< 1 Samuel 10 >

1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
Då tog Samuel ett oljoglas, och göt uppå hans hufvud, och kysste honom, och sade: Ser du, att Herren hafver smort dig till en Första öfver hans arfvedel?
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
När du nu går ifrå mig, så finner du två män vid Rachels graf i BenJamins gränso i Zelzah; de skola säga till dig: Åsninnorna äro funna, der du efter gången äst, dem att söka; och si, din fader hafver öfvergifvit tänka på åsnarna, och sörjer om eder, och säger: Hvad skall jag göra om min son?
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
Och när du går dädan fram bätter, så kommer du till den eken Thabor; der skola tre män råka dig, som gå upp till Gud i BethEl, den ene bär tre kid, den andre tre bröd, den tredje en flasko med vin.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
Och de skola helsa dig vänliga, och gifva dig tu bröd, det skall du taga af deras händer.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Sedan kommer du på Guds hög, der de Philisteers lägre är; och när du kommer derin i staden, möta dig en hop med Propheter, som komne äro af höjdene, och för dem en psaltare, och trumma, och pipa, och harpa, och de prophetera.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
Och Herrans Ande skall komma öfver dig, att du propheterar med dem; och då skall du varda en annar man.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
När nu dessa tecknen komma dig, så gör allt det dig för handen kommer; ty Gud är med dig.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
Men du skall gå neder för mig till Gilgal; si, der vill jag komma neder till dig, till att offra bränneoffer och tackoffer. I sju dagar skall du bida, tilldess jag kommer till dig, och undervisar dig hvad du göra skall.
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Och som han vände ryggen åt Samuel, och gick ifrå honom, gaf honom Gud ett annat hjerta; och all dessa tecknen kommo på den dagen.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Och då de kommo till högen, si, då mötte honom en hop Propheter; och Guds Ande kom öfver honom, så att han propheterade med dem.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Då de nu alle sågo honom, som tillförene hade känt honom, att han propheterade med Propheterna, sade de till hvarannan: Hvad är Kis son tillkommet? Är ock Saul ibland Propheterna?
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
Och en svarade der, och sade: Ho är deras fader? Dädan är det ordspråket kommet: Är ock Saul ibland Propheterna?
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Och då han utpropheterat hade, kom han upp till höjdena.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Men Sauls faderbroder sade till honom, och till hans dräng: Hvart voren I gånge? De svarade: Till att uppsöka åsnar; och då vi såge att vi funne dem icke, komme vi till Samuel.
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Då sade Sauls faderbroder: Säg mig, hvad sade eder Samuel?
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
Saul svarade sinom faderbroder: Han sade oss, att åsninnorna funna voro; men om Konungariket sade han honom intet, hvad Samuel sagt hade.
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
Samuel kallade folket in till Herran i Mizpa;
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
Och sade till Israels barn: Så säger Herren Israels Gud: Jag förde eder utur Egypten, och frälste eder utu de Egyptiers hand, och utur all Konungarikes hand som eder tvingade.
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
Och I hafven i dag förkastat edar Gud, som eder utur all edor olycko och bedröfvelse hulpit hafver, och sägen till honom: Sätt en Konung öfver oss. Nu väl, så går nu fram för Herran efter edor slägter och hus.
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
Som nu Samuel framhade alla Israels slägter, vardt råkadt inpå BenJamins slägt.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
Och som han hade BenJamins slägt fram med hennes ätter, vardt råkadt inpå Matri ätt, och råkade inpå Saul, Kis son; och de sökte efter honom, men de funno honom intet.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Då frågade de åter Herran, om han ännu skulle ditkomma? Herren svarade: Si, han hafver undstungit sig under ett fat.
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Då lupo de dit, och hemtade honom. Och då han gick fram ibland folket, var han hufvudet högre än allt folket.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
Och Samuel sade till allt folket: Här sen I, hvem Herren utvalt hafver; ty hans like är icke ibland allt folket. Då gladdes allt folket, och sade: Lycka ske Konungenom.
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
Och Samuel sade folkena all riksens rätt, och skref det uti ena bok, och ladet inför Herran. Och Samuel lät allt folket gå, hvar och en i sitt hus.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
Och Saul gick ock hem till Gibea, och en del af hären gick med honom, hvilkes hjerta Gud rörde.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
Men somlige Belials barn sade: Hvad skulle denne hjelpa oss? Och föraktade honom, och båro honom inga gåfvor; men han låts som han intet hörde det.

< 1 Samuel 10 >