< 1 Samuel 1 >

1 Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
Byl muž nějaký z Ramataim Zofim, s hory Efraim, jehož jméno bylo Elkána, syn Jerochama, syna Elihu, syna Tohu, syna Zuf Efratejského.
2 Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
A ten měl dvě ženy, jméno jedné Anna, a jméno druhé Penenna. Měla pak Penenna děti, ale Anna neměla dětí.
3 Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
I chodíval muž ten z města svého každého roku, aby se klaněl a obětoval Hospodinu zástupů, do Sílo, kdež byli dva synové Elí, Ofni a Fínes, kněží Hospodinovi.
4 Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
Když pak přišel den, v němž obětoval Elkána, dal Penenně manželce své, a všechněm synům i dcerám jejím díly.
5 Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
Anně pak dal díl jeden výborný, nebo Annu miloval, ale Hospodin zavřel byl život její.
6 Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
Přesto kormoutila ji také velmi protivnice její, toliko aby ji popouzela, proto že Hospodin zavřel byl život její.
7 Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
To když činíval každého roku, a Anna též chodívala do domu Hospodinova, tak ji kormoutívala protivnice; ona pak plakávala a nic nejídala.
8 Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
Tedy řekl jí Elkána muž její: Anna, proč pláčeš? A proč nejíš? Proč tak truchlí srdce tvé? Zdaliž já nejsem tobě lepší nežli deset synů?
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
Vstala tedy Anna, když pojedli v Sílo a napili se; a Elí kněz seděl na stolici u veřeje chrámu Hospodinova.
10 Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Ona pak jsuci v hořkosti srdce, modlila se Hospodinu a plakala velmi.
11 Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
A učinila slib, řkuci: Hospodine zástupů, jestliže vzhlédneš na trápení děvky své a rozpomeneš se na mne, a nezapomeneš na děvku svou, ale dáš služebnici své plod pohlaví mužského: tedy dám jej tobě, Hospodine, po všecky dny života jeho, a břitva nevejde na hlavu jeho.
12 Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
I stalo se, když se dlouho modlila před Hospodinem, že Elí pozor měl na ústa její.
13 Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
Ale Anna mluvila v srdci svém; toliko rtové její se hýbali, hlasu pak jejího nebylo slyšeti. I domníval se Elí, že by opilá byla.
14 Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
Protož řekl jí Elí: Dlouho-liž budeš opilá? Vystřízvěj z vína svého.
15 Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
Odpověděla Anna, řkuci: Nikoli, pane můj, žena jsem ducha truchlivého, ani vína ani nápoje opojného jsem nepila, ale vylila jsem duši svou před Hospodinem.
16 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
Nepřirovnávejž děvky své k ženě bezbožné, nebo z velikého myšlení a hořkosti své mluvila jsem až dosavad.
17 Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
Jíž odpověděl Elí, řka: Jdiž u pokoji, a Bůh Izraelský dejž tobě k prosbě tvé, zač jsi ho prosila.
18 Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
I řekla: Ó by nalezla děvka tvá milost před očima tvýma! Tedy odšedši žena cestou svou, pojedla, a tvář její nebyla více smutná.
19 Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
I vstali velmi ráno, a poklonu učinivše před Hospodinem, navrátili se, a přišli do domu svého do Ramata. Poznal pak Elkána Annu manželku svou, a Hospodin rozpomenul se na ni.
20 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
I stalo se po vyplnění dnů, jakž počala Anna, že porodila syna, a nazvala jméno jeho Samuel; nebo řekla: Vyprosila jsem ho na Hospodinu.
21 Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
Šel pak muž ten Elkána se vší čeledí svou, aby obětoval Hospodinu obět výroční a slib svůj.
22 Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
Ale Anna nešla, nebo řekla muži svému: Až odchovám dítě, tehdy povedu je, aby ukáže se před Hospodinem, zůstalo tam na věky.
23 Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
I řekl jí Elkána muž její: Učiň, cožť se dobrého vidí, zůstaň, dokudž neodchováš jeho. Ó by toliko utvrdil Hospodin slovo své! A tak zůstala žena, a krmila syna svého, až jej i odchovala.
24 Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
Potom, když ho odchovala, vedla jej s sebou, se třmi volky a jednou efi mouky a nádobou vína, i uvedla jej do domu Hospodinova v Sílo; dítě pak ještě bylo malé.
25 Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
Tedy zabili volka a přivedli dítě k Elí.
26 Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
Ona pak řekla: Poslyš mne, pane můj. Jako jest živa duše tvá, pane můj, já jsem žena ta, kteráž jsem stála tuto s tebou, modleci se Hospodinu.
27 Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
Za toto dítě jsem prosila, a dal mi Hospodin k prosbě mé to, čehož jsem prosila od něho.
28 Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.
Protož já také oddávám jej Hospodinu; po všecky dny, v nichž živ bude, oddanýť jest Hospodinu. A učinil tu poklonu Hospodinu.

< 1 Samuel 1 >