< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
And it came to pass, when Solomon had made an end of building the house of Yahweh, and the house of the king, and everything that Solomon desired, which he was pleased to make,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
then appeared Yahweh unto Solomon, a second time, —as he appeared unto him, in Gibeon.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
And Yahweh said unto him—I have heard thy prayer and thy supplication, wherewith thou hast made supplication before me, I have hallowed this house, which thou hast built, to put my Name there unto times age-abiding, —and mine eyes and my heart shall be there, continually:
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
As for thee, therefore, if thou wilt walk before me, as David thy father walked, with a whole heart and with uprightness, to do according to all that I have commanded thee, —and, my statutes and my regulations, wilt keep,
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
then will I establish the throne of thy kingdom over Israel, unto times age-abiding, —as I promised unto David thy father, saying, There shall not be cut off to thee a man, from off the throne of Israel.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
If ye, turn back, ye or your sons, from following me, and keep not my commandments, my statutes, which I have set before you, —but depart and serve other gods, and bow yourselves down to them,
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
then will I cut off Israel, from the face of the soil, which I have given unto them, and, the house which I have hallowed for my Name, will I suffer to be carried away from before me, —and Israel shall become a byword and a mockery, among all the peoples;
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
and, this house which had been renowned, shall be desolate, every one that passeth by it, shall be astonished and shall whistle, —and men shall say—For what cause, hath Yahweh done, thus, unto this land, and unto this house?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
And men will answer—Because they forsook Yahweh their God, who brought forth their fathers out of the land of Egypt, and laid hold of other gods, and bowed themselves down to them, and served them, for this cause, hath Yahweh brought in upon them all this ruin.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
And it came to pass, at the end of twenty years, when Solomon had built the two houses, —the house of Yahweh, and the house of the king;
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
Hiram king of Tyre having supplied Solomon with timber of cedar, and with timber of fir, and with gold, according to all his desire, that, then, King Solomon gave unto Hiram twenty cities, in the land of Galilee.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
And Hiram came out from Tyre to view the cities which, Solomon, had given him, —and they were not pleasing in his eyes.
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
So he said—What cities are these which thou hast given me, my brother? And he called them, Unfruitful Land, [as they are called] unto this day.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Now Hiram had sent to the king, —a hundred and twenty talents of gold.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
Now, the following, is an account of the tax which King Solomon raised, for building the house of Yahweh and his own house, and Millo, and the wall of Jerusalem, —and Hazor and Megiddo, and Gezer.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
Pharaoh king of Egypt, had gone up and captured Gezer, and burned it with fire, the Canaanites also who were dwelling in the city, had he slain, —and had given it as a dowry, to his daughter, wife of Solomon.
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
So then Solomon built Gezer, and Beth-horon, the nether,
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
and Baalath and Tadmor in the wilderness, in the land;
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
also all the store cities, which Solomon had, and the cities for chariots, and the cities for horsemen, —and the desire of Solomon that he was pleased to build in Jerusalem, and in Lebanon, and in all the land that he ruled over.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
All the people that were left, of the Amorites, the Hittites, the Perizzites, the Hivites and the Jebusites, who were, not of the sons of Israel;
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
their sons, who were left after them in the land, whom the sons of Israel were not able to devote to destruction, Solomon levied them for a toiling labour-band [which remaineth] unto this day.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
But, of the sons of Israel, Solomon devoted none to bond-service, —but, they, were men of war, and his servants, and his generals, and his heroes, and captains of his chariots, and his horsemen.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
These, were the chiefs of the officers, who were over the work, for Solomon, five hundred and fifty, —who ruled over the people that wrought in the work.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Scarcely had Pharaoh’s daughter come up out of the city of David, into her own house, which he had built for her, when he built Millo.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
And Solomon used to offer, three times a year, ascending-sacrifices and peace-offerings, upon the altar which he had built unto Yahweh, and to offer incense at the altar which was before Yahweh, —thus Solomon gave completeness unto the house.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
A fleet also, did King Solomon build in Ezion-geber, which is beside Eloth on the shore of the Red Sea, in the land of Edom.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
And Hiram sent in the fleet his servants, seamen, having knowledge of the sea, —with the servants of Solomon;
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
and they came to Ophir, and fetched from thence, gold, four hundred and twenty talents, —and brought it to King Solomon.

< 1 Kings 9 >