< 1 Samuel 12 >
1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Тогава Самуил каза на целия Израил: Ето, послушах гласа ви за всичко, що ми казахте, и поставих цар над вас.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
И сега, ето, царят ви предвожда; а аз съм стар и белокос, и, ето, синовете ми са с вас; и обходата ми от младостта ми до днес е пред вас.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Ето ме: свидетелствувайте против мене пред Господа и пред помазаника Му - Кому съм взел вола? или кому съм взел осела? или кого съм онеправдал? кого съм притеснил? или из ръката на кого съм взел подкуп, за да ослепя очите си с него, та да ви го върна?
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
А те рекоха: Не си ни онеправдал, нито си ни притеснил, нито се взел нещо от ръката на някого.
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
И рече им: Свидетел ви е Господ, свидетел е и Неговият помазаник Днес, че не намерихте нищо в ръката ми. И те отговориха: Свидетел е.
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
И рече Самуил на людете: Господ е, Който постави Моисея и Аарона и изведе бащите ви от Египетската земя.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Сега, прочее, застанете, за да разсъждавам с вас пред Господа за всичките справедливи дела, които Господ направи вам и на бащите ви.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Когато Яков дойде в Египет, и бащите ви извикаха към Господа, тогава Господ прати Моисея и Арона, които изведоха бащите ви из Египет и заселиха ги на това място.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Те обаче забравиха Господа своя Бог; затова ги предаде в ръката на Сисара, асорския военачалник, в ръката на филистимците и в ръката на моавския цар, които воюваха против тях.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Тогава те извикаха към Господа, казвайки: Съгрешихме, понеже оставихме Господа та служихме на ваалимите и на астартите; но сега избави ни от ръката на неприятелите ни, и ще Ти служим.
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
И Господ изпрати Ероваала, Водана, Ефтая и Самуила та ви избави от ръката на неприятелите ви от всякъде; и вие живеехте в безопасност.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Но когато видяхте, че Наас, царят на амонците, дойде против вас, рекохте ми: Не, но цар да царува над нас, - когато Господ вашият Бог ви беше цар.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Сега, прочее, ето царят, когото избрахте, когато искахте! и, ето Господ постави цар над вас.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Ако се боите от Господа и Му служите, и слушате гласът Му, и не въставате против Господното повеление, и следвате Господа вашия Бог, както вие, така и царят, който царува над вас, добре;
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
но, ако не слушате Господния глас, а въставате против Господното повеление, тогава Господната ръка ще бъде против, вас, както беше против бащите ви.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
Сега, прочее, застанете та вижте това велико дело, което Господ ще направи пред очите ви.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Не е ли днес жетва на пшеницата? Ще призова Господа; и Той ще прати гръмове и дъжд, за да познаете и видите, че злото, което направихте, като си поискахте цар, е голямо пред Господа.
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Тогава Самуил призова Господа; и Господ прати гръмове и дъжд през същия ден; и всичките люде се уплашиха твърде много от Господа и от Самуила.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
И всичките люде казаха на Самуила: Помоли се за слугите си на Господа твоя Бог, за да не измрем; защото върху всичките си грехове притурихме и това зло, да искаме за себе си цар.
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
И Самуил каза на людете: Не бойте се; вие наистина сторихте всичко това зло; но да се не отклоните та да не следвате Господа, а служете Господу от все сърце;
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
и да се не отклоните, защото тогава ще идете след суетностите, които не могат да ползват, или да избавят, понеже са суетни.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Защото Господ няма да остави людете Си заради великото Си Име, понеже Господ благоволи да ви направи Свои люде.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
А колкото за мене, да не даде Бог да съгреша на Господа, като престана да се моля за вас! но ще ви уча добрия и правия път.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Само бойте се от Господа, и служете Му искрено от все сърце; защото помислете колко велики дела извърши Той за вас.
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Но ако следвате да струвате зло, това и вие и царят ви ще погинете.