< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
Et lorsque Salomon eut terminé la construction de la Maison de l'Éternel, et du palais royal et de tous les lieux de plaisance de Salomon qu'il désirait élever,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
l'Éternel apparut à Salomon une seconde fois, comme Il lui était apparu à Gabaon.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
Et l'Éternel lui dit: J'ai ouï ta prière et ta supplication, par laquelle tu m'as imploré, j'ai consacré cette Maison que tu as édifiée, afin d'y mettre mon Nom pour l'éternité, et mes yeux et mon cœur y seront dans tous les temps.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
Quant à toi, si tu marches en ma présence comme David, ton père, a marché, avec l'intégrité du cœur et la droiture pour te conformer à tout ce que je t'ai prescrit, observant mes statuts et mes lois,
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
je maintiendrai éternellement le trône de ta royauté sur Israël, ainsi que je l'ai promis à David, ton père, en ces termes: Tu n'auras jamais faute d'un homme pour occuper le trône d'Israël.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
Mais si vous et vos fils vous faites défection contre moi, et ne gardez pas mes commandements, mes statuts que j'ai mis en face de vous, et si vous vous en allez servir d'autres dieux et les adorer,
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
j'arracherai Israël du sol que je lui ai donné, et, la Maison que j'ai consacrée à mon Nom, je l'ôterai de ma présence, et Israël deviendra la fable et l'objet des sarcasmes de tous les peuples.
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
Quant à cette Maison, quelle qu'en soit l'éminence, quiconque passera près d'elle, frissonnera et frémira, et l'on dira: Pourquoi l'Éternel a-t-Il ainsi traité ce pays et cette Maison?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
et il sera répondu: Parce qu'ils ont abandonné l'Éternel, leur Dieu, qui avait retiré leurs pères du pays d'Egypte, et se sont attachés à d'autres dieux, qu'ils ont adorés et servis; c'est pourquoi l'Éternel a fait fondre sur eux tout ce désastre.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
Et au bout de vingt ans, lorsque Salomon eut construit les deux édifices, le Temple de l'Éternel et le palais royal,
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
(Hiram, roi de Tyr, avait fait au Roi l'avance de bois de cèdre et de cyprès, et d'or, en tout selon son gré) alors le Roi Salomon céda à Hiram vingt villes au pays de Galilée.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
Et Hiram partit de Tyr pour examiner les villes que lui donnait Salomon, mais elles ne furent point selon son gré. Et il dit: Qu'est-ce que ces villes que tu me donnes là, mon frère?
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
Et il les appela de leur nom d'aujourd'hui, pays de Cabul.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Et Hiram avait envoyé au Roi cent vingt talents d'or.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
Et voici le mode de la corvée dont le Roi Salomon fit la levée pour construire le Temple de l'Éternel et son palais et la redoute, et le mur de Jérusalem, et Hatsor et Megiddo et Gazer.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
Pharaon, Roi d'Egypte, était monté, et s'était emparé de Gazer, et l'avait incendiée, et il avait massacré les Cananéens qui habitaient la ville, et il l'avait donnée en dot à sa fille, femme de Salomon.
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
Et Salomon rebâtit Gazer et Beth-Horon la basse
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
et Baalath et Thadmor au désert dans le pays
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
et toutes les villes d'approvisionnement appartenant à Salomon, et les villes des chars et les villes de la cavalerie, et les maisons de plaisance de Salomon qu'il se plut à bâtir à Jérusalem et au Liban, et dans tout le territoire de son royaume.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
Toute la population restée des Amoréens, Héthiens, Périzzites, Hévites et Jébusites, ne faisant point partie des enfants d'Israël,
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
c'est-à-dire leurs descendants restés après eux dans le pays, les enfants d'Israël n'ayant pu exécuter sur eux l'anathème, Salomon les leva comme serfs de corvée, ce qu'ils sont aujourd'hui.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Mais des enfants d'Israël Salomon ne fit point de serfs; car ils furent ses hommes de guerre et ses officiers et ses généraux, et ses triaires, et les chefs de ses chars et de sa cavalerie.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
Chefs préposés sur les travaux de Salomon: cinq cent cinquante, commandant la population occupée aux travaux.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Aussitôt que la fille de Pharaon fut montée de la Cité de David dans la maison qu'il lui avait bâtie, ce fut alors que Salomon bâtit la redoute.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
Et trois fois par année Salomon offrait des holocaustes, et des sacrifices pacifiques sur l'Autel qu'il avait élevé à l'Éternel, et il brûlait en personne l'encens devant l'Éternel. Il acheva donc la Maison.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
Et le Roi Salomon construisit une flotte à Etseion-Géber, située près d'Élath, au bord de la Mer aux algues, dans le pays d'Édom.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
Et Hiram envoya par un navire ses serviteurs, hommes de mer connaissant la marine, avec les serviteurs de Salomon.
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
Et ils gagnèrent Ophir d'où ils rapportèrent de l'or, quatre cent vingt talents qu'ils présentèrent au Roi Salomon.

< 1 Kings 9 >