< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Da sagde Samuel til hele Israel: "Se, jeg har føjet eder i alt, hvad I har bedt mig om, og sat en Konge over eder.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
Se, nu færdes Kongen for eders Ansigt; jeg er gammel og grå, og mine Sønner er nu iblandt eder; men jeg har færdedes for eders Ansigt fra min Ungdom indtil i Dag.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Se, her står jeg; viden imod mig i HERRENs og hans, Salvedes Påhør! Hvis Okse har jeg taget? Hvis Æsel har jeg taget? Hvem har jeg, undertrykt? Hvem har jeg gjort Uret? Af hvem har jeg taget Gave og derfor lukket Øjnene? I så Fald vil jeg give eder Erstatning!"
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
Da sagde de: "Du har ikke undertrykt os eller gjort os Uret eller taget noget fra nogen."
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
Derpå sagde han til dem: "Så er HERREN i Dag Vidne over for eder, også hans Salvede er Vidne, at I ikke har fundet noget hos mig." De sagde: "Ja!"
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
Da sagde Samuel til Folket: "HERREN er Vidne, han, som udrustede Moses og Aron og førte eders Fædre op fra Ægypten.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Så træd nu frem, at jeg kan gå i Rette med eder for HERRENs Åsyn og kundgøre eder alle de Gerninger, HERREN i sin Retfærdigher har øvet mod eder og eders Fædre.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Da Jakob og hans Sønner var kommet til Ægypten, og Ægypterne plagede dem, råbte eders Fædre til HERREN, og HERREN sendte Moses og Aron, som førte eders Fædre ud af Ægypten, og han lod dem bosætte sig her.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Men de glemte HERREN deres Gud; derfor prisgav han dem til Kong Jabin af Hazors Hærfører Sisera, til Filisterne og til Moabs Konge, så de angreb dem.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Da råbte de til HERREN og sagde: Vi har syndet, thi vi forlod HERREN og dyrkede Ba'alerne og Astarterne; men fri os nu af vore Fjenders Hånd, så vil vi dyrke dig!
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Så sendte HERREN Jerubba'al, Barak, Jefta og Samuel; og han friede eder af eders Fjenders Hånd rundt om, så I kunde bo i Tryghed.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Men da I så Ammoniterkongen Nahasj rykke frem imod eder, sagde I til mig: Nej, en Konge skal herske over os uagtet HERREN eders Gud var eders Konge!
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Og nu, her står Kongen, som I har valgt og krævet; se, HERREN har sat en Konge over eder!
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Hvis I frygter HERREN og tjener ham, adlyder hans Røst og ikke er genstridige mod HERRENs Bud, men følger HERREN eders Gud, både I og Kongen, som har fået Herredømmet over eder, da skal det gå eder vel.
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Adlyder I derimod ikke HERRENs Røst, men er genstridige mod HERRENs Bud, da skal HERRENs Hånd ramme eder og eders Konge og ødelægge eder.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
Træd nu frem og se den vældige Gerning, HERREN vil øve for eders Øjne!
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Har vi ikke Hvedehøst nu? Men jeg vil råbe til HERREN, at han skal sende Torden og Regn, for at I kan kende og se, at det i HERRENs Øjne var en stor Brøde I begik, da I krævede en Konge!"
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Derpå råbte Samuel til HERREN, og HERREN sendte samme Dag Torden og Regn. Da frygtede hele folket såre for HERREN og Samuel,
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
og hele Folket sagde til Samuel: "Bed for dine Trælle til HERREN din Gud, at vi ikke skal dø, fordi vi til vore andre Synder har føjet den Brøde at kræve en Konge!"
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Da sagde Samuel til Folket: "Frygt ikke! Vel har I øvet al den Synd; men vend eder nu ikke fra HERREN, tjen ham af hele eders Hjerte
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
og vend eder ikke til dem, som er Tomhed og hverken kan hjælpe eller frelse, fordi de er Tomhed.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Thi for sit store Navns Skyld vil HERREN ikke forstøde sit Folk, da det jo har behaget HERREN at gøre eder til sit Folk.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Det være også langt fra mig at synde mod HERREN og høre op med at bede for eder; jeg vil også vise eder den gode og rette Vej;
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
men frygt HERREN og tjen ham oprigtigt af hele eders Hjerte; thi se, hvor store Ting han gjorde imod eder!
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Men hvis I handler ilde, skal både I og eders Konge gå til Grunde!"

< 1 Samuel 12 >