< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
И собра царь Соломон вся старейшины Израилевы, вся начала колен, старейшины отечеств сынов Израилевых к себе во Сион, еже пренести кивот завета Господня от града Давидова: той есть Сион.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
И собрашася ко царю Соломону вси людие Израилевы в месяц Афаним в праздник: сей есть месяц седмый.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
И приидоша вси старейшины Израилевы, и взяша иерее кивот,
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
и вознесоша кивот Господень, и скинию свидения, и вся сосуды святыя яже во скинии свидения: и вознесоша я иерее и левити.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Царь же Соломон и весь собор Израилский, собравшеся к нему, с ним пред кивотом жряху волы и овцы несочтенны, безчисленны от множества.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
И внесоша иерее кивот завета Господня на место его во давир храма, во Святая Святых, под крила херувимов.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Херувими бо беша распростерше криле над местом кивота: и окрываху херувими над кивотом и над святыми его сверху.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
И обдержаста освященая: и зряхуся главы освященных от святых к лицу давира, и не являхуся вне.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Не бе в кивоте токмо две скрижали каменны, скрижали завета, ихже положи Моисей в Хориве, яже завеща Господь со сынами Израилевыми, внегда исходити им от земли Египетския.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
И бысть егда изыдоша иерее из святилища, и облак исполни храм Господень,
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
и не можаху иерее стати служити от лица облака, яко исполни слава Господня храм.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Тогда рече Соломон: Господь рече еже обитати во мгле,
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
аз же создах дом имени Твоему свят Тебе и готов, и престолу твоему, еже обитати Тебе в нем во веки.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
И обрати царь лице свое и благослови царь всего Израиля: весь же собор Израилев стояше.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
И рече (царь): благословен Господь Бог Израилев днесь, Иже глагола усты Своими о Давиде отце моем и рукама Своима исполни, глаголя:
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
от дне в оньже изведох люди Моя Израиля из Египта, не избрах града от всех племен Израилевых на создание храму, еже быти имени Моему тамо: но избрах во Иерусалиме быти имени Моему тамо: и избрах Давида быти ему властелину над людьми Моими Израилем:
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
и бысть на сердцы отцу моему Давиду, еже создати храм имени Господа Бога Израилева,
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
и рече Господь к Давиду отцу моему: понеже взыде на сердце твое еже создати храм имени Моему, добре сотворил еси, яко бысть на сердцы твоем:
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
обаче ты не созиждеши храма, но разве сын твой, иже изыде из чресл твоих, той созиждет храм имени Моему:
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
и возстави Господь глаголгол Свой егоже глагола: и востах вместо Давида отца моего, и седох на престоле Израилеве, якоже глагола Господь, и создах храм имени Господа Бога Израилева,
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
и поставих тамо место кивоту, в немже есть тамо завет Господень, егоже завеща Господь со отцы нашими во извождении их из земли Египетския.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
И ста Соломон пред лицем олтаря Господня пред всем собором Израилевым и воздвиже руце свои на небо,
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
и рече: Господи Боже Израилев, несть якоже Ты Бог на небеси горе и на земли низу, храняй завет и милость рабу Твоему ходящему пред Тобою всем сердцем своим,
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
яже сохранил еси рабу Твоему Давиду отцу моему: ибо глаголал еси усты Твоими и рукама Твоима совершил еси, якоже день сей:
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
и ныне, Господи Боже Израилев, сохрани рабу Твоему Давиду отцу моему, яже рекл еси ему, глаголя: не оскудеет муж от лица Моего седяй на престоле Израилеве, токмо аще сохранят чада твоя пути своя, еже ходити предо Мною, якоже ходил еси предо Мною:
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
и ныне, Господи Боже Израилев, да уверится глаголгол Твой, егоже рекл еси Давиду отцу моему:
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
яко аще истинно вселится Бог с человеки на земли? Аще небо и небо небесе не довлеют Ти, кольми паче храм сей, егоже создах имени Твоему?
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
И да призриши на молитву мою, Господи Боже Израилев, послушати молитвы, еюже молится раб Твой пред тобою к Тебе днесь,
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
да будут очи Твои отверсты на храм сей день и нощь, на место о немже рекл еси: будет имя Мое тамо на услышание молитвы, еюже молится раб Твой на месте сем день и нощь:
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
и услышиши молитву раба Твоего и людий Твоих Израиля, о нихже помолятся на месте сем: и ты услышиши на месте обиталища Твоего на небеси, и сотвориши и помилуеши:
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
елика аще согрешит кийждо ко искреннему своему, и аще приимет на него клятву еже кляти его, и приидет, и исповесть пред лицем олтаря Твоего в храме сем:
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
и Ты услышиши от небесе, и сотвориши суд людем Твоим Израилю: осудити беззаконнаго, дати путь его на главу его, и оправдити праведнаго, дати ему по правде его:
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
егда падут людие Твои Израиль пред враги, яко согрешат Ти, и обратятся к Тебе, и исповедятся имени Твоему, и помолятся и возглаголют молитву к Тебе в храме сем:
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
и Ты услышиши с небесе, и милостив будеши о согрешениих людий Своих Израиля, и возвратиши я в землю, юже дал еси отцем их:
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
внегда заключитися небеси и не быти дождю, яко согрешат Ти, и помолятся на месте сем, и исповедятся имени Твоему, и от грех своих обратятся, егда смириши их:
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
и услышиши с небесе, и милостив будеши о гресех раба Твоего и людий Твоих Израиля: яко явиши им путь благий ходити по нему, и даси дождь на землю, юже дал еси людем Твоим в достояние:
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
глад аще будет, смерть аще будет, егда будет возжжение, гусеницы, ржа аще будет, и аще оскорбят я врази их в единем от градов их: все противное, всяка болезнь,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
всяка молитва, всяко моление аще будет всякому человеку от людий Израилевых, егда познает кийждо болезнь сердца своего, и воздвигнет руце свои в храме сем:
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
и Ты услышиши от небесе, от готоваго жилища Твоего, и милостив будеши, и сотвориши, и даси коемуждо по путем его, якоже увеси сердце его, яко Ты един токмо веси всех сердца сынов человеческих:
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
да боятся Тебе вся дни, в няже поживут на земли, юже дал еси отцем нашым:
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
и чуждему, иже несть от людий Твоих Израиля, той аще приидет от земли издалеча ради имене Твоего, зане услышат имя Твое велико, и руку Твою крепкую, и мышцу Твою высокую,
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
и приидет, и помолится на месте сем:
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
и ты услышиши с небесе от готоваго жилища Твоего, и сотвориши по всем, в еликих аще призовет Тя чуждий, яко да уразумеют вси людие земнии имя Твое и убоятся Тебе, якоже людие Твои Израиль, и разумеют, яко имя Твое наречеся на храме сем, егоже создах:
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
егда изыдут людие Твои на брань на враги своя, путем имже возвратиши я, и помолятся именем Господним путем града, егоже избрал еси Себе, и ко храму, егоже аз создах имени Твоему:
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
и ты услышиши с небесе молитву их и моления их, и сотвориши оправдание им:
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
яко согрешат Ти, яко несть человек, иже не согрешит, и разгневаешися на ня, и предаси я пред враги, и попленят их пленящии в землю далече, или близ,
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
и обратят сердца своя в земли, аможе преселишася, и обратятся, и помолятся Тебе в земли преселения своего, глаголюще: согрешихом, беззаконновахом, неправдовахом:
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
и обратятся ко Тебе всем сердцем своим и всею душею своею в земли враг своих, аможе превел еси их, и помолятся к Тебе по пути земли своея, юже дал еси отцем их, и ко граду, егоже избрал еси, и ко храму, егоже создах имени Твоему:
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
и услышиши от небесе, от готоваго жилища Твоего молитву их и моление их, и сотвориши оправдание им,
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
и милостив будеши неправдам их, имиже согрешиша Ти, и по всем отметанием их, имиже отвергошася Тебе, да даси их в щедроты пред пленившими их, и ущедрят я:
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
яко людие Твои и наследие Твое суть, ихже извел еси из земли Египетския от среды пещи железныя:
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
и да будут уши Твои и очи Твои отверсты на молитву раба Твоего и к молению людий Твоих Израиля, послушати их о всех, о нихже призовут Тя,
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
яко Ты избрал еси я Себе в наследие от всех людий земли, якоже глаголал еси рукою раба Твоего Моисеа, внегда извести Тебе отцы нашя из земли Египетския, Господи Господи. Тогда глагола Соломон о храме, егда соверши созидати его: солнце познано сотвори на небеси: Господь рече пребывати во мгле: созижди храм Мой, храм благолепный себе, еже пребывати в новости: не сие ли писано в книгах песни?
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
И бысть егда сконча Соломон моляся ко Господу всею молитвою и молением сим, и воста от лица олтаря Господня припад на колена своя, и руце свои возде на небо,
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
и ста, и благослови весь собор Израилев, гласом велиим глаголя:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
благословен Господь (Бог) днесь, Иже даде покой людем Своим Израилю, по всем елика глагола: не пременися слово ни едино во всех словесех Его благих, имиже глагола рукою Моисеа раба Своего:
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
да будет Господь Бог наш с нами, якоже бе со отцы нашими: да не оставит нас, ниже да отвратит нас,
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
преклонити сердца наша к Нему, еже ходити во всех путех Его и хранити вся заповеди Его и повеления Его и оправдания Его, яже заповеда отцем нашым:
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
и да будут словеса сия, имиже молихся пред Господем Богом нашим днесь, приближающеся Господу Богу нашему день и нощь, еже творити оправдания рабу Твоему и оправдания людем Твоим Израилю во вся дни:
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
яко да разумеют вси людие земли, яко Господь Бог Той Сам Бог, и несть инаго,
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
и да будут сердца наша совершенна ко Господу Богу нашему преподобно ходити в повелениих Его и хранити заповеди Его, якоже день сей.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
И царь и вси сынове Израилевы пожроша жертву пред Господем.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
И пожре царь Соломон жертвы мирныя, яже пожре Господу, волов двадесять две тысящы и овец сто и двадесять тысящ. И обнови царь храм Господень и вси сынове Израилевы.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
В той день освяти царь (Соломон) средину двора, яже пред лицем храма Господня: яко сотвори тамо всесожжение и дары, и жертвы и тучная мирных, яко олтарь медяный, иже пред Господем, мал бе, еже не возмощи вместити всесожжения даров и жертвы мирных.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
И сотвори Соломон праздник в той день, и весь Израиль с ним, собор велий, от входа Емафа даже до реки Египта, пред Господем Богом нашим, у храма, егоже созда, ядый и пия и веселяся пред Господем Богом нашим седмь дний,
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
и во осмый день распусти люди. И благословиша царя, и идоша кийждо в домы своя, радующеся веселым сердцем о благих, яже сотвори Господь Давиду рабу Своему и Израилю людем Своим.

< 1 Kings 8 >