< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Forsothe Samuel seide to al Israel, Lo! Y herde youre vois bi alle thingis whiche ye spaken to me, and Y ordeynede a kyng on you;
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
and now the king goith bifor you. Sotheli Y wexide eld and hoor; forsothe my sones ben with you; therfor Y lyuyde bifor you fro my yong wexynge age `til to this dai. And lo!
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Y am redi; speke ye to me bifor the Lord, and bifor `the crist of hym; whether Y took `the oxe of ony man, ether the asse; if Y falsly chalengide ony mon; yf Y oppresside ony man; if Y took yifte of `the hond of ony man; and Y schal `dispise it to dai, and Y schal restore to you.
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
And thei seiden, Thou hast not falsly chalengid vs, nether hast oppressid vs, nether hast take ony thing of `the hond of ony man.
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
And he seide to hem, The Lord is witnesse ayens you, and his crist is witnesse in this day; for ye han not founde ony thing in myn hond. And thei seiden, Witnesse.
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
And Samuel seide to the puple, The Lord, that made Moises and Aaron, and ledde youre fadris out of the lond of Egipt, is present;
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
now therfor stonde ye, that Y stryue bi doom ayens you bifor the Lord, of alle the mercyes of the Lord, whiche he dide with you, and with youre fadris.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Hou Jacob entride in to Egipt, and youre fadris crieden to the Lord; and the Lord sente Moises and Aaron, and ledde youre fadris out of Egipt, and settide hem in this place.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Whiche foryaten her Lord God; and he bitook hem in the hond of Sisara, maystir of the chyualrie of Asor, and in the hond of Filisteis, and in the hond of the kyng of Moab; and thei fouyten ayens hem.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Sotheli afterward thei crieden to the Lord, and seiden, We synneden, for we forsoken the Lord, and seruyden Baalym and Astroth; now therfor delyuere thou vs fro `the hond of oure enemyes, and we schulen serue thee.
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
And the Lord sente Gerobaal, and `Bedan, that is, Sampson, and Barach, and Jepte, and Samuel, and delyuerede you fro the hond of youre enemyes bi cumpass; and ye dwelliden tristili.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Forsothe ye sien, that Naas, kyng of the sones of Amon, cam ayens you; and ye seiden to me, counseilynge to axe noon other kyng than God, Nay, but a kyng schal comaunde to vs; whanne `youre Lord God regnede in you.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Now therfor youre kyng is redi, whom ye han chose and axid; lo! the Lord yaf to you a kyng.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
If ye dreden the Lord, and seruen hym, and heren his vois, and wraththen not the `mouth of the Lord; ye and youre kyng, that comaundith to you, schulen sue youre Lord God.
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Forsothe if ye heren not the vois of `the Lord, but wraththen his word, the hond of the Lord schal be on you, and on youre fadris.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
But also now stonde ye, and se this gret thing which the Lord schal make in youre siyt.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Whether heruest of whete is not `to dai? I schal inwardli clepe the Lord, and he schal yyue voices, `that is, thundris, and reynes; and ye schulen wite, and schulen se, for ye axynge a kyng on you han do greuouse yuel to you in the siyt of the Lord.
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
And Samuel criede to the Lord, and the Lord yaf voices and reynes in that dai.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
And al the puple dredde greetli the Lord and Samuel; and al the puple seide to Samuel, Preye thou for thi seruauntis to thi Lord God, that we die not; for we addiden yuel to alle oure synnes, that we axiden a kyng to vs.
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Forsothe Samuel seide to the puple, `Nyle ye drede; ye han do al this yuel; netheles `nyle ye go awey fro the bak of the Lord, but serue ye the Lord in al youre herte;
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
and nyle ye bowe aftir veyn thingis, that schulen not profite to you, nether schulen delyuere you; for tho ben veyn thingis.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
And the Lord schal not forsake his puple for his grete name; for the Lord swoor to make you a puple to hym silf.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Forsothe this synne be fer fro me in the Lord, that Y ceesse to preye for you; and Y schal teche you a riytful weie and good.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Therfor drede ye the Lord, and `serue ye hym in treuthe, and of al youre herte; for ye sien tho grete thingis, whiche he `dide in you;
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
that if ye contynuen in malice, bothe ye and youre kyng schulen perische to gidere.

< 1 Samuel 12 >