< 1 Peter 4 >

1 Ǹjẹ́ bí Kristi ti jìyà fún wa nípa ti ará, irú kan náà ni kí ẹ̀yin fi hámọ́ra; nítorí ẹni tí ó bá ti jìyà nípa ti ara, ó ti bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Ainsi donc, puisque Christ a souffert pour nous dans la chair, armez-vous aussi du même esprit; car celui qui a souffert dans la chair a cessé de pécher,
2 Kí ẹ̀yin má ṣe fi ìgbà ayé yín ìyókù wà nínú ara mọ́ sí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ènìyàn bí kò ṣe sí ìfẹ́ Ọlọ́run.
afin que vous ne viviez plus le reste de votre temps dans la chair selon les convoitises des hommes, mais selon la volonté de Dieu.
3 Nítorí ìgbà tí ó ti kọjá ti tó fún ṣíṣe ìfẹ́ àwọn aláìkọlà, rínrìn nínú ìwà wọ̀bìà, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, ọtí àmupara, ìréde òru, kíkó ẹ̀gbẹ́ ọ̀mùtí, àti ìbọ̀rìṣà tí í ṣe ohun ìríra.
Car nous avons assez passé notre temps à satisfaire les désirs des païens, et à marcher dans l'impudicité, les convoitises, les ivrogneries, les orgies, les carrousels, et les idolâtries abominables.
4 Èyí tí ó yà wọ́n lẹ́nu pé ẹ̀yin kò ba wọn súré sínú irú àṣejù ìwà wọ̀bìà wọ́n, tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ yín ní búburú.
Ils trouvent étrange que vous ne couriez pas avec eux dans les mêmes excès d'émeute, et ils parlent mal de vous.
5 Àwọn ẹni tí yóò jíyìn fún ẹni tí ó ti múra láti ṣe ìdájọ́ alààyè àti òkú.
Ils rendront compte à celui qui est prêt à juger les vivants et les morts.
6 Nítorí èyí ní a sá ṣe wàásù ìyìnrere fún àwọn òkú, kí a lè ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nípa ti ara, ṣùgbọ́n kí wọ́n lè wà láààyè si Ọlọ́run nípa tí Ẹ̀mí.
Car c'est dans ce but que la Bonne Nouvelle a été annoncée même aux morts, afin qu'ils soient jugés comme des hommes dans la chair, mais qu'ils vivent comme devant Dieu dans l'esprit.
7 Ṣùgbọ́n òpin ohun gbogbo kù sí dẹ̀dẹ̀; nítorí náà kí ẹ̀yin wà ní àìrékọjá, kí ẹ sì máa ṣọ́ra nínú àdúrà.
Mais la fin de toutes choses est proche. C'est pourquoi, soyez sains d'esprit, maîtres de vous-mêmes, et sobres dans la prière.
8 Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tí ó gbóná láàrín ara yín, nítorí ìfẹ́ ni ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
Et surtout, soyez sérieux dans votre amour entre vous, car l'amour couvre une multitude de péchés.
9 Ẹ máa ṣe ara yín ni àlejò láìsí ìkùnsínú.
Soyez accueillants les uns envers les autres, sans vous plaindre.
10 Bí olúkúlùkù ti rí ẹ̀bùn gbà, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ máa ṣe ìpín fún ni rẹ̀ láàrín ara yín, bí ìríjú rere tí onírúurú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
Comme chacun a reçu un don, employez-vous à vous servir les uns les autres, comme de bons gestionnaires de la grâce de Dieu sous ses diverses formes.
11 Bí ẹnikẹ́ni ba ń sọ̀rọ̀, kí o máa sọ bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bí ẹnikẹ́ni bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí ó ṣe é bí agbára tí Ọlọ́run fi fún un, kí a lè máa yin Ọlọ́run lógo ní ohun gbogbo nípa Jesu Kristi, ẹni tí ògo àti ìjọba wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
Si quelqu'un parle, que ce soit comme si c'était les paroles mêmes de Dieu. Si quelqu'un sert, que ce soit avec la force que Dieu fournit, afin qu'en toutes choses Dieu soit glorifié par Jésus-Christ, à qui appartiennent la gloire et la domination dans les siècles des siècles. Amen. (aiōn g165)
12 Olùfẹ́, ẹ má ṣe ka ìdánwò gbígbóná ti ń bẹ láàrín yín láti dán yín wò bi ẹni pé ohun àjèjì ni ó dé bá yín.
Bien-aimés, ne vous étonnez pas de l'épreuve ardente qui vous a été imposée pour vous éprouver, comme si une chose étrange vous arrivait.
13 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ̀yin tí jẹ́ alábápín ìyà Kristi, ẹ máa yọ̀, kí ẹ̀yin lè yọ ayọ̀ púpọ̀ nígbà tí a bá fi ògo rẹ̀ hàn.
Mais parce que vous participez aux souffrances de Christ, réjouissez-vous, afin qu'à la révélation de sa gloire vous vous réjouissiez aussi d'une joie extrême.
14 Bí a bá gàn yín nítorí orúkọ Kristi, ẹni ìbùkún ni yín: nítorí Ẹ̀mí Ògo àti ti Ọlọ́run bà lé yín.
Si l'on vous insulte pour le nom du Christ, vous êtes heureux, car l'Esprit de gloire et de Dieu repose sur vous. De leur côté, il est blasphémé, mais de votre côté, il est glorifié.
15 Ṣùgbọ́n ẹ má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú yín jìyà bí apànìyàn, tàbí bí olè, tàbí bí olùṣe búburú, tàbí bí ẹni tí ń tojú bọ̀ ọ̀ràn ẹlòmíràn.
Que nul de vous ne souffre comme meurtrier, ou voleur, ou malfaiteur, ou comme se mêlant des affaires des autres.
16 Ṣùgbọ́n bí ó bá jìyà bí Kristiani kí ojú má ṣe tì í, ṣùgbọ́n kí ó kúkú yin Ọlọ́run lógo nítorí ti o orúkọ yìí.
Mais si l'un de vous souffre parce qu'il est chrétien, qu'il n'ait pas honte, mais qu'il glorifie Dieu à ce sujet.
17 Nítorí ti ìgbà náà dé, tí ìdájọ́ yóò bẹ̀rẹ̀ láti ilé Ọlọ́run wá, bí ó bá sì tètè tí ọ̀dọ̀ wa bẹ̀rẹ̀, ìgbẹ̀yìn àwọn tí kò gba ìyìnrere Ọlọ́run yó ha ti rí?
Car le temps est venu où le jugement doit commencer par la maison de Dieu. S'il commence d'abord par nous, qu'arrivera-t-il à ceux qui n'obéissent pas à la Bonne Nouvelle de Dieu?
18 “Bí ó bá ṣe pé agbára káká ni a fi gba olódodo là, níbo ni aláìwà-bí-Ọlọ́run àti ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò yọjú sí?”
« S'il est difficile pour le juste d'être sauvé, qu'arrivera-t-il à l'impie et au pécheur? »
19 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwọn tí ń jìyà gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run ni ṣíṣe rere, fi ọkàn wọn lè Ẹlẹ́dàá olóòtítọ́ lọ́wọ́.
Que ceux-là aussi qui souffrent selon la volonté de Dieu en faisant le bien lui confient leurs âmes, comme à un Créateur fidèle.

< 1 Peter 4 >