< 1 Samuel 11 >

1 Nahaṣi ará Ammoni gòkè lọ, ó sì dó ti Jabesi Gileadi, gbogbo ọkùnrin Jabesi sì wí fún Nahaṣi pé, “Bá wa dá májẹ̀mú, àwa yóò sì máa sìn ọ́.”
Wtedy nadciągnął Nachasz Ammonita i rozbił obóz przeciwko Jabesz-Gilead. I wszyscy mieszkańcy Jabesz powiedzieli do Nachasza: Zawrzyj z nami przymierze, a będziemy ci służyć.
2 Ṣùgbọ́n Nahaṣi ará Ammoni sì wí fún un pé, “Nípa èyí ni èmi yóò fi bá a yín ṣe ìpinnu, nípa yíyọ gbogbo ojú ọ̀tún yín kúrò, èmi yóò ṣì fi yín ṣe ẹlẹ́yà lójú gbogbo Israẹli.”
Odpowiedział im Nachasz Ammonita: Zawrę z wami [przymierze], pod warunkiem że każdemu z was wyłupię prawe oko i będzie to hańba dla całego Izraela.
3 Àwọn àgbàgbà Jabesi sì wí fún un pé, “Fún wa ní ọjọ́ méje kí àwa lè rán oníṣẹ́ sí gbogbo Israẹli; àti agbègbè bí ẹni kankan kò bá sì jáde láti gbà wá, àwa yóò fi ara wa fún ọ.”
Starsi z Jabesz odpowiedzieli mu: Daj nam siedem dni na rozesłanie posłańców po wszystkich granicach Izraela. A jeśli nie będzie nikogo, kto by nas uratował, wtedy wyjdziemy do ciebie.
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà sì wá sí Gibeah tí ó jẹ́ ìlú Saulu, wọ́n sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, gbogbo wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún.
Przyszli więc posłańcy do Gibea, [miasta] Saula, i powtórzyli te słowa do uszu ludu. Cały lud zaś podniósł donośny lament i płakał.
5 Nígbà náà gan an ni Saulu padà wá láti pápá, pẹ̀lú màlúù rẹ̀, ó sì béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn? Èéṣe tí wọ́n fi ń sọkún?” Nígbà náà ni wọ́n tún sọ fún wọn ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi.
A oto Saul wracał za wołami z pola i pytał się: Co [się stało] ludowi, że płacze? I opowiedzieli mu wszystkie słowa mieszkańców Jabesz.
6 Nígbà tí Saulu sì gbọ́ ọ̀rọ̀ wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà lé e pẹ̀lú agbára, inú rẹ̀ sì ru sókè.
Gdy Saul usłyszał te słowa, zstąpił na niego Duch Boży i [Saul] zapałał wielkim gniewem.
7 Ó sì mú màlúù méjì, ó gé wọn sí wẹ́wẹ́, ó sì rán ẹyẹẹyọ sí gbogbo Israẹli nípa ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ náà, ó ní i ẹ kéde pé, “Èyí ni a ó ṣe sí màlúù ẹnikẹ́ni tí kò bá tọ Saulu àti Samuẹli lẹ́yìn.” Nígbà náà ni ìbẹ̀rù Olúwa sì mú àwọn ènìyàn, wọ́n sì jáde bí ènìyàn kan ṣoṣo.
I wziął parę wołów, rozrąbał je na części i rozesłał je przez posłańców po wszystkich granicach Izraela, mówiąc: Tak się stanie z wołami każdego, kto nie wyruszy za Saulem i Samuelem. I padł strach PANA na lud, i wyruszyli jak jeden mąż.
8 Nígbà tí Saulu sì kó wọn jọ ní Beseki, àwọn ọkùnrin Israẹli tí a kà jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
Potem dokonał ich przeglądu w Bezek – było trzysta tysięcy synów Izraela, a mężczyzn Judy trzydzieści tysięcy.
9 Wọ́n sì sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó wá pé, “Sọ fún àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi pé, ní àkókò tí oòrùn bá mú lọ́la, àwa yóò gbà yín sílẹ̀.” Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà lọ tí wọ́n sì sọ èyí fún àwọn ọkùnrin Jabesi, inú wọn sì dùn.
I powiedzieli posłańcom, którzy przyszli: Tak powiedzcie mieszkańcom Jabesz-Gilead: Jutro, gdy przygrzeje słońce, zostaniecie wybawieni. Posłańcy wrócili więc i oznajmili to mieszkańcom Jabesz, a oni ucieszyli się.
10 Wọ́n sọ fún àwọn ará Jabesi pé, “Àwa yóò fi ara wa fún un yín ní ọ̀la, kí ẹ̀yin kí ó ṣe gbogbo èyí tí ó tọ́ lójú yín sí wa.”
Wtedy mieszkańcy Jabesz powiedzieli: Jutro wyjdziemy do was i uczynicie z nami wszystko, co się wam podoba.
11 Ní ọjọ́ kejì Saulu pín àwọn ọkùnrin rẹ̀ sí ipa mẹ́ta, wọ́n sì ya wọ àgọ́ àwọn ará Ammoni ní ìṣọ́ òwúrọ̀, wọ́n sì pa wọ́n títí di ìmóoru ọjọ́. Àwọn tókù wọ́n sì fọ́nká, tó bẹ́ẹ̀ tí méjì wọn kò kù sí ibìkan.
Nazajutrz Saul podzielił lud na trzy oddziały. One wtargnęły do środka obozu podczas straży porannej i biły Ammonitów aż do dziennej spiekoty. Ci, którzy pozostali, rozpierzchli się tak, że dwóch razem nie zostało.
12 Àwọn ènìyàn sọ fún Samuẹli pé, “Ta ni ó béèrè wí pé, Saulu yóò ha jẹ ọba lórí wa? Mú àwọn ọkùnrin náà wá, a ó sì pa wọ́n.”
Wtedy lud powiedział do Samuela: Kto to mówił: Czy Saul będzie królować nad nami? Wydajcie [tych] ludzi, abyśmy ich zabili.
13 Ṣùgbọ́n Saulu wí pé, “A kì yóò pa ẹnikẹ́ni lónìí, nítorí lónìí yìí ni Olúwa ṣiṣẹ́ ìgbàlà ní Israẹli.”
I Saul odpowiedział: Nikt nie zostanie zabity w tym dniu, gdyż dzisiaj PAN dokonał wybawienia w Izraelu.
14 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Gilgali, kí a lè fi ẹsẹ̀ Saulu múlẹ̀ bí ọba.”
Potem Samuel odezwał się do ludu: Chodźcie, pójdziemy do Gilgal i tam odnowimy królestwo.
15 Nítorí náà gbogbo ènìyàn lọ sí Gilgali, wọn sí fi Saulu jẹ ọba ní iwájú Olúwa. Níbẹ̀, ni wọn ti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀ ní iwájú Olúwa, Saulu àti gbogbo Israẹli ṣe àjọyọ̀ ńlá.
Cały lud wyruszył więc do Gilgal i tam ustanowili Saula królem przed PANEM w Gilgal. Tam też składali ofiary pojednawcze przed PANEM i bardzo się radowali, Saul i wszyscy Izraelici.

< 1 Samuel 11 >