< 1 Kings 8 >
1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Katahi ka huihuia e Horomona nga kaumatua o Iharaira ratou ko nga upoko katoa o nga iwi, ko nga rangatira o nga whare o nga matua o nga tama a Iharaira ki a Kingi Horomona, ki Hiruharama, hei mau ake mo te aaka o te kawenata a Ihowa i roto i te p a o Rawiri, ara i Hiona.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
Na ka huihui nga tangata katoa o Iharaira ki a Kingi Horomona i marama Etanimi, i te hakari, ara i te whitu o nga marama.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
Na ka tae mai nga kaumatua katoa o Iharaira, a ka mau nga tohunga ki te aaka,
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
A kawea ana te aaka a Ihowa, me te tapenakara o te whakaminenga, me nga oko tapu katoa i roto i te tapenakara, kawea ana e nga tohunga ratou ko nga Riwaiti ki runga.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Na kei te tapae a Kingi Horomona, ratou ko te huihui katoa o Iharaira, i huihui nei ki a ia ki te ritenga o te aaka, i nga hipi, i nga kau, kahore nei e taea te korero, te tatau ranei, i te tini.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Na kawea ana e nga tohunga te aaka o te kawenata a Ihowa ki tona wahi, ki te ahurewa o te whare, ki te wahi tino tapu, ki raro i nga parirau o nga kerupima.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
I roha hoki nga parirau e rua o nga kerupima ki runga ki te wahi i te aaka, a taupokina iho a runga o te aaka me ona amo e nga kerupima.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
I te roroa rawa o nga amo, kitea mai ai nga pito o nga amo i te wahi tapu i te ritenga atu o te ahurewa; otiia kihai i kitea ki waho; kei reira na ano aua mea a tae noa mai ki tenei ra.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Kahore he mea i roto i te aaka, ko nga papa kohatu e rua anake i whaowhina nei ki reira e Mohi i Horepa i ta Ihowa whakaritenga kawenata ki nga tama a Iharaira, i to ratou putanga mai i te whenua o Ihipa.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
A, no te putanga mai o nga tohunga i roto i te wahi tapu, na kua ki te whare o Ihowa i te kapua,
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
A kihai i ahei i nga tohunga te tu ki te mahi, na te kapua hoki: i ki tonu ra hoki te whare o Ihowa i te kororia o Ihowa.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Katahi ka korero a Horomona, I mea a Ihowa, ka noho ia ki te pouri nui.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Kua oti nei i ahau te hanga he whare hei nohoanga mou, he kainga pumau mou mo ake tonu atu.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
Na ka tahuri te aroaro o te kingi, a manaakitia ana e ia te huihui katoa o Iharaira; a tu ana te huihui katoa o Iharaira.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Na ka mea ia, Kia whakapaingia a Ihowa, te Atua o Iharaira, na tona mangai nei te kupu ki toku papa, ki a Rawiri, a kua rite nei i tona ringa; i mea ia,
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Mai o te ra i whakaputaina mai ai e ahau taku iwi a Iharaira i Ihipa, kihai i whiriwhiria e ahau he pa i roto i nga iwi katoa o Iharaira e hanga ai he whare hei waihotanga mo toku ingoa; engari i whiriwhiria e ahau a Rawiri hei rangatira mo taku iwi, mo Iharaira.
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Na i whai ngakau toku papa, a Rawiri ki te hanga whare mo te ingoa o Ihowa, o te Atua o Iharaira.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
Otira i mea a Ihowa ki a Rawiri, ki toku papa, I te mea i roto i tou ngakau kia hanga he whare mo toku ingoa, he pai tonu te whakaaro o tou ngakau:
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Otiia e kore koe e hanga i taua whare; engari tau tama e puta mai i tou hope, mana e hanga te whare mo toku ingoa.
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Na kua mana nei i a Ihowa tana kupu i korero ai ia, a kua ara tenei ahau i muri i a Rawiri, i toku papa, a e noho nei ahau i runga i te torona o Iharaira, e pera ana me ta Ihowa i korero ai, kua hanga hoki e ahau he whare mo te ingoa o Ihowa, o te Atua o Iharaira.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
A meinga ana e ahau ki reira he wahi mo te aaka, mo te takotoranga o te kawenata a Ihowa i whakaritea e ia ki o tatou matua i tana whakaputanga mai i a ratou i te whenua o Ihipa.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Na ka tu a Horomona ki mua i te aata a Ihowa, i te aroaro o te huihui katoa o Iharaira, whewhera tonu ona ringa whaka te rangi:
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
A ka mea, E Ihowa, e te Atua o Iharaira, kahore he Atua hei rite mou i te rangi i runga, i te whenua ranei i raro, e pupuri nei i te kawenata, i te aroha ki au pononga, ina whakapaua o ratou ngakau ki te haere i tou aroaro:
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
Mau tonu hoki i a koe nga mea i korerotia e koe ki tau pononga, ki toku papa, ki a Rawiri, i korerotia nei e tou mangai ki a ia, a kua rite nei i tou ringa; koia ano tenei inaianei.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Na kia mau, e Ihowa, e te Atua o Iharaira, aianei tau i korero ai ki tau pononga, ki toku papa, ki a Rawiri, i a koe i ki ra, E kore e whakakorea he tangata mau i toku aroaro hei noho ki te torona o Iharaira; mehemea raia ka mahara au tama ki to ratou ara, kia haere i toku aroaro.
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Na kia mana aianei, e te Atua o Iharaira, au kupu i korero ai koe ki tau pononga, ki toku papa, ki a Rawiri.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
Engari he pono ranei, tera te Atua e noho ki te whenua? nana, kahore e nui hei nohoanga mou te rangi, me te rangi o nga rangi; ka iti rawa iho te whare kua hanga nei e ahau!
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
He ahakoa ra, kia anga mai koe ki te inoi a tau pononga, ki tana karanga, e Ihowa, e toku Atua, ka whakarongo ki te karanga, ki te inoi e inoi nei tau pononga ki tou aroaro i tenei ra.
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
Kia titiro mai ou kanohi ki tenei whare i te po, i te ao, ki te wahi i ki ai koe, Ko reira toku ingoa; whakarongo ki te inoi e inoi ai tau pononga ki te ritenga mai o tenei wahi.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Kia rongo hoki koe ki te karanga a tau pononga, a tau iwi hoki, a Iharaira, ina inoi ki te ritenga mai o tenei wahi; na kia rongo koe i te wahi e noho na koe i te rangi, a ka rongo, murua to ratou hara.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
Ki te hara tetahi tangata ki tona hoa, a ka meinga he oati hei oati mana, a ka tae mai ia a ka oati ki mua i tou aata i tenei whare;
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
Tena ra, mau e whakarongo mai i te rangi, e mahi, e whakarite te whakawa a au pononga, mau e whakahe te tangata he, e mea iho tona ara ki runga ano ki tona mahunga; mau ano e whakatika ta te tika, e hoatu ki a ia nga mea e rite ana ki tona tika.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
Ki te patua tau iwi, a Iharaira e te hoariri, mo ratou i hara ki a koe, a ka hoki ki a koe, ka whakaae ki tou ingoa, ka inoi, ka karanga ki a koe i roto i tenei whare:
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
Tena ra, mau e whakarongo i te rangi, e muru te hara o tau iwi, o Iharaira, e whakahoki mai ratou ki te whenua i homai e koe ki o ratou matua.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Ki te tutakina te rangi, a kahore he ua, mo ratou i hara ki a koe; a ka inoi ratou ki te ritenga o tenei wahi, ka whakaae ki tou ingoa, ka tahuri i to ratou hara, no ratou ka whakawhiua e koe:
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
Tena ra, mau e whakarongo i te rangi, e muru te hara o au pononga, o tau iwi, o Iharaira, ina whakaako koe i a ratou ki te ara pai e haere ai ratou; a homai e koe he ua ki tou whenua, i homai nei e koe hei kainga pumau mo tau iwi.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
Ki te mea he matekai to te whenua, he mate uruta, ki te mea he ngingio, he koriri, he mawhitiwhiti ranei, he moka ranei; ki te whakapaea ranei ratou e o ratou hoariri ki te whenua o o ratou pa; ki te pa mai tetahi whiu, tetahi mate turoro ranei;
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
Ki te mea he inoi, he karanga ranei na tetahi tangata, na tau iwi katoa ranei, na Iharaira, ina mohio ratou ki te mate o tona ngakau, o tona ngakau, a ka wherahia ona ringa ki te ritenga mai o tenei whare:
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
Tena ra, mau e whakarongo mai i te rangi, i tou wahi e noho na koe, e muru te he, e mahi, e homai ki nga tangata nga mea e rite ana ki nga huarahi katoa o tenei, o tenei, e mohio ana hoki koe ki tona ngakau; ko koe anake nei hoki te mohio ana ki nga ngakau o nga tama katoa a te tangata;
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
Kia wehi ai ratou i a koe i nga ra katoa e ora ai ratou i runga i te mata o te whenua i homai nei e koe ki o matou matua.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Na, ko te tangata iwi ke, ehara nei i tau iwi, i a Iharaira, a ka tae mai i te whenua mamao, he whakaaro ki tou ingoa;
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
E rongo hoki ratou ki tou ingoa nui, ki tou ringa kaha, ki tou takakau kua oti te whakamaro; a ka haere, ka inoi ki te ritenga mai o tenei whare;
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
Mau e whakarongo mai i te rangi, i tou wahi e noho na koe, e mea nga mea katoa i karanga ai te tangata iwi ke ki a koe: kia mohio ai nga iwi katoa o te whenua ki tou ingoa, kia wehi ai i a koe, kia pera ai me tau iwi, me Iharaira; kia mohio ai h oki kua oti tou ingoa te karanga ki runga ki tenei whare ka oti nei i ahau te hanga.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
Ki te haere tau iwi ki te whawhai ki tona hoariri, ki nga wahi e tonoa ai ratou e koe, a ka inoi ki a Ihowa ki te ritenga mai o te pa kua whiriwhiria nei e koe, o te whare kua hanga nei e ahau mo tou ingoa:
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
Tena ra, mau e whakarongo mai i te rangi ki ta ratou inoi, ki ta ratou karanga, e whakatika hoki ta ratou.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
Ki te hara ratou ki a koe, kahore hoki he tangata i hapa i te hara, a ka riri koe ki a ratou, ka tuku i a ratou ki te hoa whawhai, a ka whakaraua atu e ratou hei whakarau ki te whenua o te hoa whawhai, ki te wahi tata, ki te wahi mamao ranei;
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
Na ki te hoki ake to ratou mahara i te whenua i whakaraua atu ai ratou, a ka ripeneta ratou, ka inoi ki a koe i te whenua o o ratou kaiherehere, ka mea, Kua hara matou, kua parori ke ta matou mahi, kua mahi matou i te kino;
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
A ka tahuri o ratou ngakau katoa, o ratou wairua katoa, ki a koe i te whenua o o ratou hoariri i whakaraua atu ai ratou, a ka inoi ratou ki a koe ki te ritenga mai o to ratou nei whenua i homai e koe ki o ratou matua, ki te pa i whiriwhiria nei e koe, ki tenei whare kua hanga nei e ahau mo tou ingoa:
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
Tena ra, mau e whakarongo mai i te rangi, i tou wahi e noho na koe, ki ta ratou inoi, ki ta ratou karanga, mau hoki e whakatika ta ratou,
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
Mau ano e muru te he o tau iwi i hara nei ki a koe, me a ratou mahi tutu katoa i tutu ai ki a koe; meinga ano kia arohaina ratou e o ratou kaiherehere, kia tohungia hoki e ratou:
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
Ko tau iwi hoki ratou, ko tou wahi tupu i whakaputaina mai nei e koe i Ihipa, i roto i te oumu rino;
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
Kia titiro mai ai ano ou kanohi ki te karanga a tau pononga, ki te karanga ano a tau iwi, a Iharaira, ka whakarongo ki a ratou i a ratou karangatanga katoa ki a koe.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Nau hoki ratou i wehe hei taonga tupu mou i roto i nga iwi katoa o te whenua, he kupu hoki nau, na tau pononga, na Mohi i whakapuaki, i tau whakaputanga mai i o matou matua i Ihipa, e te Ariki, e Ihowa.
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
A, i te mutunga o ta Horomona inoi i tenei inoi katoa, i tenei karanga ki a Ihowa, ka whakatika ake ia i mua i te aata a Ihowa i a ia i tuturi ra i runga i ona turi, me te tuwhera tonu ano ona ringa whaka te rangi.
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
A ka tu ia, ka manaaki i te huihui katoa o Iharaira, he nui te reo, a ka mea,
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
Kia whakapaingia a Ihowa nana nei i homai te okiokinga ki tana iwi, ki a Iharaira, rite tonu ki nga mea katoa i korerotia e ia: hore rawa tetahi kupu i taka o ana mea pai katoa i korerotia e ia, ara e tana pononga, e Mohi.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Hei hoa mo tatou a Ihowa, to tatou Atua, kia pera ano me ia i o tatau matua; kaua ia e whakarere i a tatou, kaua hoki e mawehe atu i a tatou:
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
Mana e whakaanga o tatou ngakau ki a ia, kia haere i ana ara katoa, kia pupuri i ana whakahau, i ana tikanga, i ana whakaritenga, i whakahaua e ia ki o tatou matua.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
Na kia tata ki a Ihowa, ki to tatou Atua, i te ao, i te po, enei kupu aku i karanga nei ahau ki a Ihowa, kia whakatikaia ai e ia ta tana pononga, ta tana iwi hoki, ta Iharaira e tohe ai, i nga meatanga o tenei ra, o tenei ra:
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
Kia mohio ai nga iwi katoa o te whenua ki a Ihowa, ko ia te Atua; kahore ke atu.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Na kia tapatahi o koutou ngakau ki a Ihowa ki to tatou Atua, kia haere i runga i ana tikanga, kia puritia ana whakahau, kia rite ki to tenei ra.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Na patua iho e te kingi ratou tahi ko Iharaira katoa he patunga tapu ki te aroaro o Ihowa.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
I patua hoki e Horomona he patunga mo te pai, he mea patu nana ma Ihowa, e rua tekau ma rua mano nga kau, kotahi rau e rua tekau mano nga hipi. Na kua taia te kawa o te whare o Ihowa e te kingi ratou ko nga tama katoa a Iharaira.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
I whakatapua ano e te kingi i taua ra a waenganui o te marae i mua i te whare o Ihowa; i tukua hoki e ia ki reira nga tahunga tinana, me nga whakahere totokore, me te ngako o nga whakahere mo te pai: he iti hoki no te aata parahi i te aroaro o I howa hei meatanga mo nga tahunga tinana, mo nga whakahere totokore, mo nga ngako o nga whakahere mo te pai.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
I mahia ano he hakari i taua wa e Horomona ratou ko Iharaira katoa ki te aroaro o Ihowa, o to tatou Atua, he huihuinga nui, no te haerenga atu ki Hamata tae noa ki te awa o Ihipa, e whitu nga ra, e whitu atu ano nga ra, kotahi tekau ma wha aua r a.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
I te waru o nga ra ka tukua e ia te iwi kia haere, na ka manaaki ratou i te kingi a haere koa ana ki o ratou teneti, pai tonu hoki te ngakau i nga mea pai katoa i meinga e Ihowa ki a Rawiri, ki tana pononga, ratou ko tana iwi, ko Iharaira.