< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
És volt midőn végzett Salamon azzal, hogy fölépítse az Örökkévaló házát és a király házát éa Salamonnak minden kívánalmát, amit véghezvinni akart,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
megjelent az Örökkévaló Salamonnak másodszor, amiképpen megjelent neki Gibeónban.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
És szólt hozzá az Örökkévaló: Hallottam imádságodat és könyörgésedet, mellyel könyörögtél előttem, megszenteltem e házat, melyet építettél, hogy oda helyezzem nevemet örökre és ott lesznek szemeim és szívem minden időben.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
Te pedig, ha majd előttem jársz, amint Dávid atyád járt, a szívnek feddhetetlenségében és egyenességben, cselekedvén mind aszerint, amint neked parancsoltam, törvényeimet és rendeleteimet megőrzöd;
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
akkor fönntartom királyságod trónját Izraél fölött örökre, amint kimondtam Dávid atyád felől, mondván: nem fogy el tőled való férfi Izraél trónjáról.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
Ha el fogtok tőlem fordulni, ti meg fiaitok, és nem őrizted meg parancsolataimat, törvényeimet, melyeket elétek adtam, hanem mentek és szolgáltok más isteneket és leborultok előttük:
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
akkor kiírtom Izraélt azon föld színéről, melyet nekik adtam, a házat pedig, melyet nevemnek szenteltem, elvetem színem elől; és lesz majd Izraél példázattá és gúnnyá mind a népek között.
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
Ez a ház pedig, mely legfelsőbb lehetett volna – bárki elmegy mellette, eliszonyodik és pisszeg; azt mondják: miért tett így az Örökkévaló ez országgal és e házzal!
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
És majd mondják: azért, hogy elhagyták az Örökkévalót, Istenüket, ki kivezette őseiket Egyiptom országából, de ragaszkodtak más istenekhez, leborultak előttük és szolgálták őket; ezért hozta reájuk az Örökkévaló mind e veszedelmet.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
Így volt azon húsz év múltán, amelyek alatt fölépítette Salamon a két házat, az Örökkévaló házát és a király házát –
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
Chírám, Cór királya, támogatta Salamont cédrusfákkal, ciprusfákkal és arannyal minden kivánsága szerint; akkor adott Salamon király Chírámnak húsz várost a Gálíl földjén –
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
kivonult Chírám Córból, hogy megnézze a városokat, melyeket adott neki Salamon; de nem tetszettek neki.
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
Mondta: Micsoda városok ezek, melyeket adtál nekem, testvérem? És így nevezték őket: Kábúl földje, mind e mai napig.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Küldött Chírám a királynak százhúsz kikkár aranyat.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
És ez azon robotnak ügye, melyet kivetett Salamon király, hogy építse az Örökkévaló házát és a maga házát, a millót és Jeruzsálem falát, Chácórt, Megiddót és Gézert –
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
Fáraó, Egyiptom királya fölment volt és bevette Gézert és elégette tűzzel, a városban lakó kanaánit megölte és hozományul adta leányának, Salamon feleségének –
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
fölépítette Salamon Gézert és az alsó Bét-Chóront,
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
Báalátot és Tadmórt a puszta országában;
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
meg mind az éléstár városokat, melyek Salamonéi voltak, meg a szekérhad városait és a lovasok városait és Salamonnak kívánalmát, amit építeni kívánt Jeruzsálemben és a Libánonon meg uralmának egész országában.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
Mindazon nép, mely megmaradt az emórí, a chítti, a perizzi, a chívví és a jebúszí közül, azok, akik nem Izraél fiai közül valók
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
a fiaik, kik megmaradtak utánuk az országban, akiket Izraél fiai nem bírtak kipusztítani, azokra vetett ki Salamon robotmunkát mind e mai napig.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
De Izraél fiai közül senkit sem tett Salamon rabszolgává, hanem ők voltak a harcosok, szolgái, tisztjei, hadnagyai, meg szekérhadának és lovasainak vezérei.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
Ezek a tisztek, akik felügyeltek Salamonnak munkája fölött: ötszázötvenen, a kik a munkát végző nép fölött uralmat vittek.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Alig, hogy fölment Fáraó leánya Dávid városából a maga házába, melyet épített számára, akkor fölépítette a millót.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
Bemutatni szokott Salamon háromszor az évben égő és békeáldozatokat az oltáron, melyet épített az Örökkévalónak, meg füstölögtetett azon, mely az Örökkévaló színe előtt volt. Így befejezte a házat.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
Hajórajt is készített Salamon király Ecjón-Géberben, mely Élót mellett van, a nádas tenger partján, Edóm országában.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
És küldte Chírám a hajórajjal az ő szolgáit, tengeren jártas hajósokat, Salamon szolgáival együtt.
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
Elmentek Ófirba, szereztek onnan aranyat, négyszáz húsz kikkárt, és elhozták Salamon királynak.

< 1 Kings 9 >