< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
Stalo se pak, když dokonal Šalomoun stavení domu Hospodinova a domu královského, podlé vší líbosti své, jakž vykonati umínil,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
Že se ukázal Hospodin Šalomounovi podruhé, jakož se mu byl ukázal v Gabaon.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
I řekl jemu Hospodin: Vyslyšelť jsem modlitbu tvou a prosbu tvou, kteroužs se modlil přede mnou; posvětil jsem domu toho, kterýž jsi vystavěl, aby přebývalo tam jméno mé až na věky, a byly tu oči mé i srdce mé po všecky dny.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
A ty jestliže choditi budeš přede mnou, jako chodil David otec tvůj, v dokonalosti srdce a v upřímnosti, čině všecko to, což jsem přikázal tobě, ustanovení mých i soudů mých ostříhaje:
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
Utvrdím zajisté stolici království tvého nad Izraelem na věky, jakož jsem mluvil Davidovi otci tvému, řka: Nebudeť odjat muž z rodu tvého od trůnu Izraelského.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
Pakli se nazpět odvrátíte vy i synové vaši ode mne, a nebudete ostříhati přikázaní mých a ustanovení mých, kteráž jsem vydal vám, ale odejdouce, sloužiti budete bohům cizím a klaněti se jim:
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
Vypléním docela Izraele se svrchku země, kterouž jsem jim dal, a dům tento, kteréhož jsem posvětil jménu svému, zavrhu od tváři své, i budeť Izrael za přísloví a za rozprávku mezi všemi národy.
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
Ano i dům tento, jakkoli bude slavný, kdokoli mimo něj půjde, užasne se a ckáti bude, i řekne: Proč tak učinil Hospodin zemi této a domu tomuto?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
Tedy odpovědí: Proto že opustili Hospodina Boha svého, kterýž vyvedl otce jejich z země Egyptské, a chytili se bohů cizích, a klaněli se jim i sloužili jim, protož uvedl na ně Hospodin všecky tyto zlé věci.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
Stalo se také po přeběhnutí dvadcíti let, v nichž vzdělal Šalomoun oba dva ty domy, dům Hospodinův a dům královský,
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
K čemuž byl Chíram král Tyrský daroval Šalomounovi hojně dříví cedrového a jedlového, i zlata vedlé vší vůle jeho, že dal také král Šalomoun Chíramovi dvadceti měst v zemi Galilejské.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
I vyjel Chíram z Týru, aby viděl ta města, kteráž mu daroval Šalomoun, ale nelíbila se jemu.
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
Protož řekl: Jakáž jsou ta města, kteráž mi dáváš, bratře můj? I nazval je zemí Kabul až do tohoto dne.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Nebo byl poslal Chíram králi sto a dvadceti centnéřů zlata.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
Příčina pak platu, kterýž byl uložil král Šalomoun, byla, aby stavěl dům Hospodinův a dům svůj, a Mello i zdi Jeruzalémské, též Azor a Mageddo i Gázer.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
(Farao zajisté král Egyptský vytáh, dobyl Gázeru a vypálil je, Kananejské pak, kteříž byli v tom městě, pobil a dal město za věno dceři své, manželce Šalomounově.)
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
A tak vystavěl zase Šalomoun Gázer a Betoron dolní,
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
Též Baalat a Tadmor na poušti v též zemi,
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
I všecka města, v nichž Šalomoun měl své sklady, i města vozů, i města jezdců, vše vedlé žádosti své, cožkoli chtěl stavěti v Jeruzalémě, a na Libánu i po vší zemi panování svého.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
Všecken také lid, kterýž byl pozůstal z Amorejských, Hetejských, Ferezejských, Hevejských a Jebuzejských, kteříž nebyli z synů Izraelských,
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
Totiž syny jejich, kteříž byli pozůstali po nich v zemi, jichž nemohli synové Izraelští vyhladiti, uvedl Šalomoun pod plat a v službu až do tohoto dne.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Z synů pak Izraelských žádného nepodrobil v službu Šalomoun, ale byli muži váleční, a služebníci jeho, a knížata jeho, vůdcové jeho a úředníci nad vozy a jezdci jeho.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
Bylo těch předních vládařů, kteříž byli nad dílem Šalomounovým, pět set a padesát. Ti spravovali lidi, kteříž dělali.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Dcera pak Faraonova přestěhovala se z města Davidova do domu svého, kterýž jí byl vystavěl Šalomoun. Tehdáž také vystavěl Mello.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
I obětoval Šalomoun každého roku třikrát oběti zápalné a pokojné na oltáři, kterýž byl vzdělal Hospodinu, ale kadíval na tom, kterýž byl před Hospodinem, když dokonal dům.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
Nadělal také král Šalomoun lodí velikých v Aziongaber, kteréž jest podlé Elat, na břehu moře Rudého v zemi Idumejské.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
A poslal Chíram na těch lodech služebníky své, plavce umělé na moři, s služebníky Šalomounovými.
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
Kteříž přeplavivše se do Ofir, nabrali tam zlata čtyři sta a dvadceti centnéřů, a přivezli králi Šalomounovi.

< 1 Kings 9 >