< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Potem je Salomon zbral Izraelove starešine in vse poglavarje rodov, vodilne izmed očetov Izraelovih otrok, h kralju Salomonu v Jeruzalem, da bi lahko prinesli gor skrinjo Gospodove zaveze iz Davidovega mesta, ki je Sion.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
Vsi možje iz Izraela so se na praznik zbrali h kralju Salomonu, v mesecu etanímu, ki je sedmi mesec.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
Prišli so vsi Izraelovi starešine in duhovniki so dvignili skrinjo.
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
Gor so prinesli Gospodovo skrinjo, šotorsko svetišče skupnosti shoda in vse svete posode, ki so bile v šotorskem svetišču, celo te so duhovniki in Lévijevci prinesli gor.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Kralj Salomon in vsa Izraelova skupnost, ki je bila zbrana k njemu, so bili z njim pred skrinjo. Žrtvovali so ovce in vole, ki se jih zaradi množice ni dalo ne povedati ne prešteti.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Duhovniki so skrinjo Gospodove zaveze prinesli na njeno mesto, v hišni orakelj, k najsvetejšemu kraju, celo pod peruti kerubov.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Kajti keruba sta svoji dve peruti razprostirala nad prostorom skrinje in keruba sta od zgoraj pokrivala skrinjo in njena drogova.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
Drogova so izvlekli, da sta se konca drogov videla iz svetega kraja pred orakljem, odzunaj pa nista bila vidna in tam sta do današnjega dne.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
V skrinji ni bilo ničesar razen dveh kamnitih plošč, ki ju je Mojzes položil tja pri Horebu, ko je Gospod sklenil zavezo z Izraelovi otroci, ko so prišli iz egiptovske dežele.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
Pripetilo se je, ko so duhovniki prišli ven iz svetega kraja, da je oblak napolnil Gospodovo hišo,
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
tako da duhovniki zaradi oblaka niso mogli stati, da bi služili, kajti Gospodova slava je napolnila Gospodovo hišo.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Potem je spregovoril Salomon: » Gospod je rekel, da bo prebival v gosti temi.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Zagotovo sem ti zgradil hišo, da prebivaš v njej, ustaljen kraj zate, da v njem prebivaš na veke.«
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
Kralj je obrnil svoj obraz naokrog in blagoslovil vso Izraelovo skupnost (in vsa Izraelova skupnost je stala)
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
in rekel je: »Blagoslovljen bodi Gospod, Izraelov Bog, ki je s svojimi usti spregovoril mojemu očetu Davidu in je to izpolnil s svojo roko, rekoč:
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
›Od dneva, ko sem svoje ljudstvo Izraela privedel ven iz Egipta, nisem izbral nobenega mesta izmed vseh Izraelovih rodov, da bi zgradil hišo, da bi bilo v njej lahko moje ime, temveč sem izbral Davida, da bo nad mojim ljudstvom Izraelom.‹
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
To je bilo na srcu mojega očeta Davida, da zgradi hišo za ime Gospoda, Izraelovega Boga.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
Gospod je rekel mojemu očetu Davidu: ›Medtem ko je bilo to v tvojem srcu, da zgradiš hišo mojemu imenu, si storil dobro, da je bilo to v tvojem srcu.
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Vendar pa hiše ne boš gradil ti, temveč tvoj sin, ki bo izšel iz tvojih ledij, on bo zgradil hišo mojemu imenu.‹
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Gospod je izpolnil svojo besedo, ki jo je govoril in dvignjen sem bil na položaj svojega očeta Davida in sedim na Izraelovem prestolu, kakor je obljubil Gospod in zgradil sem hišo za ime Gospoda, Izraelovega Boga.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Tam sem pripravil prostor za skrinjo, v kateri je Gospodova zaveza, ki jo je on sklenil z našimi očeti, ko jih je privedel ven iz egiptovske dežele.«
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Salomon je stal pred Gospodovim oltarjem v prisotnosti vse Izraelove skupnosti in svoji roki razširil proti nebu
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
in rekel: » Gospod, Izraelov Bog, ni Boga, podobnega tebi, na nebu zgoraj ali na zemlji spodaj, ki ohranjaš zavezo in usmiljenje s svojimi služabniki, ki z vsem svojim srcem hodijo pred teboj,
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
ki si svojemu služabniku Davidu, mojemu očetu, ohranil to, kar si mu obljubil. Govoril si s svojimi usti in si to tudi izpolnil s svojo roko, kakor je to ta dan.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Zato zdaj Gospod, Izraelov Bog, ohrani s svojim služabnikom Davidom, mojim očetom, to, kar si mu obljubil, rekoč: ›Ne bo ti zmanjkalo moža v mojem pogledu, da bi sedel na Izraelovem prestolu; samo da tvoji otroci pazijo na svojo pot, da hodijo pred menoj, kakor si ti hodil pred menoj.‹
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Sedaj, oh Izraelov Bog, naj bo tvoja beseda, prosim te, resnična, ki si jo govoril svojemu služabniku, mojemu očetu Davidu.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
Toda ali bo Bog zares prebival na zemlji? Glej, nebo in nebesa nebes te ne morejo obseči, kako veliko manj ta hiša, ki sem jo zgradil?
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
Vendar se ozri na molitev svojega služabnika in k njegovi ponižni prošnji, oh Gospod, moj Bog, da prisluhneš klicu in molitvi, ki jo ta dan tvoj služabnik moli pred teboj,
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
da bodo tvoje oči lahko ponoči in podnevi odprte proti tej hiši, torej proti kraju, o katerem si rekel: ›Moje ime bo tam, ‹ da boš lahko prisluhnil molitvi, ki jo bo tvoj služabnik naredil k temu kraju.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Prisluhni ponižni prošnji svojega služabnika in svojega ljudstva Izraela, ko bodo molili k temu kraju. Pozorno poslušaj v nebesih, svojem prebivališču. In ko si pozorno slišal, odpusti.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
Če se katerikoli človek prekrši zoper svojega bližnjega in je nanj položena prisega, da mu povzroči, da priseže in prisega pride pred tvoj oltar v tej hiši,
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
potem pozorno poslušaj v nebesih, ukrepaj in sodi svoja služabnika, obsodi zlobnega, da privedeš njegovo pot na njegovo glavo in opraviči pravičnega, da mu daš glede na njegovo pravičnost.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
Ko bo tvoje ljudstvo Izrael udarjeno pred sovražnikom, ker so grešili zoper tebe in se bo ponovno obrnilo k tebi, priznalo tvoje ime, molilo in naredilo ponižno prošnjo k tebi v tej hiši,
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
potem pozorno poslušaj v nebesih in odpusti greh svojega ljudstva Izraela in jih ponovno privedi v deželo, ki jo daješ njihovim očetom.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Ko je nebo zaprto in ni dežja, ker so grešili zoper tebe; če molijo k temu kraju in priznajo tvoje ime in se obrnejo od svojega greha, ko si jih ti prizadel,
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
potem pozorno poslušaj v nebesih in odpusti greh svojih služabnikov in svojega ljudstva Izraela, da jih naučiš dobro pot, po kateri naj bi hodili in jim daš dež na svojo deželo, ki si jo dal svojemu ljudstvu v dediščino.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
Če bo v deželi lakota, če bo kužna bolezen, kvarjenje, plesen, leteča kobilica ali če bo tam gosenica; če jih njihov sovražnik oblega v deželi njihovih mest, kakršnakoli nadloga, kakršnakoli bolezen bo,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
kakršnokoli molitev in ponižno prošnjo bo naredil katerikoli človek ali vse tvoje ljudstvo Izrael, ki bo spoznal, vsak mož nadlogo svojega lastnega srca in bo svoje roke razširil proti tej hiši,
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
potem pozorno poslušaj v nebesih, svojem prebivališču, odpusti, ukrepaj in daj vsakemu možu glede na njegove poti, čigar srce poznaš (kajti ti, celó le ti, poznaš srca vseh človeških otrok),
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
da se te bodo lahko bali vse dni, ki jih živijo v deželi, ki si jo dal našim očetom.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Poleg tega glede tujca, ki ni iz tvojega ljudstva Izraela, temveč zaradi tvojega imena prihaja iz daljne dežele
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
(kajti slišali bodo o tvojem velikem imenu, o tvoji močni roki in o tvojem iztegnjenem laktu), ko bo prišel in molil k tej hiši,
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
pozorno poslušaj v nebesih, svojem bivališču in ukrepaj glede na vse, za kar bo tujec klical k tebi, da bo vse ljudstvo zemlje lahko spoznalo tvoje ime, da se te boji, kakor to dela tvoje ljudstvo Izrael in da bodo lahko vedeli, da je ta hiša, ki sem jo zgradil, imenovana po tvojem imenu.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
Če gre tvoje ljudstvo ven na bitko zoper svojega sovražnika, kamorkoli jih boš poslal in bodo molili h Gospodu, k mestu, ki si ga ti izbral in k hiši, ki sem jo zgradil za tvoje ime,
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
potem pozorno poslušaj v nebesih njihovo molitev, njihovo ponižno prošnjo in obravnavaj njihov primer.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
Če grešijo zoper tebe (kajti tam ni človeka, ki ne greši) in si jezen nanje in jih izročiš sovražniku, tako da jih odvedejo ujetnike v deželo sovražnika, daleč ali blizu,
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
vendar če si bodo premislili v deželi, kamor so bili odvedeni ujeti in se pokesajo in naredijo ponižno prošnjo k tebi, v deželi tistih, ki so jih odvedli ujete, rekoč: ›Grešili smo in storili pokvarjeno, zagrešili smo zlobnost‹
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
in se tako vrnejo k tebi z vsem svojim srcem in z vso svojo dušo v deželi svojih sovražnikov, ki so jih odvedli ujete in molijo k tebi, k svoji deželi, ki si jo dal njihovim očetom, mestu, ki si ga ti izbral in hiši, ki sem jo zgradil za tvoje ime,
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
potem pozorno poslušaj njihovo molitev in njihovo ponižno prošnjo v nebesih, svojem prebivališču in obravnavaj njihov primer
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
in odpusti svojemu ljudstvu, ker so grešili zoper tebe in vse njihove prestopke, s katerimi so se prekršili zoper tebe in jim daj sočutje pred tistimi, ki so jih odvedli ujete, da bodo lahko imeli sočutje do njih,
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
kajti oni so tvoje ljudstvo in tvoja dediščina, ki si jo privedel iz Egipta, iz srede železne talilne peči,
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
da bodo tvoje oči lahko odprte k ponižni prošnji tvojega služabnika in k ponižni prošnji tvojega ljudstva Izraela, da jim prisluhneš v vsem, v čemer kličejo k tebi.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Kajti oddvojil si jih izmed vsega zemeljskega ljudstva, da bi bili tvoja dediščina, kakor si govoril po roki svojega služabnika Mojzesa, ko si naše očete privedel iz Egipta, oh Gospod Bog.«
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
Bilo je tako, ko je Salomon nehal moliti vso to molitev in ponižno prošnjo h Gospodu, da je vstal izpred Gospodovega oltarja od klečanja na svojih kolenih, s svojima rokama, razširjenima k nebu.
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
Vstal je in z močnim glasom blagoslovil vso Izraelovo skupnost, rekoč:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
»Blagoslovljen bodi Gospod, ki je svojemu ljudstvu Izraelu dal počitek, glede na vse, kar je obljubil. Niti ena beseda ni manjkala od vse njegove dobre obljube, ki jo je obljubil po roki svojega služabnika Mojzesa.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Gospod, naš Bog, naj bo z nami, kakor je bil z našimi očeti. Naj nas ne pusti niti naj nas ne zapusti,
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
da bo lahko naša srca nagnil k sebi, da hodimo po vseh njegovih poteh in da ohranjamo vse njegove zapovedi, njegove zakone in njegove sodbe, ki jih je zapovedal našim očetom.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
Naj bodo te moje besede, s katerimi sem naredil ponižno prošnjo pred Gospodom, blizu Gospodu, našemu Bogu, podnevi in ponoči, da ohrani zadevo svojega služabnika in zadevo svojega ljudstva Izraela ob vseh časih, kakor bo stvar zahtevala,
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
da bo vse ljudstvo zemlje lahko vedelo, da Gospod je Bog in da tam ni nobenega drugega.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Naj bo vaše srce torej popolno z Gospodom, našim Bogom, da se ravna po njegovih zakonih in da ohranja njegove zapovedi, kakor je ta dan.«
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Kralj in ves Izrael z njim je daroval klavno daritev pred Gospodom.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
Salomon je daroval žrtvovanje mirovnih daritev, ki jih je daroval Gospodu, dvaindvajset tisoč volov in sto dvajset tisoč ovc. Tako so kralj in vsi Izraelovi otroci posvetili Gospodovo hišo.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
Istega dne je kralj posvetil sredino dvora, ki je bila pred Gospodovo hišo, kajti tam je daroval žgalne daritve, jedilne daritve in tolščo mirovnih daritev, ker je bil bronast oltar, ki je bil pred Gospodom, premajhen, da sprejme žgalne daritve, jedilne daritve in tolščo mirovnih daritev.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
Ob tistem času je Salomon priredil praznovanje in ves Izrael z njim, velika skupnost, od vhoda v Hamát do egiptovske reke, pred Gospodom, svojim Bogom, sedem dni in sedem dni, torej štirinajst dni.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
Na osmi dan je ljudstvo odposlal proč in blagoslovili so kralja in radostni in veselega srca zaradi vse dobrote, ki jo je Gospod storil za svojega služabnika Davida in za svoje ljudstvo Izrael, odšli k svojim šotorom.

< 1 Kings 8 >