< 1 Samuel 10 >
1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
Tad Samuēls ņēma eļļas trauciņu un to izlēja uz viņa galvu un to skūpstīja un sacīja: vai Tas Kungs tevi nav svaidījis par valdnieku pār Savu mantību?
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
Kad tu šodien no manis aiziesi, tad tu atradīsi divus vīrus pie Rahēles kapa, pie Benjamina robežām Celcā, tie uz tevi sacīs: tās ēzeļu mātes ir atrastas, ko tu esi izgājis meklēt, un redzi, tavs tēvs no tām ēzeļu mātēm ir mitējies un bēdājās jūsu pēc, sacīdams: ko lai es daru sava dēla pēc.
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
Un no turienes vēl tālāki gājis, tu nāksi pie Tābor ozola, tur tevi sastaps trīs vīri, kas uz Bēteli iet pie Dieva; viens nesīs trīs kazlēnus un otrs nesīs trīs maizes klaipus un trešais nesīs trauku ar vīnu.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
Un tie tevi apsveicinās laipnīgi un tev dos divas maizes; tās ņem no viņu rokām.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Pēc tam tu nāksi uz to Dieva pakalnu, kur Fīlistu lēģeri stāv, un kad tu pilsētā nāksi, tad tu sastapsi vienu praviešu pulku no kalna nākam, un viņu priekšā stīgas un bungas un stabules un kokles, un tie runās praviešu vārdus.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
Un Tā Kunga Gars uz tevi nāks, ka tu līdz ar tiem praviešu vārdus runāsi, un tad tu tapsi pārvērsts par citu vīru.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
Kad nu šās zīmes tev notiks, tad dari, kā tava roka māk, jo Dievs ir ar tevi.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
Bet tev būs noiet manā priekšā uz Gilgalu, un redzi, es nonākšu pie tevis, dedzināmos upurus upurēt un pateicības upurus upurēt. Septiņas dienas tev tur būs gaidīt, tiekams es pie tevis nāku un tev saku, kas tev jādara.
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Un notikās, kad viņš savu muguru grieza, no Samuēla aiziet, tad Dievs viņam deva citu sirdi, un visas tās zīmes notika tai pašā dienā.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Tiem nu tur pie tā pakalna nākot, redzi, tad praviešu pulks viņu sastapa, un Tā Kunga Gars nāca pār viņu, un viņš runāja praviešu vārdus viņu starpā.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Un visi, kas viņu citkārt bija pazinuši, kad tie to redzēja ar tiem praviešiem praviešu vārdus runājam, tad tie ļaudis cits uz citu sacīja: kas tam Ķisa dēlam noticis? Vai Sauls arīdzan starp praviešiem?
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
Tad viens vīrs no turienes atbildēja un sacīja: kas tad ir šo tēvs? Tādēļ tas sakāms vārds ir cēlies: Vai Sauls arīdzan starp praviešiem?
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Un viņš beidza praviešu vārdus runāt, un nāca uz to kalnu.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Tad Saula tēva brālis sacīja uz viņu un uz viņa puisi: kur bijāt gājuši? Viņš sacīja: tās ēzeļu mātes meklēt, un kad mēs redzējām, ka nav, tad mēs nācām pie Samuēla.
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Tad Saula tēva brālis sacīja: saki man jel, ko jums Samuēls ir teicis?
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
Un Sauls sacīja uz savu tēva brāli: viņš mums patiesi ir sacījis, tās ēzeļu mātes esam atrastas; bet par to ķēniņa godu, par ko Samuēls bija runājis, viņš tam nekā nesacīja. -
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
Tad Samuēls tos ļaudis sasauca Tā Kunga priekšā uz Micpu.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
Un viņš sacīja uz Israēla bērniem: tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: Es Israēli esmu izvedis no ēģiptiešu rokas un no visu ķēniņu rokas, kas jūs spaidīja;
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
Bet jūs šodien savu Dievu esat atmetuši, kas jūs no visām jūsu bēdām un izbailēm ir atpestījis, un uz Viņu esat sacījuši: “Cel pār mums ķēniņu.” Nu tad, stājaties Tā Kunga priekšā pēc savām ciltīm un pēc saviem tūkstošiem.
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
Kad nu Samuēls visām Israēla ciltīm bija licis klātu nākt, tad Benjamina cilts tapa iezīmēta.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
Un kad viņš Benjamina ciltij pēc viņas radiem lika klātu nākt, tad Matra radi tapa iezīmēti, un Sauls, Ķisa dēls, tapa iezīmēts. Un tie to meklēja, bet neatrada.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Tad tie To Kungu vaicāja: vai vēl kāds še atnācis? Tad Tas Kungs sacīja: redzi, viņš starp tiem traukiem ir paslēpies.
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Tad tie steidzās un viņu no turienes atveda, un viņš stājās ļaužu vidū, un viņš bija veselu galvu lielāks nekā visi ļaudis.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
Tad Samuēls sacīja uz visiem ļaudīm: vai jūs redzat, kādu Tas Kungs ir izredzējis? Jo neviens nav tāds, kā viņš, starp visiem ļaudīm. Tad visi ļaudis gavilēja un sacīja: lai dzīvo ķēniņš!
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
Tad Samuēls uz tiem ļaudīm teica to ķēniņa tiesu un to sarakstīja grāmatā un nolika Tā Kunga priekšā. Un Samuēls atlaida visus ļaudis, ikvienu uz viņa mājām.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
Un Sauls gāja arīdzan mājās uz Ģibeju, un viņam gāja līdz pulks vīru, kam Dievs sirdi bija kustinājis.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
Bet kādi nelieši sacīja: ko šis mums palīdzēs? Un tie viņu nicināja un viņam nenesa dāvanas. Bet viņš nelikās to dzirdējis.