< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Tedy zebrał Salomon starsze Izraelskie, i wszystkie celniejsze z każdego pokolenia, i przedniejsze z ojców synów Izraelskich, do siebie do Jeruzalemu, aby przeniesiona była skrzynia przymierza Pańskiego z miasta Dawidowego, które jest Syon.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
I zeszli się do króla Salomona wszyscy mężowie Izraelscy mięsiąca Września w uroczyste święto; a ten miesiąc jest siódmy.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
A gdy się zeszli wszyscy starsi Izraelscy, wzięli kapłani skrzynię.
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
I przenieśli skrzynię Pańską, i namiot zgromadzenia, i wszystkie naczynia święte, które były w namiocie, a przenieśli je kapłani i Lewitowie.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Lecz król Salomon, i wszystko mnóstwo Izraelskie, które się zeszło do niego, z nim przed skrzynią ofiarowali owce i woły, których nie liczono ani rachowano dla mnóstwa.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Wnieśli tedy kapłani skrzynię przymierza Pańskiego na miejsce jej do wnętrznego domu, do świątnicy świętych, pod skrzydła Cherubinów.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Albowiem Cherubinowie mieli rozciągnione skrzydła nad miejscem skrzyni, a okrywali Cherubinowie skrzynię i drążki jej z wierzchu.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
I powyciągali one drążki, tak, że widać było końce ich w świątnicy na przodku świątnicy świętych; ale nie widać ich było zewnątrz; i tamże były aż do dnia tego.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Nic nie było w skrzyni tylko dwie tablice kamienne, które tam był schował Mojżesz na Horebie, gdy stanowił przymierze Pan z synami Izraelskimi, gdy szli z ziemi Egipskiej.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
I stało się, gdy wychodzili kapłani z świątnicy, że obłok napełnił dom Pański.
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
Tak iż się nie mogli kapłani ostać i służyć dla onego obłoku; albowiem napełniła była chwała Pańska dom Pański.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Tedy rzekł Salomon: Pan powiedział, iż miał mieszkać we mgle.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Jużem zbudował dom na mieszkanie tobie, miejsce, abyś tam przebywał na wieki.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
I obrócił król oblicze swoje, i błogosławił wszystkiemu zgromadzeniu Izraelskiemu; a wszystko zgromadzenie Izraelskie stało.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
I rzekł: Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, który mówił usty swemi do Dawida, ojca mego, i skutecznie to wypełnił, mówiąc:
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Ode dnia, któregom wywiódł lud mój Izraelski z Egiptu, nie obrałem miasta ze wszystkich pokoleń Izraelskich ku zbudowaniu domu, gdzieby przebywało imię moje, alem obrał Dawida, aby był nad ludem moim Izraelskim.
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Postanowiłci był wprawdzie w sercu swem Dawid, ojciec mój, zbudować dom imieniowi Pana, Boga Izraelskiego;
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
Ale rzekł Pan do Dawida, ojca mego: Aczkolwiekeś postanowił w sercu twem, zbudować dom imieniowi memu, i dobrześ uczynił, żeś to umyślił w sercu twojem.
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Wszakże ty nie będziesz budował tego domu; ale syn twój, który wynijdzie z biódr twoich, ten zbuduje dom imieniowi memu.
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
A tak utwierdził Pan słowo swoje, które był powiedział. Bom ja powstał miasto Dawida, ojca mego, i usiadłem na stolicy Izraelskiej, jako był powiedział Pan, i zbudowałem dom imieniowi Pana, Boga Izraelskiego
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
I naznaczyłem tam miejsce skrzyni, w której jest przymierze Pańskie, które uczynił z ojcy naszymi, gdy je wywiódł z ziemi Egipskiej.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Tedy stanął Salomon przed ołtarzem Pańskim, przed wszystkiem zgromadzeniem Izraelskiem, i wyciągnął ręce swoje ku niebu,
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
I rzekł: Panie, Boże Izraelski, niemasz tobie podobnego Boga na niebie wzgórę, ani na ziemi nisko; który chowasz umowę i miłosierdzie sługom twym, którzy chodzą przed tobą całem sercem swojem;
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
Któryś spełnił słudze twemu Dawidowi, ojcu memu, coś mu powiedział; coś mówił usty swemi, toś skutecznie wypełnił, jako się dnia tego pokazuje.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Przetoż teraz o Panie, Boże Izraelski, ziść słudze twemu Dawidowi, ojcu memu, coś mu powiedział, mówiąc: Nie będzie odjęty przed twarzą moją z narodu twego mąż, któryby siedział na stolicy Izraelskiej, jeźli tylko będą przestrzegali synowie twoi drogi swej, chodząc przede mną, jakoś ty chodził przed oblicznością moją.
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Przetoż teraz, o Boże Izraelski, niech będzie utwierdzone proszę słowo twoje, któreś mówił do sługi twego Dawida, ojca mego.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
(Aczci wprawdzie, izali Bóg będzie mieszkał na ziemi? Oto niebiosa, i nieba niebios, nie mogą cię ogarnąć; jakoż daleko mniej ten dom, którym zbudował.)
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
A wejrzyj na modlitwę sługi twego, i na prośbę jego, o Panie Boże mój, wysłuchaj wołanie i modlitwę, którą się dziś sługa twój modli przed tobą.
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
A niech będą otworzone oczy twoje nad tym domem w nocy i we dnie, nad tem miejscem, o któremeś powiedział: Tu będzie imię moje; abyś wysłuchiwał modlitwę, którą się będzie modlił sługa twój na miejscu tem.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Wysłuchajże prośby sługi twego, i ludu twego Izraelskiego, który się modlić będzie na tem miejscu. Ty wysłuchaj z miejsca mieszkania twego, z nieba, a wysłuchawszy bądź miłościw.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
Gdyby człowiek zgrzeszył przeciwko bliźniemu swemu, a przywiódłby go do przysięgi, tak, żeby przysięgać musiał, a przyszłaby ta przysięga przed ołtarz twój w tym domu:
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
Ty wysłuchaj z nieba, a rozeznaj i rozsądź sługi twoje, potępiając niezbożnego, i obracając sprawy jego na głowę jego, a usprawiedliwiając sprawiedliwego, oddawając mu według sprawiedliwości jego.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
Gdyby był porażony lud twój Izraelski od nieprzyjaciela, przeto iż zgrzeszyli przeciw tobie, a nawróciliby się do ciebie, wyznawając imię twoje, a modląc się, przepraszaliby cię w tym domu:
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
Ty wysłuchaj z nieba, i odpuść grzech ludowi twemu Izraelskiemu, a przywróć je zasię do ziemi, którąś dał ojcom ich.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Gdyby zawarte było niebo, a nie byłoby dżdżu, przeto że zgrzeszyli przeciwko tobie, a modliliby się na tem miejscu, wyznawając imię twoje, a od grzechów swoich odwróciliby się, gdybyś je utrapił:
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
Ty wysłuchaj z nieba, a odpuść grzech sług twoich, i ludu twego Izraelskiego, nauczywszy ich drogi prawej, po której chodzić mają, a daj deszcz na ziemię twoję, którąś dał w dziedzictwo ludowi twemu.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
Byłliby głód na ziemi, byłliby mor, susza, rdza, szarańcza, jeźliby były chrząszcze, jeźliby go ścisnął nieprzyjaciel jego w ziemi mieszkania jego, albo jakakolwiek plaga, albo jakakolwiek niemoc:
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
Wszelką modlitwę, i wszelką prośbę, którąby czynił którykolwiek człowiek, albo wszystek lud twój Izraelski, ktoby jedno uznał ranę serca swego, i wyciągnąłby ręce swe w domu tym:
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
Ty wysłuchaj z nieba, z miejsca mieszkania twego, a odpuść, i uczyń, i oddaj każdemu według wszelkich dróg jego, które znasz w sercu jego; bo ty, ty sam znasz serca wszystkich synów ludzkich;
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
Aby się ciebie bali po wszystkie dni, które żyć będą na ziemi, którąś dał ojcom naszym.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Nadto i cudzoziemiec, który nie jest z ludu twego Izraelskiego, przyjdzieli z ziemi dalekiej dla imienia twego;
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
(Bo usłyszą o imieniu twojem wielkiem, i o ręce twojej możnej, i o ramieniu twojem wyciągnionem, ) przyjdzieli tedy, a będzie się modlił w tym domu:
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
Ty wysłuchaj z nieba, z miejsca mieszkania twego, a uczyń wszystko, o co zawoła do ciebie on cudzoziemiec, aby poznali wszyscy narodowie ziemscy imię twoje, i bali się ciebie, jako lud twój Izraelski, a żeby wiedzieli, że imię twoje wzywane jest nad tym domem, którym zbudował.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
Gdyby wyszedł lud twój na wojnę przeciwko nieprzyjacielowi swemu drogą, którą je poślesz, a modliliby się Panu, obróciwszy się ku miastu, któreś obrał, i ku domowi, którym zbudował imieniowi twemu:
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
Wysłuchajże z nieba modlitwę ich, i prośbę ich, a wykonaj sąd ich.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
Gdyby też zgrzeszyli przeciwko tobie, (bo niemasz człowieka, któryby nie grzeszył, ) a rozgniewawszy się na nie, podałbyś je pod moc nieprzyjacielowi, któryby je pojmawszy, zawiódł je w niewolę, do ziemi nieprzyjacielskiej, dalekiej albo bliskiej:
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
A upamiętaliby się w sercu swojem w onej ziemi, do której są zaprowadzeni w niewolę, i nawróciliby się, a przepraszaliby cię w ziemi tych, którzy je pojmali, mówiąc: Zgrzeszyliśmy, i źleśmy uczynili, niepobożnieśmy się sprawowali;
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
A tak nawróciliby się do ciebie z całego serca swego, i z całej duszy swej, w ziemi nieprzyjaciół swoich, którzy je pojmali, a modliliby się tobie, obróciwszy się ku ziemi swej, którąś dał ojcom ich, ku miastu, któreś obrał, i ku domowi, którym zbudował imieniowi twemu:
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
Wysłuchajże tedy z nieba, z miejsca mieszkania twego, modlitwę ich i prośbę ich, a wykonaj sąd ich,
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
A bądź miłościw ludowi twemu, który przeciw tobie zgrzeszył, i wszystkim nieprawościom ich, któremi wystąpili przeciw tobie, a nakłoń ku nim miłosierdzia tych, którzy je pojmali, aby się zmiłowali nad nimi;
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
Ponieważ są ludem twoim, i dziedzictwem twojem, któreś wywiódł z Egiptu, z pośrodku pieca żelaznego.
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
Niech będą oczy twoje otwarte na prośbę sługi twego, i na prośbę ludu twego Izraelskiego, abyś je wysłuchał we wszystkiem, o co cię wzywać będą.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Albowiemeś je ty sobie odłączył za dziedzictwo ze wszystkich narodów ziemi, jakoś powiedział przez Mojżesza, sługę twego, gdyś wywiódł ojce nasze z Egiptu, o Panie Boże!
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
I stało się, gdy Salomon modląc się Panu dokonał wszystkiej onej modlitwy i prośby, że wstał od ołtarza Pańskiego, a przestał klęczeć i podnosić rąk swoich ku niebu;
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
A stojąc błogosławił wszystkiemu zgromadzeniu Izraelskiemu wielkim głosem, mówiąc:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
Błogosławiony Pan, który dał odpocznienie ludowi swemu Izraelskiemu, według wszystkiego, co powiedział; nie chybiło żadne słowo ze wszystkich słów jego dobrych, które mówił przez Mojżesza, sługę swego.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Niechże będzie Pan, Bóg nasz, z nami, jako był z ojcy naszymi; niech nas nie opuszcza, ani nas odrzuca;
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
Ale niech nakłoni serce nasze ku sobie, żebyśmy chodzili po wszystkich drogach jego, strzegąc rozkazania jego, i wyroków jego, i sądów jego, które przykazał ojcom naszym.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
A niech będą te słowa moje, któremim się modlił przed Panem, bliskie Pana Boga naszego we dnie i w nocy, aby wykonywał sąd sługi swego, i sąd ludu swego Izraelskiego, sądząc każdą sprawę dnia swojego;
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
Żeby poznali wszyscy narodowie ziemscy, iż Pan sam jest Bogiem, a nikt inszy.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Niechże tedy będzie serce wasze doskonałe ku Panu, Bogu naszemu, abyście chodzili w wyrokach jego, a strzegli przykazań jego, jako i dnia dzisiejszego.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Tedy król, i wszystek Izrael z nim, sprawowali ofiary przed Panem.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
I ofiarował Salomon ofiarę spokojną, którą sprawował Panu, wołów dwadzieścia i dwa tysiące, i owiec sto i dwadzieścia tysięcy. A tak poświęcali dom Pański król i wszyscy synowie Izraelscy.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
Onegoż dnia poświęcił król pośrodek sieni, która była przed domem Pańskim; bo tam ofiarował całopalenie, i ofiarę śniedną, i tłustości ofiar spokojnych, przeto że ołtarz miedziany, który był przed Panem, był mały, i nie mogły się na nim zmieścić całopalenia, i ofiary śniedne, i tłustości ofiar spokojnych.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
A tak obchodził Salomon na on czas święto zacne, i wszystek Izrael z nim, zgromadzenie wielkie od wejścia do Emat aż do rzeki Egipskiej, przed Panem, Bogiem naszym, przez siedm dni i przez siedm dni, to jest, przez czternaście dni.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
A dnia ósmego rozpuścił lud; którzy błogosławiąc królowi, rozeszli się do przybytków swoich, weseląc się, i ciesząc się w sercu swem ze wszystkiego dobrego, które uczynił Pan Dawidowi, słudze swemu, i Izraelowi, ludowi swemu.

< 1 Kings 8 >