< 1 Peter 3 >
1 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín; pé, bí ẹnikẹ́ni ba tilẹ̀ ń ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, kí a lè jèrè wọn láì sọ̀rọ̀ nípa ìwà àwọn aya wọn.
Hasonlóképpen az asszonyok engedelmeskedjenek férjüknek, hogy ha közülük egyesek nem engedelmeskednének is az igének, feleségük magaviselete ige nélkül is nyerje meg őket,
2 Nígbà tí wọ́n bá ń wo ìwà rere pẹ̀lú ẹ̀rù yín.
figyelve istenfélő és tiszta életetekre.
3 Kí ọ̀ṣọ́ yín má ṣe jẹ́ ọ̀ṣọ́ òde, tí irun dídì, àti wúrà lílò, tàbí ti aṣọ wíwọ̀;
Akiknek ékessége ne legyen külsőséges: hajfonogatás, arany ékszer vagy fényes öltözet,
4 ṣùgbọ́n kí ó jẹ́ ẹni tí ó fi ara sin ní ọkàn, nínú ọ̀ṣọ́ àìdíbàjẹ́ ti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ àti ẹ̀mí tútù, èyí tí i ṣe iyebíye níwájú Ọlọ́run.
hanem a szív elrejtett embere: a szelíd és csendes lélek maradandóságával. Ez igen értékes az Isten előtt.
5 Nítorí báyìí ni àwọn obìnrin mímọ́ ìgbàanì pẹ̀lú, tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run, fi ṣe ara wọn lọ́ṣọ̀ọ́, wọn a máa tẹríba fún àwọn ọkọ wọn.
Így ékesítették magukat hajdan a szent asszonyok is, akik Istenben reménykedtek és engedelmeskedtek férjüknek.
6 Gẹ́gẹ́ bí Sara ti gbọ́ ti Abrahamu, tí ó ń pè é ní olúwa rẹ̀. Ọmọbìnrin ẹni tí ẹ̀yin jẹ́, bí ẹ̀yin bá ń ṣe rere, tí ohunkóhun kò sí dẹ́rùbà yín.
Ahogyan Sára is engedelmeskedett Ábrahámnak, urának nevezve őt. Akinek leányai lesztek, ha jót cselekedtek és nem féltek semmiféle fenyegetéstől.
7 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ẹ̀yin ọkọ, ẹ máa fi òye ba àwọn aya yín gbé, ẹ máa fi ọlá fún aya, bi ohun èlò ti kò lágbára, àti pẹ̀lú bí àjùmọ̀jogún oore-ọ̀fẹ́ ìyè; kí àdúrà yín má bà á ní ìdènà.
A férfiak hasonlóképpen megértően éljenek együtt feleségükkel, mint gyengébb nemmel, tiszteletet adva nekik, mint akik örökös társaik az élet kegyelmében, hogy imádságaitok meg ne hiúsuljanak.
8 Lákòótan, kí gbogbo yín jẹ́ onínú kan, ẹ máa bá ara yín kẹ́dùn, ẹ ní ìfẹ́ ará, ẹ máa ṣe ìyọ́nú, ẹ ni ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀.
Végül pedig legyetek mindnyájan együtt érzők, rokonérzelműek, atyafiszeretők, irgalmasak, alázatosak.
9 Ẹ má ṣe fi búburú san búburú, tàbí fi èébú san èébú: ṣùgbọ́n kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ máa súre; nítorí èyí ni a pè yín sí, kí ẹ̀yin lè jogún ìbùkún.
Ne fizessetek gonosszal a gonoszért, vagy szidalommal a szidalomért, sőt ellenkezőleg: áldást mondjatok, tudva, hogy arra hívattatok el, hogy áldást örököljetek.
10 Nítorí, “Ẹni tí yóò bá fẹ́ ìyè, ti yóò sì rí ọjọ́ rere, kí o pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi, àti ètè rẹ̀ mọ́ kúrò nínú sísọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Mert aki szeretne örülni az életnek, és jó napokat látni, őrizze meg nyelvét a gonosztól, és ajkait, hogy ne szóljanak álnokságot;
11 Kí ó yà kúrò nínú ibi, kí ó sì máa ṣe rere; kí ó máa wá àlàáfíà, kí ó sì máa lépa rẹ̀.
Forduljon el a gonosztól, és cselekedjék jót, keresse a békességet, és kövesse azt.
12 Nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo, etí rẹ̀ sì ṣí sí ẹ̀bẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú.”
Mert az Úr szeme az igazakon van, és füle azoknak könyörgésén, az Úr arca pedig a gonoszt cselekvők ellen fordul.
13 Tá nì yóò sì ṣe yín ní ibi, bí ẹ̀yin bá jẹ́ onítara sí ohun rere?
Ki az, aki bántalmaz titeket, ha a jónak követői lesztek?
14 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá jìyà nítorí òdodo, a ti bùkún yín. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù ìhàlẹ̀ wọn, kí ẹ má sì ṣe kọminú.”
De ha szenvedtek is az igazságért, boldogok vagytok. Fenyegetésüktől pedig ne féljetek, se zavarba ne essetek.
15 Ṣùgbọ́n ẹ bọ̀wọ̀ fún Kristi bí Olúwa ní ọkàn yín: kí ẹ sì múra tan nígbà gbogbo láti dá olúkúlùkù lóhùn tí ń béèrè ìrètí tí o ń bẹ nínú yín, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn tútù àti ìbẹ̀rù.
Az Úr Krisztust pedig szenteljétek meg szívetekben. Mindig készek legyetek megfelelni mindenkinek, aki számot kér tőletek a bennetek lévő reménységről
16 Kí ẹ máa ni ẹ̀rí ọkàn rere bí wọ́n ti ń sọ̀rọ̀ yín ní ibi, kí ojú lè ti àwọn tí ń kẹ́gàn ìwà rere yín nínú Kristi.
szelíden, tisztességtudóan és jó lelkiismerettel, hogy megszégyenüljenek azok, akik a Krisztusban való jó életeteket gyalázzák.
17 Nítorí ó sàn, bí ó bá jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run, kí ẹ jìyà fún ṣíṣe rere ju fún ṣíṣe búburú lọ.
Mert jobb, ha jót cselekedve, mintsem gonoszt cselekedve szenvedtek, ha így akarja Isten.
18 Nítorí tí Kristi pẹ̀lú jìyà lẹ́ẹ̀kan nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, olóòótọ́ fún àwọn aláìṣòótọ́, kí a lè mú wa dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí a pa nínú ara, ṣùgbọ́n tí a sọ di ààyè nínú ẹ̀mí.
Mert Krisztus is szenvedett egyszer a bűnökért, mint igaz a nem igazakért, hogy minket Istenhez vezéreljen. Megölettetett ugyan test szerint, de megelevenítetett Lélek szerint.
19 Nínú èyí tí ó lọ pẹ̀lú tí ó sì wàásù fún àwọn ẹ̀mí nínú túbú,
Így ment el a börtönben lévő lelkekhez, és prédikált azoknak,
20 àwọn tí ó ṣe aláìgbọ́ràn nígbà kan, nígbà tí sùúrù Ọlọ́run dúró pẹ́ ní sá à kan ní ọjọ́ Noa, nígbà tí wọ́n fi kan ọkọ̀ nínú èyí tí a gba ọkàn díẹ̀ là nípa omi, èyí ni ẹni mẹ́jọ.
akik egykor engedetlenek voltak, amikor Isten Nóé napjaiban türelmesen várakozott, a bárka készítésekor, amelyben csak nyolc lélek menekült meg víz által.
21 Àpẹẹrẹ èyí ti ń gbà yín là nísinsin yìí pẹ̀lú, àní ìtẹ̀bọmi, kì í ṣe wíwẹ́ èérí ti ara nù, bí kò ṣe ìdáhùn ẹ̀rí ọkàn rere si Ọlọ́run, nípa àjíǹde Jesu Kristi.
Ami minket is megtart most, mint a keresztség képmása, ami nem a test szennyének a lemosása, hanem könyörgés Istenhez jó lelkiismeretért Jézus Krisztus feltámadása által.
22 Ẹni tí ó lọ sí ọ̀run, tí ó sì ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run: pẹ̀lú àwọn angẹli, àwọn aláṣẹ, àti àwọn alágbára sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
Ő fölmenvén a mennybe, Istennek jobbján van, és alávettettek neki az angyalok, hatalmasságok és erők.