi yokusibusa,’ lanxa uThixo uNkulunkulu wenu wayeyinkosi yenu.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Khathesi nansi inkosi eliyikhethileyo, yona elayicelayo; khangelani, uThixo uselibekele inkosi phezu kwenu.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Nxa limesaba uThixo limkhonze njalo limlalele lingahlamukeli imilayo yakhe, njalo nxa lina kanye lenkosi elibusayo lilandela uThixo uNkulunkulu wenu, kuhle!
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Kodwa nxa uThixo lingamlaleli, njalo nxa lihlamukela imilayo yakhe, isandla sakhe sizamelana lani, njengoba sasimelane laboyihlo.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
Khathesi-ke manini lithule libone into enkulu uThixo asezayenza phambi kwamehlo enu!
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Kanti khathesi akusisikhathi sokuvuna ingqoloyi na? Ngizakhuleka kuThixo ukuba athumele umdumo lezulu. Njalo lizabona ukuthi yinto embi njani elayenzayo emehlweni kaThixo lapho licela inkosi.”
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Emva kwalokho uSamuyeli wakhuleka kuThixo, njalo khona mhlalokho uThixo wathumela umdumo lezulu. Ngakho abantu bonke bamesaba uThixo loSamuyeli.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
Bonke abantu bathi kuSamuyeli, “Khulekela izinceku zakho kuThixo uNkulunkulu wakho ukuze singafi, ngoba sesengeze kwezinye zonke izono zethu ngobubi bokucela inkosi.”
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
USamuyeli waphendula wathi, “Lingesabi. Selibenzile bonke lobububi; kodwa lingamfulatheli uThixo; kodwa khonzani uThixo ngezinhliziyo zenu zonke.
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
Lingaphendukeli ezithombeni ezingasizi lutho. Zingeke zilenzele lutho, kumbe zilihlenge, ngoba kazilasizo.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Ngenxa yebizo lakhe elikhulu uThixo kayikubalahla abantu bakhe, ngoba uThixo wathokoziswa yikulenza libe ngabakhe.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Mina-ke kangiyikukwenza ukuthi ngenze isono kuThixo ngokungalikhulekeli. Njalo ngizalifundisa indlela enhle lelungileyo.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Kodwa mesabeni ngeqiniso uThixo, limkhonze ngobuqotho ngezinhliziyo zenu zonke. Khumbulani izinto ezinkulu alenzela zona.
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Kodwa lingaphikelela ukwenza okubi, lina lenkosi yenu lizakhukhulwa.”

< 1 Samuel 12 >