< 1 Peter 3 >
1 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín; pé, bí ẹnikẹ́ni ba tilẹ̀ ń ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, kí a lè jèrè wọn láì sọ̀rọ̀ nípa ìwà àwọn aya wọn.
Que les femmes soient soumises à leurs maris, afin que, s'il y a des maris qui n'obéissent pas à la Parole, ils soient gagnés par la conduite de leurs femmes, sans le secours de la parole,
2 Nígbà tí wọ́n bá ń wo ìwà rere pẹ̀lú ẹ̀rù yín.
lorsqu'ils verront leur conduite chaste et respectueuse.
3 Kí ọ̀ṣọ́ yín má ṣe jẹ́ ọ̀ṣọ́ òde, tí irun dídì, àti wúrà lílò, tàbí ti aṣọ wíwọ̀;
Que leur parure ne soit pas cette parure extérieure, qui consiste à se tresser les cheveux, à se couvrir de bijoux d'or ou à s'ajuster des vêtements,
4 ṣùgbọ́n kí ó jẹ́ ẹni tí ó fi ara sin ní ọkàn, nínú ọ̀ṣọ́ àìdíbàjẹ́ ti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ àti ẹ̀mí tútù, èyí tí i ṣe iyebíye níwájú Ọlọ́run.
mais qu'elles ornent l'être caché du coeur, de la parure impérissable d'un esprit doux et paisible, qui est d'un grand prix devant Dieu.
5 Nítorí báyìí ni àwọn obìnrin mímọ́ ìgbàanì pẹ̀lú, tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run, fi ṣe ara wọn lọ́ṣọ̀ọ́, wọn a máa tẹríba fún àwọn ọkọ wọn.
C'est ainsi qu'autrefois se paraient les saintes femmes qui mettaient leur espérance en Dieu, en demeurant soumises à leurs maris:
6 Gẹ́gẹ́ bí Sara ti gbọ́ ti Abrahamu, tí ó ń pè é ní olúwa rẹ̀. Ọmọbìnrin ẹni tí ẹ̀yin jẹ́, bí ẹ̀yin bá ń ṣe rere, tí ohunkóhun kò sí dẹ́rùbà yín.
telle était Sarah, qui obéissait à Abraham, l'appelant son seigneur, elle, dont vous êtes devenues les filles par votre bonne conduite, et par votre courage qui ne s'effraie de rien.
7 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ẹ̀yin ọkọ, ẹ máa fi òye ba àwọn aya yín gbé, ẹ máa fi ọlá fún aya, bi ohun èlò ti kò lágbára, àti pẹ̀lú bí àjùmọ̀jogún oore-ọ̀fẹ́ ìyè; kí àdúrà yín má bà á ní ìdènà.
Et vous de même, maris, comportez-vous sagement avec vos femmes, comme avec un sexe faible. Traitez-les avec honneur, comme héritant aussi avec vous la grâce de la vie, pour que rien ne vienne vous empêcher, les uns et les autres, de prier.
8 Lákòótan, kí gbogbo yín jẹ́ onínú kan, ẹ máa bá ara yín kẹ́dùn, ẹ ní ìfẹ́ ará, ẹ máa ṣe ìyọ́nú, ẹ ni ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀.
Enfin soyez tous animés des mêmes pensées et des mêmes sentiments, pleins d'amour fraternel, de tendresse, d'humilité.
9 Ẹ má ṣe fi búburú san búburú, tàbí fi èébú san èébú: ṣùgbọ́n kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ máa súre; nítorí èyí ni a pè yín sí, kí ẹ̀yin lè jogún ìbùkún.
Ne rendez point mal pour mal, ni injure pour injure; bénissez au contraire, car c'est à cela que vous avez été appelés, afin d'hériter la bénédiction.
10 Nítorí, “Ẹni tí yóò bá fẹ́ ìyè, ti yóò sì rí ọjọ́ rere, kí o pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi, àti ètè rẹ̀ mọ́ kúrò nínú sísọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Que celui, en effet, qui veut aimer la vie et voir des heureux jours, empêche sa langue de dire du mal et ses lèvres de proférer des paroles trompeuses;
11 Kí ó yà kúrò nínú ibi, kí ó sì máa ṣe rere; kí ó máa wá àlàáfíà, kí ó sì máa lépa rẹ̀.
qu’il se détourne du mal et fasse le bien; qu’il recherche la paix et la poursuive;
12 Nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo, etí rẹ̀ sì ṣí sí ẹ̀bẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú.”
car le Seigneur a les yeux sur les justes, et se oreilles sont attentives à leurs prières; mais la face du Seigneur est contre ceux qui font le mal.»
13 Tá nì yóò sì ṣe yín ní ibi, bí ẹ̀yin bá jẹ́ onítara sí ohun rere?
Et qui vous maltraitera, si vous vous portez avec ardeur au bien?
14 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá jìyà nítorí òdodo, a ti bùkún yín. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù ìhàlẹ̀ wọn, kí ẹ má sì ṣe kọminú.”
Quand même vous souffririez pour la justice, soyez heureux. «Ne redoutez pas leurs menaces, et ne vous laissez pas troubler;
15 Ṣùgbọ́n ẹ bọ̀wọ̀ fún Kristi bí Olúwa ní ọkàn yín: kí ẹ sì múra tan nígbà gbogbo láti dá olúkúlùkù lóhùn tí ń béèrè ìrètí tí o ń bẹ nínú yín, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn tútù àti ìbẹ̀rù.
mais sanctifiez dans vos coeurs Christ, le Seigneur.» Soyez toujours prêts à répondre, mais avec douceur et respect, à quiconque vous demande raison de votre espérance,
16 Kí ẹ máa ni ẹ̀rí ọkàn rere bí wọ́n ti ń sọ̀rọ̀ yín ní ibi, kí ojú lè ti àwọn tí ń kẹ́gàn ìwà rere yín nínú Kristi.
ayant une bonne conscience, afin que, sur le point même où l’on vous calomnie, vous couvriez de confusion ceux qui diffament votre conduite en Christ:
17 Nítorí ó sàn, bí ó bá jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run, kí ẹ jìyà fún ṣíṣe rere ju fún ṣíṣe búburú lọ.
il vaut mieux souffrir, si telle est la volonté de Dieu, en faisant bien qu'en faisant mal.
18 Nítorí tí Kristi pẹ̀lú jìyà lẹ́ẹ̀kan nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, olóòótọ́ fún àwọn aláìṣòótọ́, kí a lè mú wa dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí a pa nínú ara, ṣùgbọ́n tí a sọ di ààyè nínú ẹ̀mí.
Christ aussi a bien souffert pour les péchés, lui juste pour les injustes, afin de nous donner accès auprès de Dieu, lorsqu'il a été mis à mort quant à la chair, mais qu'il a été rendu vivant quant à l'esprit.
19 Nínú èyí tí ó lọ pẹ̀lú tí ó sì wàásù fún àwọn ẹ̀mí nínú túbú,
Esprit, il est allé prêcher aux esprits qui sont en prison, pour avoir été jadis rebelles,
20 àwọn tí ó ṣe aláìgbọ́ràn nígbà kan, nígbà tí sùúrù Ọlọ́run dúró pẹ́ ní sá à kan ní ọjọ́ Noa, nígbà tí wọ́n fi kan ọkọ̀ nínú èyí tí a gba ọkàn díẹ̀ là nípa omi, èyí ni ẹni mẹ́jọ.
lorsqu'au temps de Noé la longanimité de Dieu temporisait, pendant que se construisait l'arche, dans laquelle un petit nombre de personnes, huit seulement, furent sauvées à travers l'eau.
21 Àpẹẹrẹ èyí ti ń gbà yín là nísinsin yìí pẹ̀lú, àní ìtẹ̀bọmi, kì í ṣe wíwẹ́ èérí ti ara nù, bí kò ṣe ìdáhùn ẹ̀rí ọkàn rere si Ọlọ́run, nípa àjíǹde Jesu Kristi.
Cette eau, dont le baptême est l'image — non ce baptême qui ôte les souillures du corps, mais celui qui est l'aspiration d'une bonne conscience vers Dieu — nous sauve maintenant, nous aussi, par la résurrection de Jésus-Christ,
22 Ẹni tí ó lọ sí ọ̀run, tí ó sì ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run: pẹ̀lú àwọn angẹli, àwọn aláṣẹ, àti àwọn alágbára sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
qui est à la droite de Dieu, dans le ciel où il est allé, et où les anges, les principautés et les puissances lui sont soumis.