< 1 Samuel 10 >
1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
Ningĩ Samũeli akĩoya kĩnandũ kĩa maguta, akĩmaitĩrĩria Saũlũ mũtwe, na akĩmũmumunya, akĩmwĩra atĩrĩ, “Githĩ Jehova ndagũitĩrĩirie maguta ũtuĩke mũtongoria wa igai rĩake?
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
Ũmũthĩ twatigana, nĩũgũcemania na andũ eerĩ hakuhĩ na mbĩrĩra ya Rakeli, kũu Zeliza mũhaka-inĩ wa Benjamini. Nĩmarĩkwĩra atĩrĩ, ‘Ndigiri iria wathiire gũcaria-rĩ, nĩcionekete. Na rĩu thoguo nĩatigĩte gwĩciiria ũhoro wacio na nĩamakĩte nĩ ũndũ waku. Aroria atĩrĩ, “Ngwĩka atĩa nĩ ũndũ wa mũrũ wakwa?”’
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
“Ningĩ kuuma kũu nĩũgũthiĩ na mbere ũkinye mũtĩ-inĩ ũrĩa mũnene wa Taboru. Nĩũgũcemania na andũ atatũ makĩambata mathiĩ kũu Betheli kũrĩ Ngai. Ũmwe arĩkorwo akuuĩte tũũri tũtatũ, ũrĩa ũngĩ mĩgate ĩtatũ, na ũrĩa ũngĩ mondo ya ndibei.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
Nao makũgeithie na makũhe mĩgate ĩĩrĩ, ĩrĩa ũrĩamũkĩra kuuma kũrĩ o.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
“Thuutha ũcio ũthiĩ nginya Gibea ya Ngai, kũrĩa kũrĩ kambĩ ya Afilisti ya arangĩri. Na wakuhĩrĩria itũũra rĩu-rĩ, nĩũgũcemania na mũtongoro wa gĩkundi kĩa anabii maikũrũkĩte makiuma handũ hau hatũũgĩru marĩ na inanda cia kĩnũbi, na tũhembe, na mĩtũrirũ, na inanda cia mũgeeto ikĩgambio mbere yao, na nĩmegũkorwo makĩratha mohoro.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
Roho wa Jehova nĩegũũka igũrũ rĩaku na hinya, na nĩũkũratha mohoro hamwe nao; nawe nĩũkũgarũrwo ũtuĩke mũndũ ũngĩ.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
Marũũri macio maarĩkia kũhingio-rĩ, ĩka o ũrĩa guoko gwaku kũngĩhota gwĩka, nĩgũkorwo Ngai arĩ hamwe nawe.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
“Ikũrũka mbere yakwa nginya Giligali. Ti-itherũ nĩngaikũrũka njũke kũrĩ we ndute magongona ma njino na maruta ma ũiguano. No no nginya weterere mĩthenya mũgwanja nginya njũke harĩ we ngwĩre ũrĩa wagĩrĩirwo nĩ gwĩka.”
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Na rĩrĩa Saũlũ aahũndũkaga matigane na Samũeli-rĩ, Ngai akĩgarũra ngoro ya Saũlũ, namo marũũri macio mothe makĩhingio mũthenya o ro ũcio.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Rĩrĩa maakinyire Gibea-rĩ, mũtongoro wa anabii ũkĩmũtũnga; nake Roho wa Ngai agĩũka igũrũ rĩake na hinya, agĩĩturanĩra nao, na akĩratha mohoro.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Rĩrĩa andũ arĩa othe maamũũĩ maamuonire akĩratha mohoro me hamwe na anabii, makĩũrania atĩrĩ, “Nĩ ũndũ ũrĩkũ ũyũ wĩkĩkĩte kũrĩ mũrũ wa Kishu? Kaĩ Saũlũ atuĩkĩte wa thiritũ ya anabii?”
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
Mũndũ watũũraga kũu agĩcookia atĩrĩ, “Nake ithe wao nũũ?” Naguo ũndũ ũcio ũgĩtuĩka ũndũ ũngĩtuĩka thimo, gũkooragio atĩrĩ, “Saũlũ o nake nĩ wa gĩkundi kĩa anabii?”
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Thuutha wa Saũlũ gũtiga kũratha mohoro, agĩthiĩ handũ hau hatũũgĩru.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Hĩndĩ ĩyo ithe mũnini wa Saũlũ akĩũria Saũlũ na ndungata yake atĩrĩ, “Mũraarĩ kũ?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Gwetha ndigiri, no rĩrĩa twaciagire tũgĩthiĩ kũrĩ Samũeli.”
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Ithe mũnini wa Saũlũ akiuga atĩrĩ, “Njĩĩra ũrĩa Samũeli aakwĩrire.”
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
Saũlũ agĩcookia atĩrĩ, “Nĩatwĩrire o wega atĩ ndigiri nĩcionekete.” No ndeerire ithe mũnini ũrĩa Samũeli aamwĩrire ũhoro ũkoniĩ ũthamaki.
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
Samũeli agĩtũmanĩra andũ a Isiraeli mongane harĩ Jehova kũu Mizipa,
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga: ‘Niĩ nĩ niĩ ndaarutire Isiraeli, ngĩmambatia kuuma bũrũri wa Misiri, na nĩ niĩ ndaamũkũũrire kuuma watho-inĩ wa Misiri, na mothamaki-inĩ mothe marĩa maamũhinyagĩrĩria.’
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
No rĩrĩ, nĩmũregete Ngai wanyu, ũrĩa ũmũhonokagia kuuma kũrĩ mĩnyamaro na mathĩĩna manyu mothe, na mũkoiga atĩrĩ, ‘Aca, tũhe mũthamaki atũthamakagĩre.’ Nĩ ũndũ ũcio rĩu mwĩneanei mbere ya Jehova ta ũrĩa mĩhĩrĩga yanyu na mbarĩ cianyu itariĩ.”
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
Rĩrĩa Samũeli aarehire mĩhĩrĩga yothe ya Isiraeli hakuhĩ-rĩ, mũhĩrĩga wa Benjamini nĩguo wathuurirwo.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
Ningĩ akĩrehithia mũhĩrĩga wa Benjamini hau mbere, mbarĩ o mbarĩ, na mbarĩ ya Matiri nĩyo yathuurirwo. Mũthia-inĩ Saũlũ mũrũ wa Kishu agĩthuurwo. No maamwetha matiigana kũmuona.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Nĩ ũndũ ũcio magĩtuĩria ũhoro makĩria harĩ Jehova, “Mũndũ ũcio nĩokĩte gũkũ?” Nake Jehova akiuga atĩrĩ, “Ĩĩ, ehithĩte harĩa indo ciigĩtwo.”
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Nao magĩtengʼera, makĩmũgĩĩra, na aarũgama gatagatĩ ka andũ-rĩ, nĩwe warĩ mũraihu gũkĩra andũ arĩa angĩ othe.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
Samũeli akĩĩra andũ othe atĩrĩ, “Nĩmuona mũndũ ũrĩa Jehova athuurĩte? Gũtirĩ mũndũ ũhaana take harĩ andũ aya othe.” Nao andũ makĩanĩrĩra makiuga atĩrĩ, “Mũthamaki arotũũra ihinda iraaya!”
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
Samũeli agĩtaarĩria andũ mawatho ma ũthamaki. Nake akĩmaandĩka gĩkũnjo-inĩ akĩmaiga mbere ya Jehova. Ningĩ Samũeli akĩĩra andũ mathiĩ, o mũndũ gwake mũciĩ.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
Saũlũ o nake agĩthiĩ gwake mũciĩ kũu Gibea, oimagarĩtio nĩ andũ njamba arĩa ngoro ciao ciahutĩtio nĩ Ngai.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
No andũ amwe a thogothogo makiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ aahota atĩa gũtũhonokia?” Makĩmũnyarara na matiigana kũmũrehera iheo. Nowe Saũlũ agĩĩkirĩra ki.