< 1 Samuel 10 >

1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
USamuweli wasethatha umfuma wamafutha, wawathela ekhanda lakhe, wamanga, wathi: Angithi kungoba iNkosi ikugcobele ukuthi ube ngumbusi phezu kwelifa layo?
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
Ekusukeni kwakho kimi lamuhla uzafica abantu ababili engcwabeni likaRasheli emngceleni wakoBhenjamini eZeliza; njalo bazakuthi kuwe: Obabhemikazi obuyebadinga sebetholiwe, khangela-ke, uyihlo useyekele udaba labobabhemikazi, usenqinekela lina esithi: Ngizayenzelani indodana yami?
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
Nxa usudlule lapho waya phambili, uzafika esihlahleni se-okhi seThabhori; lalapho uzahlangana labantu abathathu besenyuka besiya kuNkulunkulu eBhetheli, omunye ephethe amazinyane amathathu, lomunye ephethe amaqebelengwana ezinkwa amathathu, lomunye ephethe imbodlela yewayini.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
Bazakubuza ngempilo, bakunike izinkwa ezimbili, ozazithatha esandleni sabo.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Emva kwalokho uzafika eqaqeni lukaNkulunkulu lapho okuhlala khona ibutho lenqaba yamaFilisti; kuzakuthi-ke, nxa ufika lapho emzini uzahlangana lexuku labaprofethi besehla endaweni ephakemeyo, laphambi kwabo kulogubhu lwezintambo, lesigubhu, lomhlanga, lechacho, beprofetha.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
LoMoya kaNkulunkulu uzafika ngamandla phezu kwakho, uprofethe kanye labo, uphendulwe ube ngomunye umuntu.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
Kuzakuthi-ke lapho lezizibonakaliso zikufikela, wena wenze lokho isandla sakho esizakuthola, ngoba uNkulunkulu ulawe.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
Uzakwehla phambi kwami uye eGiligali; khangela-ke, ngizakwehlela kuwe ukuze nginikele iminikelo yokutshiswa, ngihlabe imihlatshelo yeminikelo yokuthula. Uzalinda insuku eziyisikhombisa ngize ngifike kuwe, ngikutshele lokho ozakwenza.
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Kwasekusithi lapho esefulathele ukuthi asuke kuSamuweli, uNkulunkulu wamnika enye inhliziyo; lazo zonke lezizibonakaliso zeza mhlalokho.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Lapho sebefikile khona eqaqeni, khangela, ixuku labaprofethi lamhlangabeza; uMoya kaNkulunkulu wasefika ngamandla phezu kwakhe, waprofetha phakathi kwabo.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Kwasekusithi bonke ababemazi mandulo bebona ukuthi, khangela, uprofetha labaprofethi, abantu bathi, omunye komunye: Kuyini lokhu okwehlele indodana kaKishi? Kanti uSawuli laye uphakathi kwabaprofethi?
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
Kwasekuphendula umuntu owakhona wathi: Kanti ngubani uyise wabo? Ngakho kwasekusiba yisaga ukuthi: Kanti uSawuli laye uphakathi kwabaprofethi?
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Eseqedile ukuprofetha wafika endaweni ephakemeyo.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Uyise omncinyane kaSawuli wathi kuye lencekwini yakhe: Beliye ngaphi? Wasesithi: Ukuyadinga obabhemikazi; lapho sesibona ukuthi kabakho sasesifika kuSamuweli.
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Uyise omncinyane kaSawuli wathi: Ake ungitshele ukuthi utheni kini uSamuweli?
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
USawuli wasesithi kuyise omncinyane: Usitshelile sibili ukuthi obabhemikazi sebetholakele. Kodwa udaba lombuso akhuluma ngalo uSamuweli kamtshelanga.
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
USamuweli wasebizela abantu ndawonye eNkosini eMizipa;
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
wathi kubantwana bakoIsrayeli: Itsho njalo iNkosi uNkulunkulu kaIsrayeli: Mina ngamenyusa uIsrayeli eGibhithe, ngalikhulula esandleni samaGibhithe lesandleni sayo yonke imibuso eyalicindezelayo.
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
Kodwa lamuhla lina limalile uNkulunkulu wenu, yena ngokwakhe owalisindisayo engozini zonke zenu lensizini zenu; laselisithi kuye: Hatshi, beka inkosi phezu kwethu. Ngakho-ke manini phambi kweNkosi ngezizwe zenu langezinkulungwane zenu.
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
USamuweli wasesondeza zonke izizwe zakoIsrayeli; njalo isizwe sakoBhenjamini sabanjwa.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
Wasesondeza isizwe sakoBhenjamini ngensendo zaso, losendo lwakoMatiri lwabanjwa, loSawuli indodana kaKishi wabanjwa. Kuthe bemdinga katholakalanga.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Ngakho babuya babuza eNkosini ukuthi lowomuntu usezafika lapha yini? INkosi yasisithi: Khangelani, ucatshile empahleni.
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Basebegijima bamlanda khona; lapho esemi phakathi kwabantu, wayemude kulabo bonke abantu kusukela ehlombe lakhe kusiya phezulu.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
USamuweli wasesithi kubo bonke abantu: Liyambona yini lowo iNkosi emkhethileyo, ukuthi kakho loyedwa onjengaye kubo bonke abantu? Bonke abantu basebememeza bathi: Kayiphile inkosi!
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
USamuweli wasebatshela abantu indlela yombuso, wawubhala egwalweni, walubeka phambi kweNkosi. USamuweli wasebayekela bonke abantu bahamba, wonke waya endlini yakhe.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
USawuli laye wasesiya endlini yakhe eGibeya; kwasekuhamba laye amaqhawe onhliziyo zawo uNkulunkulu wayezithintile.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
Kodwa abantwana bakaBheliyali bathi: Uzasisindisa njani lo? Basebemdelela, kabamphathelanga sipho; kodwa wazithulela.

< 1 Samuel 10 >