< 1 Samuel 11 >

1 Nahaṣi ará Ammoni gòkè lọ, ó sì dó ti Jabesi Gileadi, gbogbo ọkùnrin Jabesi sì wí fún Nahaṣi pé, “Bá wa dá májẹ̀mú, àwa yóò sì máa sìn ọ́.”
Na rĩrĩ, Nahashu ũrĩa Mũamoni nĩambatire agĩthiĩ akĩrigiicĩria Jabeshi-Gileadi. Nao andũ othe a Jabeshi makĩmwĩra atĩrĩ, “Gĩa na kĩrĩĩko kĩa ũiguano, na ithuĩ nĩ tũrĩgũtungatagĩra.”
2 Ṣùgbọ́n Nahaṣi ará Ammoni sì wí fún un pé, “Nípa èyí ni èmi yóò fi bá a yín ṣe ìpinnu, nípa yíyọ gbogbo ojú ọ̀tún yín kúrò, èmi yóò ṣì fi yín ṣe ẹlẹ́yà lójú gbogbo Israẹli.”
Nowe Nahashu ũcio Mũamoni agĩcookia atĩrĩ, “Nĩtũkũgĩa na kĩrĩĩko kĩa ũiguano na inyuĩ mwetĩkĩra ũndũ ũyũ ũmwe: atĩ ngũũre riitho rĩa ũrĩo rĩa o mũndũ wothe nĩgeetha nyararithie andũ a Isiraeli othe.”
3 Àwọn àgbàgbà Jabesi sì wí fún un pé, “Fún wa ní ọjọ́ méje kí àwa lè rán oníṣẹ́ sí gbogbo Israẹli; àti agbègbè bí ẹni kankan kò bá sì jáde láti gbà wá, àwa yóò fi ara wa fún ọ.”
Athuuri acio a Jabeshi makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũhe mĩthenya mũgwanja nĩguo tũtũme andũ Isiraeli guothe, kũngĩaga mũndũ wa gũtũhonokia-rĩ, nĩtũkwĩneana kũrĩ we.”
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà sì wá sí Gibeah tí ó jẹ́ ìlú Saulu, wọ́n sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, gbogbo wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún.
Rĩrĩa andũ acio matũmĩtwo maakinyire Gibea gwa Saũlũ na makĩheana ũhoro ũcio kũrĩ andũ-rĩ, andũ othe makĩrĩra maanĩrĩire.
5 Nígbà náà gan an ni Saulu padà wá láti pápá, pẹ̀lú màlúù rẹ̀, ó sì béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn? Èéṣe tí wọ́n fi ń sọkún?” Nígbà náà ni wọ́n tún sọ fún wọn ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi.
Na rĩrĩ, Saũlũ nĩgũcooka aacookaga oimĩte mĩgũnda-inĩ, oimĩte ndegwa ciake thuutha, akĩũria atĩrĩ, “Kaĩ andũ aya moonete ũũru ũrĩkũ? Nĩ kĩĩ kĩratũma marĩre?” Nao magĩcookera ũhoro ũcio makĩmwĩra ũrĩa andũ a Jabeshi moigĩte.
6 Nígbà tí Saulu sì gbọ́ ọ̀rọ̀ wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà lé e pẹ̀lú agbára, inú rẹ̀ sì ru sókè.
Rĩrĩa Saũlũ aiguire ũhoro ũcio, Roho wa Ngai agĩũka igũrũ rĩake na hinya mũno, nake agĩcinwo nĩ marakara.
7 Ó sì mú màlúù méjì, ó gé wọn sí wẹ́wẹ́, ó sì rán ẹyẹẹyọ sí gbogbo Israẹli nípa ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ náà, ó ní i ẹ kéde pé, “Èyí ni a ó ṣe sí màlúù ẹnikẹ́ni tí kò bá tọ Saulu àti Samuẹli lẹ́yìn.” Nígbà náà ni ìbẹ̀rù Olúwa sì mú àwọn ènìyàn, wọ́n sì jáde bí ènìyàn kan ṣoṣo.
Akĩnyiita ndegwa igĩrĩ, agĩcitinangia icunjĩ, na agĩtũma andũ Isiraeli guothe nacio, makĩanagĩrĩra atĩrĩ, “Ũũ nĩguo ndegwa cia mũndũ o wothe igwĩkwo ũrĩa ũtekũrũmĩrĩra Saũlũ na Samũeli.” Naguo guoya woimĩte harĩ Jehova ũkĩnyiita andũ acio, nao makiumagara ta maarĩ o mũndũ ũmwe.
8 Nígbà tí Saulu sì kó wọn jọ ní Beseki, àwọn ọkùnrin Israẹli tí a kà jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
Hĩndĩ ĩrĩa Saũlũ aamatarire hamwe marĩ kũu Bezeki, andũ a Isiraeli maarĩ andũ ngiri magana matatũ na andũ a Juda ngiri mĩrongo ĩtatũ.
9 Wọ́n sì sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó wá pé, “Sọ fún àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi pé, ní àkókò tí oòrùn bá mú lọ́la, àwa yóò gbà yín sílẹ̀.” Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà lọ tí wọ́n sì sọ èyí fún àwọn ọkùnrin Jabesi, inú wọn sì dùn.
Nao makĩĩra andũ acio maatũmĩtwo atĩrĩ, “Ĩrai andũ acio a Jabeshi-Gileadi atĩrĩ, ‘rũciũ ihinda rĩrĩa riũa rĩgaakorwo rĩhiũhĩte, nĩguo mũkaahonokio.’” Rĩrĩa andũ acio maatũmĩtwo mathiire makĩheana ũhoro ũcio kũrĩ andũ a Jabeshi-rĩ, andũ acio makĩiyũrwo nĩ gĩkeno kĩnene.
10 Wọ́n sọ fún àwọn ará Jabesi pé, “Àwa yóò fi ara wa fún un yín ní ọ̀la, kí ẹ̀yin kí ó ṣe gbogbo èyí tí ó tọ́ lójú yín sí wa.”
Nao makĩĩra andũ a Amoni atĩrĩ, “Rũciũ nĩtũkeneana kũrĩ inyuĩ, na inyuĩ no mũtwĩke ũrĩa wothe mũkoona kwagĩrĩire.”
11 Ní ọjọ́ kejì Saulu pín àwọn ọkùnrin rẹ̀ sí ipa mẹ́ta, wọ́n sì ya wọ àgọ́ àwọn ará Ammoni ní ìṣọ́ òwúrọ̀, wọ́n sì pa wọ́n títí di ìmóoru ọjọ́. Àwọn tókù wọ́n sì fọ́nká, tó bẹ́ẹ̀ tí méjì wọn kò kù sí ibìkan.
Mũthenya ũyũ ũngĩ Saũlũ akĩgayania ita rĩake akĩiga andũ ikundi ithatũ; na hĩndĩ ya ituanĩra rĩa arangĩri rĩa gũgĩkĩa makĩhithũka kambĩ-inĩ ya Aamoni makĩmooraga nginya rĩrĩa riũa rĩakoretwo rĩhiũhĩte. Arĩa maatigarire makĩharaganio. Nĩ ũndũ ũcio gũtiarĩ andũ ao eerĩ maatigĩtwo me hamwe.
12 Àwọn ènìyàn sọ fún Samuẹli pé, “Ta ni ó béèrè wí pé, Saulu yóò ha jẹ ọba lórí wa? Mú àwọn ọkùnrin náà wá, a ó sì pa wọ́n.”
Andũ acio magĩcooka makĩĩra Samũeli atĩrĩ, “Nĩ a acio mooragia atĩrĩ, ‘Saũlũ no atũthamakĩre?’ Tũrehere andũ acio tũmoorage.”
13 Ṣùgbọ́n Saulu wí pé, “A kì yóò pa ẹnikẹ́ni lónìí, nítorí lónìí yìí ni Olúwa ṣiṣẹ́ ìgbàlà ní Israẹli.”
Nowe Saũlũ akiuga atĩrĩ, “Gũtirĩ mũndũ o na ũũ ũkũũragwo ũmũthĩ, nĩ ũndũ mũthenya ũyũ Jehova nĩahonoketie Isiraeli.”
14 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Gilgali, kí a lè fi ẹsẹ̀ Saulu múlẹ̀ bí ọba.”
Hĩndĩ ĩyo Samũeli agĩcooka akĩĩra andũ acio atĩrĩ, “Ũkai, tũthiĩ Giligali na tũrĩ kũu tũkindĩre ũthamaki.”
15 Nítorí náà gbogbo ènìyàn lọ sí Gilgali, wọn sí fi Saulu jẹ ọba ní iwájú Olúwa. Níbẹ̀, ni wọn ti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀ ní iwájú Olúwa, Saulu àti gbogbo Israẹli ṣe àjọyọ̀ ńlá.
Nĩ ũndũ ũcio andũ othe magĩthiĩ Giligali na magĩkindĩra atĩ Saũlũ nĩwe mũthamaki marĩ mbere ya Jehova. Nao marĩ kũu makĩruta maruta ma ũiguano marĩ mbere ya Jehova, nake Saũlũ na andũ othe a Isiraeli magĩkũngũĩra na njĩra nene.

< 1 Samuel 11 >