< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
Or, il arriva que lorsque Salomon eut achevé l’édifice de la maison du Seigneur, l’édifice du roi, et tout ce qu’il avait souhaité et voulu faire,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
Le Seigneur lui apparut une seconde fois, comme il lui avait apparu à Gabaon.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
Et le Seigneur lui dit: J’ai exaucé ta prière et tes supplications que tu as faites devant moi: j’ai sanctifié cette maison que tu as bâtie, afin que j’y établisse mon nom à jamais; et mes yeux et mon cœur seront là tous les jours.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
Toi aussi tu marches devant moi comme a marché ton père, dans la simplicité de cœur et dans l’équité; et si tu fais tout ce que je t’ai ordonné, et que tu gardes mes lois et mes ordonnances,
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
J’établirai le trône de ton règne sur Israël à jamais, comme je l’ai promis à David ton père, disant: Un homme de ta race ne sera pas ôté du trône d’Israël.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
Mais si vous vous détournez entièrement, vous et vos fils, ne me suivant pas, et ne gardant pas mes commandements et mes cérémonies que je vous ai exposés; et si vous vous en allez, et que vous serviez des dieux étrangers et que vous les adoriez,
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
J’enlèverai Israël de la surface de la terre que je lui ai donnée; et le temple que j’ai consacré à mon nom, je le rejetterai loin de ma présence, et Israël deviendra le brocard et la fable de tous les peuples.
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
Et cette maison sera en exemple; et quiconque passera auprès d’elle sera étonné, sifflera, et dira: Pourquoi le Seigneur a-t-il fait ainsi à cette terre et à cette maison?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
Et on répondra: Parce qu’ils ont abandonné le Seigneur leur Dieu, qui a retiré leurs pères de l’Egypte, et qu’ils ont suivi des dieux étrangers, et qu’ils les ont adorés et servis: c’est pour cela que le Seigneur a amené sur eux ce malheur.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
Or, vingt ans s’étant écoulés après que Salomon eut bâti les deux maisons, c’est-à-dire la maison du Seigneur et la maison du roi,
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
(Hiram, roi de Tyr, fournissant à Salomon des bois de cèdre et de sapin, et de l’or tout autant qu’il en avait besoin) alors Salomon donna à Hiram vingt villes dans la terre de Galilée.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
Et Hiram sortit de Tyr pour voir les villes que lui avait données Salomon, et elles ne lui plurent pas,
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
Et il dit: Sont-ce là les villes que vous m’avez données, mon frère? Et il les appela terre de Chabul, jusqu’à ce jour.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Hiram envoya aussi au roi Salomon cent vingt talents d’or.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
Telle est la somme des dépenses que Salomon fit pour bâtir la maison du Seigneur, sa maison, Mello, les murs de Jérusalem, Héser, Mageddo et Gaser.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
Pharaon, roi d’Egypte, monta, et prit Gazer et la mit à feu; et il battit le Chananéen qui habitait dans la ville, et il la donna pour dot à sa fille, femme de Salomon.
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
Salomon rebâtit donc Gazer et Béthoron la basse,
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
Baalath et Palmyre, dans la terre du désert.
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
Et il fortifia tous les bourgs qui lui appartenaient et qui étaient sans mur, et les villes des chars, et les villes des cavaliers, et tout ce qu’il lui plut de bâtir dans Jérusalem, sur le Liban, et dans toute la terre de sa puissance.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
Quant à tout le peuple qui était demeuré des Amorrhéens, des Héthéens, des Phérézéens, des Hévéens et des Jébuséens, qui ne sont point des enfants d’Israël,
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
Et quant à leurs enfants, qui étaient demeurés dans la terre, c’est-à-dire ceux que les Israélites n’avaient pu exterminer, Salomon les a faits tributaires jusqu’à ce jour.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Mais pour les enfants d’Israël, Salomon établit qu’aucun ne servirait; mais ils étaient ses hommes de guerre; et il en fit ses ministres, ses principaux officiers, les chefs de son armée et les commandants de ses chars et de ses chevaux.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
Or, les principaux officiers préposés à tous les travaux de Salomon étaient au nombre de cinq cent cinquante, qui avaient le peuple sous eux, et qui commandaient les travaux entrepris.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Or la fille de Pharon monta de la cité de David en sa maison, que lui avait bâtie Salomon; ce fut alors que le roi bâtit Mello.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
Salomon offrait aussi trois fois chaque année des holocaustes et des victimes pacifiques sur l’autel qu’il avait bâti au Seigneur, et il brûlait du parfum devant le Seigneur; et le temple avait été achevé.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
Le roi Salomon équipa aussi une flotte à Asiongaber, qui est près d’Ailath, sur le rivage de la mer Rouge, dans la terre d’Idumée.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
Et Hiram envoya sur cette flotte ses serviteurs, matelots, et connaissant la mer, avec les serviteurs de Salomon.
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
Et lorsqu’ils furent venus en Ophir, ils y prirent quatre cent vingt talents d’or et les apportèrent au roi Salomon.

< 1 Kings 9 >