< 1 Kings 1 >

1 Nígbà tí Dafidi ọba di arúgbó, ọjọ́ rẹ̀ sì pọ̀, ara rẹ̀ kò le è móoru bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n da ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ bò ó.
Ie amy zao fa bey naho nigain-kantetse t’i Davide mpanjaka; aa ndra t’ie nisafo-damba tsy nahazo hafanàñe.
2 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí fún un pé, “Ẹ jẹ́ kí a wá ọ̀dọ́mọbìnrin wúńdíá kan kí ó dúró ti ọba, kì ó sì máa tọ́jú rẹ̀. Kí ó dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀ kí ara ọba olúwa wa lè móoru.”
Aa le hoe o mpitoro’eo ama’e: Ho paiañe somondrara ki’e i talèko mpanjakay, ie hijohañe añatrefa’ i mpanjakay, hiatrak’ aze, naho hàndre añ’araña’e, hahazoa’ i talèko mpanjakay hafanàñe.
3 Nígbà náà ni wọ́n lọ jákèjádò ilẹ̀ Israẹli láti wá ọ̀dọ́mọbìnrin arẹwà, wọ́n sì rí Abiṣagi, ará Ṣunemu, wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ ọba.
Aa le nanitsike i tane Israeley iereo nitsoeke ty ampela soa; le nitendreke t’i Abisage nte-Sonamý vaho na­sese amy mpanjakay.
4 Ọmọbìnrin náà rẹwà gidigidi; ó sì ń ṣe ìtọ́jú ọba, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n ọba kò sì bá a lòpọ̀.
Toe nimontramontra i somondraray; naho niatrake i mpanjakay vaho nitoroñ’ aze fe tsy niolora’ i mpanjakay.
5 Adonijah ẹni tí ìyá rẹ̀ ń ṣe Haggiti sì gbé ara rẹ̀ ga, ó sì wí pé, “Èmi yóò jẹ ọba.” Ó sì ṣètò kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin, pẹ̀lú àádọ́ta ọkùnrin láti máa sáré níwájú rẹ̀.
Nisenge-vatañe amy zao t’i Adonià ana’ i Kagite, ami’ty hoe: Izaho ty ho mpanjaka. Aa le nihentseñe’e sarete naho mpiningi-tsoavala vaho ondaty limampolo ho mpilay aolo’e.
6 (Baba rẹ̀ kò bà á nínú jẹ́ rí nípa bíbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi hùwà báyìí?” Ó sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin, òun ni a bí lé Absalomu.)
Mbe lia’e tsy nibosehan-drae’e ami’ ty hoe: Manao akore o anoe’oo? toe ni-ondaty maràm-bintan-dre, nanonjohy i Absalome te nasamake.
7 Adonijah sì gbèrò pẹ̀lú Joabu, ọmọ Seruiah àti Abiatari àlùfáà, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
Nivesoveso am’ Ioabe ana’ i Tseroia naho amy Abiatare mpisoron-dre; le norihe’ iereo t’i Adonià nañolotse aze.
8 Ṣùgbọ́n Sadoku àlùfáà, Benaiah ọmọ Jehoiada, Natani wòlíì, Ṣimei àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Rei àti olórí ogun Dafidi ni kò darapọ̀ mọ́ Adonijah.
Fe tsy nimpiami’ Adonià t’i Tsadoke mpisoroñe naho i Benaià ana’ Iehoiada naho i Natane mpitoky naho i Simeý naho i Reý vaho o fanalolahi’ i Davideio.
9 Nígbà náà ni Adonijah fi àgùntàn àti màlúù àti ẹran ọ̀sìn tí ó sanra rú ẹbọ níbi Òkúta Soheleti tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ En-Rogeli. Ó sì pe gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ ọba.
Nandenta añondry naho añombe naho kobatròke marine ty lamilami’ i Tsokelete añ’ila’ i En-drogele eo t’i Adonià; le kinoi’e iaby o longo’eo, o ana’ i mpanjakaio vaho o nte-Iehoda mpitoro’ i mpanjakaio;
10 Ṣùgbọ́n kò pe Natani wòlíì tàbí Benaiah tàbí àwọn olórí tàbí Solomoni arákùnrin rẹ̀.
fe tsy kinanji’e t’i Natane mpitoky naho i Benaià, naho o fanalolahio vaho i Selomò rahalahi’e,
11 Nígbà náà ni Natani béèrè lọ́wọ́ Batṣeba, ìyá Solomoni pé, “Ǹjẹ́ ìwọ kò gbọ́ pé Adonijah, ọmọ Haggiti ti jẹ ọba láìjẹ́ pé Dafidi olúwa wa mọ̀ sí i?
Aa le nisaontsy amy Betesebà rene’ i Selomò t’i Natane ami’ty hoe, Tsy jinanji’o hao te fa mifehe t’i Adonià ana’ i Hagite, vaho tsy fohi’ i Davide talèntika?
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, jẹ́ kí èmi gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn bí ìwọ ṣe lè gba ẹ̀mí rẹ là àti ẹ̀mí ọmọ rẹ Solomoni.
Antao arè, angao hitolorako hevetse, handrombaha’o ty fiai’o naho ty fiai’ i ana’o Selo­mòy.
13 Lọ sọ́dọ̀ Dafidi ọba, kí o sì wí fún un pé, ‘Olúwa mi ọba, ǹjẹ́ ìwọ kò búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, “Dájúdájú Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi?” Èéṣe nígbà náà tí Adonijah fi jẹ ọba?’
Akia mb’amy Davide mpanjaka mb’eo, le ano ty hoe: Tsy nifantà’o amo mpitoro’o ampelao hao, ry talèko mpanjaka, ty hoe: Toe hanonjohy ahy t’i Selomò ana’o hifehe, hiambesatse am-pitobohako eo? aa vaho akore t’i Adonià, ie mifeheo?
14 Níwọ́n ìgbà tí ìwọ sì wà níbẹ̀, tí o sì ń bá ọba sọ̀rọ̀ èmi yóò wá, láti wádìí ohun tí o ti sọ.”
Aa ihe mbe mitaroñe amy mpanjakay, le horihako ao hañonjoñe o saontsi’oo;
15 Bẹ́ẹ̀ ni Batṣeba lọ rí ọba ní inú yàrá rẹ̀, ọba sì gbó gidigidi níbi tí Abiṣagi ará Ṣunemu ti ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba.
Aa le niheo mb’ amy mpanjakay añ’efe’e ao t’i Betesebà: toe niloho bey i mpanjakay ie natrafe’ i Abi­sage nte Sonamý i mpanjakay.
16 Batṣeba sì tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba. Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”
Nidrodrètse t’i Betesebà naho niambane amy mpanjakay. Le hoe i mpanjakay: Ino o paia’oo?
17 Ó sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi; ìwọ fúnra rẹ̀ fi Olúwa Ọlọ́run rẹ búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, ‘Solomoni ọmọ rẹ yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi.’
Le hoe re tama’e, O ry talèko: Nifanta’o añamy Iehovà Andria­naña­hare’o amy anak’ ampata’o, ty hoe: Toe hanonjohy ahy am-pifeheañe t’i Selo­mò ana’o, vaho ie ty hitobok’ amy fiambesam-pifeheakoy.
18 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Adonijah ti di ọba, ìwọ, ọba olúwa mi kò sì mọ̀ nípa rẹ̀.
Fe inao te mifehe t’i Adonià henanekeo vaho tsy fohi’o ry talèko mpanjaka;
19 Òun sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran tí ó ní ọ̀rá, àti àgùntàn rú ẹbọ, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, àti Abiatari àlùfáà àti Joabu balógun, ṣùgbọ́n kò sì pe Solomoni ìránṣẹ́ rẹ.
mbore fa nandenta añombe naho kobatroke vaho añondry tsifotofoto re le kinoi’e iaby o anam-panjakao, naho i Abiatare mpisoroñe, vaho Ioabe mpifelek’ i valobohòkey; fe tsy kinanji’e t’i Selomò mpitoro’o.
20 Olúwa mi ọba, ojú gbogbo Israẹli ń bẹ lára rẹ, láti mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ.
Ie amy zao hene ama’o, ry talèko mpanjaka ty fihaino’ Israele, ty hitaroña’o te ia ty hiambesatse amy fiambesan-talèko mpanjakay hanonjohy aze.
21 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí olúwa mi ọba bá sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, wọn yóò sì ka èmi àti Solomoni sí ẹlẹ́ṣẹ̀.”
Naho tsy izay, hifetsake te, ie mirotse an-droae’e ao ty talèko mpanjaka, le hatao mpandilatse iraho naho i Selomò anako.
22 Bí ó sì ti ń bá ọba sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Natani wòlíì sì wọlé.
Ie mbe nisaon­tsy amy mpanjakay, le nimoak’ ao t’i Natane mpitoky
23 Wọ́n sì sọ fún ọba pé, “Natani wòlíì wà níbí.” Ó sì lọ síwájú ọba, ó wólẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀.
vaho nitohine’e ami’ty hoe i mpanjakay, Ingo t’i Natane mpitoky. Aa ie tafa-zilik’ amy mpanjakay, le nibokobokok’ aolo’ i mpanjakay, nihohok’ an-tane ty lahara’e.
24 Natani sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ, olúwa mi ọba, ti sọ pé Adonijah ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn rẹ àti pé òun ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ?
Le hoe t’i Natane, Ry talèko mpanjaka, Nitaroñe ty hoe hao irehe te i Adonià ty hifehe manonjohy azo, le ie ty hiambesatse amy fiambesa’oy?
25 Ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ ní òní, ó sì ti rú ẹbọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran ọlọ́ràá àti àgùntàn. Ó sì ti pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, balógun àti Abiatari àlùfáà. Nísìnsinyìí, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Kí Adonijah ọba kí ó pẹ́!’
Amy t’ie nizotso mb’eo anindroany nandenta añombe naho kobatroke naho añondry maro vaho nambarà’e iaby o anam-panjakao naho o mpifelek’ i valobohòkeio naho i Abiatare mpisoroñe; ie mikama naho mitohok’ añ’atrefa’e eo, manao ty hoe, Lava havelo ry Adonià mpanjaka.
26 Ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́ rẹ, àti Sadoku àlùfáà, àti Benaiah ọmọ Jehoiada, àti Solomoni ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè.
Fe izaho, izaho mpitoro’o, naho i Tsadoke mpisoroñe, naho i Benaià ana’ Iehoiadà, vaho i Se­lomò mpitoro’o—tsy nambara’e.
27 Ṣé nǹkan yìí ni olúwa mi ọba ti ṣe láìjẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ?”
Nanoen-talèko mpanjaka hao izao, ie tsy natoro’o amo mpitoro’oo ty hanonjohy azo hiambesatse am-piambesan-talèko mpanjaka?
28 Nígbà náà ni Dafidi ọba wí pé, “Pe Batṣeba wọlé wá.” Ó sì wá síwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
Aa hoe ty natoi’ i Davide mpanjaka, Kanjio homb’ amako mb’ etoa t’i Betesebà. Le niheo mb’ añatrefa’ i mpanjakay mb’eo re, nijohañe aolo’ i mpanjakay.
29 Ọba sì búra pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbà mí kúrò nínú gbogbo wàhálà
Le nifanta ty hoe i mpanjakay: Kanao veloñe t’Iehovà nijebañe ty fiaiko amy ze haoreañe iaby,
30 Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Israẹli búra fún yọ pé, Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”
tsy kalafo te nifantàko ama’o añam’ Iehovà, Andrianañahare’ Israele, ty hoe: Hifehe handimbe ahy t’i Selomò ana’o, le ie ty handimbe ahy hiambesatse amy fitobohakoy. Toe hanoeko anito.
31 Nígbà náà ni Batṣeba tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí olúwa mi Dafidi ọba kí ó pẹ́!”
Nidròdreke mb’an-tane ty lahara’ i Bete-sebà, niambane amy mpanjakay, nanao ty hoe: Lonik’ abey te ho veloñe nainai’e ty talèko Davide mpanjaka.
32 Dafidi ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadoku àlùfáà wọlé fún mi àti Natani wòlíì àti Benaiah ọmọ Jehoiada.” Nígbà tí wọ́n wá síwájú ọba,
Le hoe t’i Davide mpanjaka, Kanjio homb’ amako mb’etoa t’i Tsadoke mpisoroñe, naho i Natane mpitoky, vaho i Benaià ana’ Iehoiadà. Aa le nomb’ añatrefa’ i mpanjakay mb’eo iereo.
33 ọba sì wí fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Solomoni ọmọ mi kí ó gun ìbáaka mi, kí ẹ sì mú un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gihoni.
Le hoe i mpanjakay am’ iereo: Endeso ama’ areo o mpitoro’ i talè’ areoio, le ampiningiro amy borikekoy t’i Selomò, le aseseo hizotso mb’e Gihone mb’eo;
34 Níbẹ̀ ni Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì yóò ti fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!’
le hañory aze ho mpanjaka’ Israele t’i Tsa­doke mpisoroñe naho i Natane mpitoky; le popòho i antsivay, vaho ano ty hoe: Mahavelo t’i Selomò mpanjaka.
35 Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jẹ ọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Israẹli àti Juda.”
Le mionjona mb’ etoa am-pañorihañ’ aze, le homb’eo re hiambesatse amy fitobohakoy, amy te ie ty handimbe ahy ho mpanjaka; ie ty jinoboko hifehe Israele naho Iehodà.
36 Benaiah ọmọ Jehoiada sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀.
Aa le hoe ty natoi’ i Benaià ana’ Iehoiada amy mpanjakay: Amena! Lonike t’ie ty hanoe’ Iehovà Andrianañaharen-talèko mpanjaka.
37 Bí Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Solomoni kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ olúwa mi Dafidi ọba lọ!”
Hambañ’ amy nindreza’ Iehovà amy talèko mpanjakaiy ty hindreza’e amy Selomò, naho honjone’e ambone’ ty fiambesa’ i talèko Davide mpanjakay i fiambesa’ey.
38 Nígbà náà ni Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada, àwọn ará Kereti àti Peleti sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Solomoni gun ìbáaka Dafidi ọba wá sí Gihoni.
Aa le nizotso mb’eo t’i Tsadoke mpisoroñe naho i Natane mpitoky naho i Benaià ana’ Iehoiada naho o nte-Kereteo naho o nte Peleteo le natongoa’ iereo amy borìke’ i Davide mpanjakay t’i Selomò vaho nasese’ iereo mb’e Gihone mb’eo.
39 Sadoku àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Solomoni lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!”
Le nakare’ i Tsadoke i tsifa ama’menake boak’ amy Kivohoiy naho noriza’e t’i Selo­mò vaho nipopoeñe i antsivay; le hene nirihoñe ty hoe ondatio, Mahavelo ry Selomò mpanjaka.
40 Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.
Nionjomb’eo am-pañorihañe aze ondaty iabio; nitio-tsoly vaho nirebeke an-kafaleam-bey, kanao nahariatse i taney ty fikontsiaña’ ondatio.
41 Adonijah àti gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ìpè, Joabu sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”
Jinanji’ i Adonià naho o nambarà’eo, ie vaho nianjam-pikama. Le hoe t’Ioabe naho nahajanjiñe ty feo’ i antsivay: Ino o fipoñafan-drañoraño an-drovao?
42 Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani ọmọ Abiatari àlùfáà sì dé, Adonijah sì wí pé, “Wọlé wá, ọkùnrin yíyẹ ìwọ gbọdọ̀ mú ìròyìn rere wá.”
Ie mbe nisaontsy, ingo, pok’eo t’Ionatane ana’ i Abiatare mpisoroñe: le hoe t’i Adonià: Miziliha, ry lahy manjofake, mpinday entan-tsoa.
43 Jonatani sì dáhùn, ó sì wí fún Adonijah pé, “Lóòótọ́ ni olúwa wa Dafidi ọba, fi Solomoni jẹ ọba.
Le hoe ty natoi’ Ionatane amy Adonià, Toe i Selomò ty nanoe’ i Davide mpanjaka talèn-tika, mpanjaka;
44 Ọba sì ti rán Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada àti àwọn ará Kereti àti Peleti pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì ti gbé e gun ìbáaka ọba,
naho nirahe’ i mpanjakay hindre ama’e t’i Tsadoke mpisoroñe naho i Natane mpitoky naho i Benaià ana’ Iehoiadà naho o nte-Kereteo naho o nte-Peleteo, le nampiningire’ iereo amy borì’ i mpanjakaiy;
45 Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gihoni. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, ìlú sì ń hó pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni ariwo tí ẹ̀yin ń gbọ́.
vaho noriza’ i Tsadoke mpisoroñe naho i Natane mpitoky ho mpanjaka e Gihone ao re; mivoamboañe boak’ ao an-drebeke iereo kanao mañeno-tsatsake o rovao. Izay o korakoràke janji’ areoo.
46 Solomoni sì ti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀.
Eka! fa miambesatse amy fiambesam-pifeheañey t’i Selomò.
47 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì ti tún wá láti bá olúwa wa Dafidi ọba yọ̀, wí pé, ‘Kí Ọlọ́run rẹ̀ mú orúkọ Solomoni lókìkí ju tirẹ̀ lọ àti kí ìtẹ́ rẹ̀ kí ó pọ̀ ju tirẹ̀ lọ!’ Ọba sì tẹ ara rẹ̀ ba lórí ibùsùn rẹ̀,
Nimb’eo ka o mpitoro’ i mpanjakaio hitata i Davide mpanjaka talèn-tika ami’ty hoe: Honjone’ i Andrianañahare’o ambone’ ty tahina’o ty tahina’ i Selomò vaho hampitoabore’e ambone’ i fiambesa’oy ty fiambesa’e; le niondrek’ am-pandrea’e eo i mpanjakay.
48 ọba sì wí pé, ‘Ògo ni fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti jẹ́ kí ojú mi rí ẹnìkan tí ó jókòó lórí ìtẹ́ mi lónìí.’”
Tinovo’ i mpanjakay ty ti-hoe, Andriañeñe t’Iehovà, Andrianañahare’ Israele, nanolotse ty hiambesatse amy fitobohakoy anindroany, hahatreava’ o masokoo.
49 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ Adonijah dìde ní ìdágìrì, wọ́n sì túká.
Fonga nangebahebak’ amy zao o nambarà’ i Adoniào, le niongake, songa ninankañe mb’ an-dala’e mb’eo.
50 Ṣùgbọ́n Adonijah sì bẹ̀rù Solomoni, ó lọ, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
Nirevendreveñe amy zao t’i Adonià ty amy Selomò, le niavotse mb’eo nivontititse amo tsifa’ i kitreliio.
51 Nígbà náà ni a sì sọ fún Solomoni pé, “Adonijah bẹ̀rù Solomoni ọba, ó sì di ìwo pẹpẹ mú, Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí ọba Solomoni búra fún mi lónìí pé, òun kì yóò fi idà pa ìránṣẹ́ rẹ̀.’”
Aa le nisaontsieñe amy Selomò ty hoe: Inao! mañeveñe amy Selomò mpanjaka t’i Adonià, kanao tambozore’e o tsifan-kitrelio, le hoe ty asa’e, Ehe te hifanta amako anito t’i Selomò mpanjaka tsy hanjevoñe i mpitoro’ey am-pibara.
52 Solomoni sì dáhùn pé, “Bí ó bá fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ ẹni ọ̀wọ̀, irun orí rẹ̀ kan kì yóò sì bọ́ sílẹ̀; ṣùgbọ́n bí a bá rí búburú kan ní ọwọ́ rẹ̀ òun yóò kú.”
Le hoe t’i Selomò, Naho miboake hondaty vañon-dre, leo raik’ amo maroi’eo tsy hipok’ an-tane; f’ie tendrehan-kaloloañe le hihomake.
53 Nígbà náà ni Solomoni ọba rán àwọn ènìyàn, wọ́n sì mú un sọ̀kalẹ̀ láti ibi pẹpẹ wá. Adonijah sì wá, ó sì foríbalẹ̀ fún Solomoni ọba, Solomoni sì wí pé, “Lọ ilé rẹ.”
Aa le nañirake t’i Selo­mò mpanjaka, vaho nazotso’ iareo amy kitreliy. Nimb’eo re niambane amy Selo­mò mpanjaka; le hoe ty Se­lomò ama’e: Akia mb’ añ’akiba’o añe.

< 1 Kings 1 >