< 1 Samuel 10 >

1 Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
Alors, Samuel prit une petite fiole d'huile, il la vida sur sa tête, il le baisa, et lui dit: Le Seigneur ne vient-il pas de t'oindre pour que tu sois chef de son peuple Israël? Tu règneras sur le peuple du Seigneur; tu le sauveras des mains de ses ennemis. Voici le signe à quoi tu reconnaîtras que tu es oint par le Seigneur, comme roi de son héritage:
2 Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
Aussitôt qu'aujourd'hui tu te seras éloigné de moi, tu rencontreras, près du sépulcre de Rachel, en la montagne de Benjamin, deux hommes, courant à grands pas; ils te diront: On a retrouvé les ânesses que vous êtes allés chercher; ton père ne compte plus pour rien les ânesses, et il prépare grande chère, à cause de vous, disant: Que ferai-je pour mon fils?
3 “Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
Tu partiras de ce lieu; ensuite, tu iras jusqu'au chêne de Thabor; là, tu trouveras trois hommes montant vers le Seigneur en Béthel, et portant: l'un, trois chevreaux; le second, trois corbeilles pleines de pains; le troisième, une outre de vin.
4 Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
Ils te demanderont si tu vas bien, et te donneront deux de leurs pains, que tu accepteras.
5 “Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Après cela, tu arriveras sur la colline de Dieu, où les Philistins ont un tertre fortifié, et où réside le Nasib philistin; quand tu y seras entré, tu rencontreras un chœur de prophètes descendant du haut lieu, précédés d'instruments à cordes, de tambours et de flûtes; tous prophétisant.
6 Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
Et l'esprit du Seigneur s'élancera sur toi; tu prophétiseras avec eux, et tu seras devenu un autre homme.
7 Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
Lorsque tous ces signes seront venus, fais tout ce que te suggérera l'occasion, parce que Dieu sera avec toi.
8 “Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
Tu descendras en face de Galgal, et je te rejoindrai pour offrir un holocauste et des hosties pacifiques; tu attendras mon arrivée sept jours; ensuite, je t'instruirai de tout ce que tu auras à faire.
9 Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
Dès que Saül se fut retourné pour s'éloigner de Samuel, Dieu changea son cœur, et, ce jour-là, tous les signes arrivèrent.
10 Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
De ce lieu, il se rendit à la colline, il vit devant lui le chœur des prophètes, l'Esprit de Dieu s'élança sur lui; et il prophétisa au milieu d'eux.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
Or, tous ceux qui le connaissaient précédemment, le virent; il était au milieu des prophètes; et, parmi le peuple, chacun dit à son voisin: Qu'est-il arrivé au fils de Cis? Saül aussi est-il au nombre des prophètes?
12 Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
L'un d'eux répondit, et il dit: Quel est donc son père? A cause de cela, ce mot est passé en proverbe: Saül aussi est-il au nombre des prophètes?
13 Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
Ensuite, il cessa de prophétiser, et il alla sur la colline à l'autel.
14 Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
Et l'un de ses parents dit à lui et à son serviteur: Où êtes-vous allés? A quoi ils répondirent: Chercher les ânesses, mais nous ne les avons pas trouvées, et nous sommes entrés chez Samuel.
15 Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
Puis, le parent dit à Saül: Fais-moi connaître ce que t'a dit Samuel?
16 Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
Saül répondit: Que les ânesses étaient retrouvées; mais il ne lui dit rien de la royauté.
17 Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
Et Samuel convoqua tout le peuple devant le Seigneur, à Masphath.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
Et il dit aux fils d'Israël: Voici ce qu'a dit le Seigneur Dieu d'Israël: J'ai fait sortir d'Égypte les fils d'Israël, je vous ai tirés des mains du Pharaon, roi d'Égypte, et de tous les rois qui vous avaient opprimés.
19 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
Aujourd'hui, vous avez rejeté le Dieu qui seul est votre Sauveur en tous vos maux, en toutes vos afflictions, et vous avez dit: Nous le voulons, donne- nous un roi. Maintenant donc, présentez-vous devant le Seigneur, par tribus, par familles.
20 Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
Samuel fit alors avancer toutes les tribus d'Israël, et le sort désigna la tribu de Benjamin.
21 Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
Il fit avancer la tribu de Benjamin, par familles, et le sort désigna la famille de Mattari. On fit avancer la famille de Mattari homme par homme, et le sort désigna Saül, fils de Cis. Samuel le demanda, mais on ne le trouva point.
22 bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
Et Samuel interrogea encore le Seigneur, disant: L'homme est-il venu ici? Et le Seigneur lui répondit: Il est caché parmi les bagages.
23 Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
Il y courut, il l'y trouva, et il l'amena au milieu du peuple. Or, il dépassait le peuple entier de toute la tête.
24 Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
Samuel dit alors à tout le peuple: Avez-vous vu celui que le Seigneur s'est choisi? a-t-il parmi vous son pareil? Tout le peuple fut de son avis, et ils crièrent: Vive le roi!
25 Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
Samuel apprit ensuite au peuple les justes droits du roi; il les transcrivit en un livre qu'il déposa devant le Seigneur. Enfin, Samuel congédia tout le peuple, et chacun retourna en sa demeure.
26 Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
Saül rentra dans sa maison à Gabaa; et les hommes vaillants, dont Dieu avait touché le cœur pour qu'ils s'unissent à Saül, l'accompagnèrent.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.
Mais les fils de pestilence dirent: Est-ce celui-là qui nous sauvera? Et ils le méprisèrent, et ils ne lui portèrent point de présents.

< 1 Samuel 10 >