< 1 Samuel 10 >

1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
Samuil bir may komzikini elip uning bexiƣa tɵküp uni sɵyüp mundaⱪ dedi: — «Mana bu, Pǝrwǝrdigarning seni Ɵz mirasiƣa ǝmir boluxⱪa mǝsiⱨ ⱪilƣini ǝmǝsmu?
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
Sǝn bügün mǝndin ayrilƣandin keyin Binyamin zeminining qegrisidiki Zǝlzaⱨƣa yetip barƣiningda Raⱨilǝning ⱪǝbrisining yenida sanga ikki kixi uqraydu; ular sanga: «Sǝn izdǝp barƣan exǝklǝr tepildi, wǝ mana, atang exǝklǝrdin ƣǝm ⱪilmay, bǝlki silǝr üqün: Oƣlumni ⱪandaⱪ ⱪilip taparmǝn, dǝp ǝnsirimǝktǝ» dǝp eytidu.
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
Sǝn u yǝrdin mengip, Tabordiki dub dǝrihigǝ yǝtkǝndǝ Pǝrwǝrdigarning aldiƣa berix üqün Bǝyt-Əlgǝ qiⱪip ketiwatⱪan üq kixigǝ uqraysǝn. Ulardin biri üq oƣlaⱪ, biri üq nan wǝ yǝnǝ biri bir tulum xarabni kɵtürüp kelidu.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
— Ular sanga salam ⱪilip ikki nanni sunidu; sǝn bǝrginini ⱪolliridin alƣin.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Andin sǝn «Hudaƣa [atalƣan] Gibeaⱨ xǝⱨǝrigǝ barisǝn (u yǝrdǝ Filistiylǝrning bir lǝxkǝrgaⱨi bar); sǝn xu xǝⱨǝrgǝ kǝlsǝng qiltar, tǝmbur, nǝy wǝ lirilarni kɵtürüp yuⱪiri jayidin qüxkǝn bir bɵlǝk pǝyƣǝmbǝrlǝr sanga uqraydu. Ular bexarǝtlik sɵzlǝrni ⱪilidu.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigarning Roⱨi sening wujudungƣa qüxidu, sǝn ular bilǝn birliktǝ bexarǝtlik sɵzlǝrni ⱪilisǝn wǝ yengi bir adǝm bolisǝn.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
Muxu alamǝtlǝr sanga kǝlgǝndǝ, ⱪolungdin nemǝ kǝlsǝ xuni ⱪilƣin. Qünki Huda sǝn bilǝn billidur.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
Andin mǝndin ilgiri Gilgalƣa qüxüp barisǝn. Mana, mǝn ⱨǝm yeningƣa qüxüp kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlar sunux wǝ inaⱪ ⱪurbanliⱪlar ⱪilix üqün kelimǝn. Mǝn yeningƣa berip, nemǝ ⱪilixing kerǝklikini uⱪturmiƣuqǝ, meni yǝttǝ kün saⱪlap turƣin».
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Wǝ xundaⱪ boldiki, u burulup Samuildin ayrilƣanda Huda uningƣa yengi bir ⱪǝlb ata ⱪildi; wǝ bu alamǝtlǝrning ⱨǝmmisi axu küni ǝmǝldǝ kɵrsitildi.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Ular Gibeaⱨƣa yetip kǝlgǝndǝ mana, bir bɵlǝk pǝyƣǝmbǝrlǝr uningƣa uqridi; Hudaning Roⱨi uning wujudiƣa qüxti, buning bilǝn u ularning arisida bexarǝt ⱪilixⱪa baxlidi.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Uni ilgiri tonuydiƣanlarning ⱨǝmmisi uning pǝyƣǝmbǝrlǝrning arisida bexarǝt ⱪilƣinini kɵrgǝndǝ ular bir-birigǝ: — Kixning oƣliƣa nemǝ boptu? Saulmu pǝyƣǝmbǝrlǝrdin biri boldimu nemǝ? — deyixti.
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
Əmma yǝrlik bir adǝm: — Bularning atiliri kimlǝr? — dedi. Xuning bilǝn: «Saulmu pǝyƣǝmbǝrlǝrning birimidu?» dǝydiƣan gǝp pǝyda boldi.
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Əmdi Saul bexarǝtlik sɵzlǝrni ⱪilip bolup, yuⱪiri jayƣa qiⱪip kǝtti.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Saulning taƣisi uningdin wǝ uning hizmǝtkaridin: — Nǝgǝ berip kǝldinglar? dǝp soridi. U: — Exǝklǝrni izdigili qiⱪtuⱪ; lekin ularni tapalmay Samuilning ⱪexiƣa barduⱪ, dedi.
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Saulning taƣisi: — Samuilning silǝrgǝ nemǝ deginini manga eytip bǝrginǝ, dedi.
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
Saul taƣisiƣa: — U jǝzm bilǝn bizgǝ exǝklǝr tepildi, dǝp hǝwǝr bǝrdi, dedi. Lekin Samuilning padixaⱨliⱪ ixi toƣruluⱪ eytⱪan sɵzini uningƣa dǝp bǝrmidi.
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
Samuil ǝmdi hǝlⱪni Pǝrwǝrdigarning aldiƣa jǝm bolunglar dǝp, Mizpaⱨⱪa qaⱪirdi.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
U Israilƣa: — Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Mǝn silǝr Israilni Misirdin qiⱪirip misirliⱪlarning ⱪolidin azad ⱪilip, silǝrgǝ zulum ⱪilƣan ⱨǝmmǝ padixaⱨliⱪlarning ⱪolidin ⱪutⱪuzdum.
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
Lekin bügünki kündǝ silǝrni bexinglarƣa qüxkǝn barliⱪ balayi’apǝtlǝrdin wǝ barliⱪ muxǝⱪⱪǝtlǝrdin ⱪutⱪuzƣuqi Hudayinglardin waz keqip uningƣa: «Yaⱪ. Üstimizgǝ bir padixaⱨ bekitip bǝrgǝysǝn» — dedinglar. Əmdi ɵzünglarni ⱪǝbilǝnglar boyiqǝ, jǝmǝtinglar boyiqǝ Pǝrwǝrdigarning aldiƣa ⱨazir ⱪilinglar» — dedi.
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
Xuning bilǝn Samuil Israilning ⱨǝmmǝ ⱪǝbililirini aldiƣa jǝm ⱪilip, qǝk taxliwidi, qǝk Binyamin ⱪǝbilisigǝ qiⱪti.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
U Binyamin ⱪǝbilisini jǝmǝt-jǝmǝtliri boyiqǝ ɵz aldiƣa kǝltürüp qǝk taxliwidi, qǝk Matrining jǝmǝtigǝ qiⱪti. Andin keyin yǝnǝ qǝk taxliwidi, Kixning oƣli Saulƣa qiⱪti. Ular uni izdiwidi, ǝmma uni tapalmidi.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Xunga ular Pǝrwǝrdigardin yǝnǝ: — U kixi bu yǝrgǝ kelǝmdu? — dǝp soridi. Pǝrwǝrdigar jawabǝn: — Mana, u yük-taⱪlarning arisiƣa yoxuruniwaldi, dedi.
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Xunga ular yügürüp berip uni xu yǝrdin elip kǝldi. U hǝlⱪning otturisida turƣanda halayiⱪning boyi uning mürisigimu kǝlmidi.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
Samuil barliⱪ hǝlⱪⱪǝ: — Əmdi Pǝrwǝrdigar talliƣan kixigǝ ⱪaranglar! Dǝrwǝⱪǝ barliⱪ hǝlⱪning iqidǝ uningƣa yetidiƣan birsi yoⱪtur, dedi. Wǝ hǝlⱪning ⱨǝmmisi: — Padixaⱨ yaxisun! — dǝp towlaxti.
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
Samuil hǝlⱪⱪǝ padixaⱨliⱪ ⱨoⱪuⱪ-ⱪanunlirini uⱪturdi wǝ uni oram yazma ⱪilip yezip qiⱪip, Pǝrwǝrdigarning aldiƣa ⱪoydi. Andin Samuil ⱨǝmmǝ hǝlⱪni, ⱨǝrⱪaysisini ɵz ɵylirigǝ ⱪayturdi.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
Saulmu ⱨǝm Gibeaⱨdiki ɵyigǝ ⱪaytti; kɵngülliri Huda tǝripidin tǝsirlǝndürülgǝn bir türküm batur kixi uning bilǝn billǝ bardi.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
Lekin birnǝqqǝ rǝzil kixi: — Bu kixi ⱪandaⱪmu bizni ⱪutⱪuzalisun? — dǝp uni kǝmsitip uningƣa ⱨeq sowƣat bǝrmidi; ǝmma u anglimasliⱪⱪa saldi.

< 1 Samuel 10 >