< 1 Peter 3 >
1 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín; pé, bí ẹnikẹ́ni ba tilẹ̀ ń ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, kí a lè jèrè wọn láì sọ̀rọ̀ nípa ìwà àwọn aya wọn.
Także i żony! bądźcie poddane mężom swoim, aby i ci, którzy nie wierzą słowu, przez pobożne obcowanie żon, bez słowa byli pozyskani,
2 Nígbà tí wọ́n bá ń wo ìwà rere pẹ̀lú ẹ̀rù yín.
Obaczywszy czyste w bojaźni Bożej obcowanie wasze.
3 Kí ọ̀ṣọ́ yín má ṣe jẹ́ ọ̀ṣọ́ òde, tí irun dídì, àti wúrà lílò, tàbí ti aṣọ wíwọ̀;
Których ochędostwo niech będzie nie ono zwierzchne, w splecieniu włosów i obłożeniu się złotem, albo w ubieraniu się w szaty:
4 ṣùgbọ́n kí ó jẹ́ ẹni tí ó fi ara sin ní ọkàn, nínú ọ̀ṣọ́ àìdíbàjẹ́ ti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ àti ẹ̀mí tútù, èyí tí i ṣe iyebíye níwájú Ọlọ́run.
Ale on skryty serdeczny człowiek, zależący w nieskażeniu cichego i spokojnego ducha, który jest przed obliczem Bożem kosztowny.
5 Nítorí báyìí ni àwọn obìnrin mímọ́ ìgbàanì pẹ̀lú, tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run, fi ṣe ara wọn lọ́ṣọ̀ọ́, wọn a máa tẹríba fún àwọn ọkọ wọn.
Albowiem tak niekiedy i one święte małżonki, które nadzieję miały w Bogu, zdobiły się, będąc poddane mężom swoim.
6 Gẹ́gẹ́ bí Sara ti gbọ́ ti Abrahamu, tí ó ń pè é ní olúwa rẹ̀. Ọmọbìnrin ẹni tí ẹ̀yin jẹ́, bí ẹ̀yin bá ń ṣe rere, tí ohunkóhun kò sí dẹ́rùbà yín.
Jako Sara była posłuszną Abrahamowi nazywając go panem; której wy stałyście się córkami, gdy dobrze czynicie, nie bojąc się żadnego postrachu.
7 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ẹ̀yin ọkọ, ẹ máa fi òye ba àwọn aya yín gbé, ẹ máa fi ọlá fún aya, bi ohun èlò ti kò lágbára, àti pẹ̀lú bí àjùmọ̀jogún oore-ọ̀fẹ́ ìyè; kí àdúrà yín má bà á ní ìdènà.
Także i wy, mężowie! mieszkajcie z niemi umiejętnie, a jako mdlejszemu naczyniu niewieściemu oddawajcie uczciwość, jako też spółdziedziczkom łaski żywota, aby się modlitwy wasze nie przerywały.
8 Lákòótan, kí gbogbo yín jẹ́ onínú kan, ẹ máa bá ara yín kẹ́dùn, ẹ ní ìfẹ́ ará, ẹ máa ṣe ìyọ́nú, ẹ ni ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀.
A na koniec wszyscy bądźcie jednomyślni, spółcierpiący doległości, braterstwo miłujący, miłosierni i dobrotliwi,
9 Ẹ má ṣe fi búburú san búburú, tàbí fi èébú san èébú: ṣùgbọ́n kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ máa súre; nítorí èyí ni a pè yín sí, kí ẹ̀yin lè jogún ìbùkún.
Nie oddawając złego za złe, ani łajania za łajanie, lecz przeciwnym obyczajem dobrorzecząc, gdyż wiecie, iż na to powołani jesteście, abyście błogosławieństwo odziedziczyli.
10 Nítorí, “Ẹni tí yóò bá fẹ́ ìyè, ti yóò sì rí ọjọ́ rere, kí o pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi, àti ètè rẹ̀ mọ́ kúrò nínú sísọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Albowiem kto chce żywot miłować i oglądać dni dobre, niech pohamuje języka swego od złego, a usta jego niech nie mówią zdrady;
11 Kí ó yà kúrò nínú ibi, kí ó sì máa ṣe rere; kí ó máa wá àlàáfíà, kí ó sì máa lépa rẹ̀.
Niech się odwróci od złego, a czyni dobre; niech szuka pokoju i ściga go.
12 Nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo, etí rẹ̀ sì ṣí sí ẹ̀bẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú.”
Albowiem oczy Pańskie otworzone są na sprawiedliwych, a uszy jego ku prośbie ich; lecz oblicze Pańskie przeciwko tym, którzy czynią złe rzeczy.
13 Tá nì yóò sì ṣe yín ní ibi, bí ẹ̀yin bá jẹ́ onítara sí ohun rere?
I któż jest, co by wam złe uczynił, jeźlibyście dobrego naśladowcami byli?
14 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá jìyà nítorí òdodo, a ti bùkún yín. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù ìhàlẹ̀ wọn, kí ẹ má sì ṣe kọminú.”
Ale chociażbyście też cierpieli dla sprawiedliwości, błogosławieni jesteście, a strachu ich nie lękajcie się, ani trwożcie sobą, ale Pana Boga poświęcajcie w sercach waszych.
15 Ṣùgbọ́n ẹ bọ̀wọ̀ fún Kristi bí Olúwa ní ọkàn yín: kí ẹ sì múra tan nígbà gbogbo láti dá olúkúlùkù lóhùn tí ń béèrè ìrètí tí o ń bẹ nínú yín, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn tútù àti ìbẹ̀rù.
Bądźcie zawsze gotowi ku daniu odpowiedzi każdemu domagającemu się od was rachunku o tej nadziei, która w was jest, z cichością i z bojaźnią, mając sumienie dobre;
16 Kí ẹ máa ni ẹ̀rí ọkàn rere bí wọ́n ti ń sọ̀rọ̀ yín ní ibi, kí ojú lè ti àwọn tí ń kẹ́gàn ìwà rere yín nínú Kristi.
Aby w tem, w czem was pomawiają jako złoczyńców, zawstydzili się ci, którzy naganę dawają waszemu dobremu obcowaniu w Chrystusie.
17 Nítorí ó sàn, bí ó bá jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run, kí ẹ jìyà fún ṣíṣe rere ju fún ṣíṣe búburú lọ.
Lepiej bowiem jest, abyście dobrze czyniąc, jeźli się tak podoba woli Bożej, cierpieli, niżeli źle czyniąc.
18 Nítorí tí Kristi pẹ̀lú jìyà lẹ́ẹ̀kan nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, olóòótọ́ fún àwọn aláìṣòótọ́, kí a lè mú wa dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí a pa nínú ara, ṣùgbọ́n tí a sọ di ààyè nínú ẹ̀mí.
Bo i Chrystus raz za grzechy cierpiał, sprawiedliwy za niesprawiedliwych, aby nas przywiódł do Boga, umartwiony będąc ciałem, ale ożywiony duchem;
19 Nínú èyí tí ó lọ pẹ̀lú tí ó sì wàásù fún àwọn ẹ̀mí nínú túbú,
Przez którego i tym duchom, którzy są w więzieniu, przyszedłszy kazał.
20 àwọn tí ó ṣe aláìgbọ́ràn nígbà kan, nígbà tí sùúrù Ọlọ́run dúró pẹ́ ní sá à kan ní ọjọ́ Noa, nígbà tí wọ́n fi kan ọkọ̀ nínú èyí tí a gba ọkàn díẹ̀ là nípa omi, èyí ni ẹni mẹ́jọ.
Którzy niekiedy nieposłuszni byli, gdy raz oczekiwała Boża cierpliwość za dni Noego, kiedy korab gotowano, w którym mało (to jest ośm) dusz zachowane są w wodzie.
21 Àpẹẹrẹ èyí ti ń gbà yín là nísinsin yìí pẹ̀lú, àní ìtẹ̀bọmi, kì í ṣe wíwẹ́ èérí ti ara nù, bí kò ṣe ìdáhùn ẹ̀rí ọkàn rere si Ọlọ́run, nípa àjíǹde Jesu Kristi.
Czego teraz chrzest wzorem będąc, zbawia nas (nie składanie cielesnego plugastwa, ale obietnica spólna sumienia dobrego u Boga, ) przez zmartwychwstanie Jezusa Chrystusa,
22 Ẹni tí ó lọ sí ọ̀run, tí ó sì ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run: pẹ̀lú àwọn angẹli, àwọn aláṣẹ, àti àwọn alágbára sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
Który jest na prawicy Bożej, szedłszy do nieba, podbiwszy sobie Aniołów i zwierzchności, i mocy.