< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Ningĩ Mũthamaki Solomoni agĩĩta athuuri a Isiraeli, na atongoria othe a mĩhĩrĩga, na anene a nyũmba cia andũ a Isiraeli moke kũrĩ we Jerusalemu, nĩguo maambatie ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova kuuma Zayuni, Itũũra rĩrĩa inene rĩa Daudi.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
Nao andũ othe a Isiraeli magĩũka hamwe kũrĩ Mũthamaki Solomoni hĩndĩ ya gĩathĩ kĩa mweri wa Ethanimu, nĩguo mweri wa mũgwanja.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
Rĩrĩa athuuri othe a Isiraeli maakinyire-rĩ, athĩnjĩri-Ngai makĩoya ithandũkũ rĩu,
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
nao makĩambatia ithandũkũ rĩa Jehova hamwe na Hema-ya-Gũtũnganwo, na indo ciothe iria nyamũre ciarĩ thĩinĩ wayo. Nao athĩnjĩri-Ngai na Alawii magĩciambatia,
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
nake Mũthamaki Solomoni na kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli kĩrĩa gĩacemanĩtie harĩ we kĩrĩ mbere ya ithandũkũ rĩu, gĩkĩruta igongona rĩa ngʼondu nyingĩ na ngʼombe nyingĩ mũno, ũũ atĩ itingĩandĩkirwo mũigana wacio kana itarĩke.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Nao athĩnjĩri-Ngai magĩcooka makĩrehe ithandũkũ rĩu rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova handũ harĩo thĩinĩ wa hekarũ, Handũ-harĩa-Hatheru-Mũno, makĩrĩiga rungu rwa mathagu ma makerubi.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Makerubi macio maatambũrũkĩtie mathagu mamo igũrũ rĩa harĩa haigĩtwo ithandũkũ rĩu, na makahumbĩra ithandũkũ, o na mĩtĩ yarĩo ya kũrĩkuua.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
Mĩtĩ ĩyo yarĩ mĩraihu mũno, ũndũ mĩthia yayo yoonagwo nĩ mũndũ arĩ mbere ya Handũ-harĩa-Hatheru, no ndĩonekaga nĩ mũndũ arĩ nja ya Handũ-harĩa-Hatheru; na ĩrĩ o ho nginya ũmũthĩ.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Thĩinĩ wa ithandũkũ rĩu gũtiarĩ na kĩndũ kĩngĩ tiga o ihengere iria igĩrĩ cia mahiga iria Musa aigĩte ho rĩrĩa aarĩ Horebu, kũrĩa Jehova aarĩkanĩire kĩrĩkanĩro na andũ a Isiraeli maarĩkia kuuma bũrũri wa Misiri.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
Rĩrĩa athĩnjĩri-Ngai meeherire makiuma Handũ-harĩa-Hatheru, itu rĩkĩiyũra hekarũ ya Jehova.
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
Nao athĩnjĩri-Ngai matingĩahotire kũruta wĩra wao nĩ ũndũ wa itu rĩu, nĩgũkorwo riiri wa Jehova nĩwaiyũrĩte hekarũ yake.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Ningĩ Solomoni akiuga atĩrĩ, “Jehova oigĩte atĩ nĩarĩikaraga thĩinĩ wa itu rĩrĩa itumanu;
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
no rĩrĩ, ti-itherũ nĩngwakĩire hekarũ kĩĩrorerwa, handũ haku ha gũtũũra nginya tene.”
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
O hĩndĩ ĩyo kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli kĩrũgamĩte o hau, mũthamaki agĩkĩhũgũkĩra, agĩkĩrathima.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Ningĩ akiuga atĩrĩ: “Jehova arogoocwo, o we Ngai wa Isiraeli, ũrĩa ũhingĩtie na guoko gwake mwene ũrĩa eerĩire baba, Daudi, na kanua gake mwene. Nĩgũkorwo oigire atĩrĩ,
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
‘Kuuma mũthenya ũrĩa ndaarutire andũ akwa a Isiraeli kuuma Misiri, ndirĩ ndathuura itũũra inene thĩinĩ wa mũhĩrĩga o na ũmwe wa Isiraeli, atĩ nĩguo njakĩrwo hekarũ ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩakwa kuo, no nĩndathuurire Daudi athamakĩre andũ akwa Isiraeli.’
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
“Baba Daudi nĩatuĩte na ngoro yake gwaka hekarũ ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩa Jehova, o we Ngai wa Isiraeli.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
No Jehova eerire baba, Daudi, atĩrĩ, ‘Tondũ nĩwatuĩte na ngoro yaku kũnjakĩra hekarũ ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩakwa-rĩ, nĩ wekire wega nĩ gwĩciiria ũguo ngoro-inĩ yaku.
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
No rĩrĩ, wee tiwe ũgwaka hekarũ ĩyo, no nĩ mũrũguo, ũrĩa uumĩte mũthiimo-inĩ waku na thakame-inĩ yaku, ũcio nĩwe ũgaaka hekarũ ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩakwa.’
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
“Jehova nĩatũũrĩtie kĩrĩkanĩro kĩu, na rĩu nĩnjookete ithenya rĩa baba Daudi, na ngaikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene gĩa Isiraeli, o ta ũrĩa Jehova eeranĩire, na nĩnjakĩte hekarũ ĩrĩa ĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai wa Isiraeli.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Hau nĩho thondekete handũ ha kũiga ithandũkũ rĩrĩa rĩ na kĩrĩkanĩro kĩrĩa Jehova aarĩkanĩire na maithe maitũ, rĩrĩa aamarutire bũrũri wa Misiri.”
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Hĩndĩ ĩyo Solomoni akĩrũgama mbere ya kĩgongona kĩa Jehova, o hau mbere ya kĩũngano gĩothe kĩa Isiraeli, agĩtambũrũkia moko make na igũrũ,
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
akiuga atĩrĩ: “Wee Jehova, Ngai wa Isiraeli, gũtirĩ Ngai ũngĩ ũhaana tawe kũu igũrũ kana gũkũ thĩ, o wee ũhingagia kĩrĩkanĩro kĩa wendo harĩ ndungata ciaku iria irũmagĩrĩra njĩra yaku na ngoro ciacio ciothe.
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
Wee nĩũhingĩirie baba, Daudi ndungata yaku kĩrĩkanĩro gĩaku; ũndũ ũrĩa weranĩire na kanua gaku nĩũhingĩtie na guoko gwaku, o ta ũrĩa kũhaana ũmũthĩ.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
“Na rĩrĩ, Jehova, Ngai wa Isiraeli, hingĩria baba, Daudi ndungata yaku ciĩranĩro iria wamwĩrĩire rĩrĩa woigire atĩrĩ, ‘Ndũkaaga mũndũ wa gũikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene kĩa Isiraeli arĩ mbere yakwa, angĩkorwo ariũ aku nĩmarĩthiiaga na mĩthiĩre yagĩrĩire mbere yakwa, o ta ũrĩa wee ũtũire ũthiiaga mbere yakwa.’
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Na rĩrĩ, Wee Ngai wa Isiraeli, reke kiugo gĩaku kĩrĩa werĩire baba, Daudi ndungata yaku, kĩhinge.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
“No kũhoteke Ngai atũũre gũkũ thĩ? Igũrũ, o na kũrĩa igũrũ mũno-rĩ, wee ndũngĩiganĩra kuo. Hekarũ ĩno njakĩte-rĩ, githĩ ndĩkĩrĩ nini makĩria!
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
No o na kũrĩ ũguo-rĩ, thikĩrĩria ihooya rĩa ndungata yaku, ĩgĩthaithana ĩiguĩrwo tha, Wee Jehova Ngai wakwa. Igua gũkaya na ihooya rĩrĩa ndungata yaku ĩrakũhooya ĩrĩ mbere yaku ũmũthĩ.
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
Maitho maku maroikara marorete hekarũ ĩno ũtukũ na mũthenya, o handũ haha wee woigire atĩrĩ, ‘Rĩĩtwa rĩakwa rĩrĩkoragwo ho,’ nĩgeetha ũiguage ihooya rĩrĩa ndungata yaku ĩrĩhooyaga ĩrorete handũ haha.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Igua gũthaithana kwa ndungata yaku na kwa andũ aku a Isiraeli rĩrĩa mekũhooya marorete handũ haha. Ũigue ũrĩ kũu igũrũ, o kũu gĩikaro gĩaku, na watũigua ũgatũrekera.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
“Rĩrĩa mũndũ angĩhĩtĩria mũndũ wa itũũra rĩake na gũtuĩke no nginya ehĩte, nake oke ehĩtĩre hau mbere ya kĩgongona gĩaku hekarũ-inĩ ĩno-rĩ,
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
hĩndĩ ĩyo nĩ ũkaigua ũrĩ kũu igũrũ na ũtue itua. Ũtuithanie ndungata ciaku ciira, ũrĩa mũhĩtia atuĩrwo ciira na acookererwo nĩ mahĩtia make marĩa ekĩte. Nake ũrĩa ũtehĩtie ũmũtue ndehĩtie, na nĩ ũndũ ũcio wonanie atĩ ti mwĩhia.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
“Rĩrĩa andũ aku a Isiraeli mahootwo nĩ thũ nĩ ũndũ nĩmakũhĩtĩirie, nao magũcookerere na moimbũre rĩĩtwa rĩaku, na mahooe magĩgũthaithaga marĩ hekarũ-inĩ ĩno-rĩ,
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
hĩndĩ ĩyo nĩũkamaigua ũrĩ kũu igũrũ, na ũrekere andũ aku a Isiraeli mehia mao na ũmacookie bũrũri ũrĩa waheire maithe mao.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
“Rĩrĩa igũrũ rĩkaahingwo na mbura yage kuura tondũ wa ũrĩa andũ aku makũhĩtĩirie-rĩ, mangĩkaahooya marorete handũ haha na moimbũre rĩĩtwa rĩaku, na magarũrũke matigane na mehia mao, tondũ nĩũmanyamarĩtie-rĩ,
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
hĩndĩ ĩyo ũkaamaigua ũrĩ o kũu igũrũ, na ũrekere ndungata ciaku, andũ aku a Isiraeli, mehia mao. Marute mũtũũrĩre ũrĩa mwagĩrĩru, na ũmoirĩrie mbura bũrũri-inĩ ũcio waheire andũ aku ũtuĩke igai rĩao.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
“Kũngĩkaagĩa ngʼaragu kana mũthiro bũrũri-inĩ, kana mĩgũnda ĩhĩe nĩ mbaa kana mbuu, kana gũũke ngigĩ kana ngũnga, kana thũ imarigiicĩrie itũũra-inĩ rĩmwe rĩao, na mwanangĩko o na ũrĩkũ kana mũrimũ ũngĩgooka-rĩ,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
na rĩrĩa mũndũ o na ũrĩkũ wa andũ aku a Isiraeli angĩkaahooya kana athaithane, o mũndũ aamenya mĩnyamaro ĩrĩa arĩ nayo ngoro-inĩ yake, na atambũrũkie moko make amerekeirie hekarũ-inĩ ĩno-rĩ,
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
hĩndĩ ĩyo ũkaigua ũrĩ kũu igũrũ gĩikaro-inĩ gĩaku, ũmarekere, na ũtuĩre o mũndũ itua kũringana na ũrĩa wothe ekĩte, tondũ we nĩũĩ ngoro yake, (nĩgũkorwo nowe wiki ũũĩ ngoro cia andũ othe),
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
nĩgeetha matũũre magwĩtigĩrĩte matukũ mothe marĩa megũtũũra bũrũri ũrĩa waheire maithe maitũ.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
“Ha ũhoro wa mũndũ wa kũngĩ ũrĩa ũtarĩ wa andũ aku a Isiraeli, no nĩoimĩte bũrũri wa kũraya nĩ ũndũ wa Rĩĩtwa rĩaku,
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
tondũ andũ nĩmakaigua ngumo ya Rĩĩtwa rĩaku inene, na ũhoro wa ciĩko cia guoko gwaku kũrĩ hinya gũtambũrũkĩtio, rĩrĩa agooka ahooe erekeire hekarũ ĩno,
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
hĩndĩ ĩyo nĩũkamaigua ũrĩ o kũu igũrũ, gĩikaro-inĩ gĩaku, na mũndũ ũcio wa kũngĩ ũkamũhingĩria ũrĩa wothe agakũhooya, nĩgeetha andũ othe a thĩ mamenye rĩĩtwa rĩaku na magwĩtigĩre o ta ũrĩa andũ aku a Isiraeli magwĩtigĩrĩte, na mamenye atĩ nyũmba ĩno njakĩte ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩaku.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
“Rĩrĩa andũ aku maathiĩ mbaara-inĩ kũrũa na thũ ciao, o kũrĩa ũngĩmatũma, nao mahooe Jehova merekeire itũũra rĩĩrĩ inene ũthuurĩte na hekarũ ĩno njakĩte ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩaku,
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
hĩndĩ ĩyo ũkaigua mahooya na gũthaithana kwao ũrĩ kũu igũrũ na ũmatirĩrĩre ũhoro-inĩ ũcio wao.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
“Rĩrĩa makwĩhĩria, nĩgũkorwo gũtirĩ mũndũ ũtehagia, nawe ũmarakarĩre ũmaneane kũrĩ thũ, nacio imatahe imatware bũrũri wacio, ũrĩ kũraya kana ũrĩ gũkuhĩ;
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
nao mangĩĩcookera ngoro-inĩ ciao marĩ o kũu bũrũri ũrĩa maatahĩirwo, na merire, na magũthaithe marĩ o kũu bũrũri wa acio mamatooretie, na moige atĩrĩ, ‘Nĩtwĩhĩtie, na nĩtwĩkĩte mahĩtia, na tũgeka maũndũ ma waganu’;
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
na mangĩgagũcookerera na ngoro ciao ciothe, na mĩoyo yao, marĩ bũrũri wa thũ ciao iria ciamatahire, nao mahooe merekeire bũrũri ũrĩa waheire maithe mao, na merekeire itũũra rĩrĩa inene rĩrĩa ũthuurĩte na hekarũ ĩno njakĩte ĩĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩaku-rĩ;
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
hĩndĩ ĩyo ũrĩ o kũu igũrũ, gĩikaro-inĩ gĩaku, ũkaigua ihooya rĩao na mathaithana mao, na ũmatirĩrĩre ũhoro-inĩ ũcio wao.
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
Na ũkarekera andũ aku, o acio makwĩhĩtie; ũmarekere mahĩtia marĩa mothe magwĩkĩte, na ũtũme acio mamatooretie mamaiguĩre tha;
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
tondũ nĩ andũ aku na igai rĩaku, o andũ arĩa warutire bũrũri wa Misiri, ũkĩmaruta kuuma mwaki-inĩ ũcio mũhiũ wa gũtwekia kĩgera.
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
“Ũrohingũra maitho maku na ũigue mathaithana ma ndungata yaku na ma andũ aku a Isiraeli, ningĩ wĩtĩkĩre kũmathikagĩrĩria rĩrĩa rĩothe maagũkaĩra.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Nĩgũkorwo nĩwe wamathuurire kuuma thĩinĩ wa ndũrĩrĩ ciothe cia thĩ matuĩke igai rĩaku kĩũmbe, o ta ũrĩa woimbũrire na kanua ka ndungata yaku Musa, hĩndĩ ĩrĩa wee, Mwathani Jehova, warutire maithe maitũ kuuma bũrũri wa Misiri.”
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
Rĩrĩa Solomoni aarĩkirie mahooya macio mothe na gũthaitha Jehova-rĩ, agĩũkĩra, akĩehera mbere ya kĩgongona kĩa Jehova, harĩa aaturĩtie ndu aambararĩtie moko make na igũrũ.
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
Akĩrũgama na akĩrathima kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli na mũgambo mũnene, akiuga atĩrĩ:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
“Jehova arogoocwo, ũrĩa ũheete andũ ake a Isiraeli ũhurũko o ta ũrĩa eranĩire. Gũtirĩ kiugo o na kĩmwe gĩa ciĩranĩro ciothe iria njega iria eeranĩire na kanua ka ndungata yake Musa gĩtahingĩte.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Jehova Ngai witũ aroikara hamwe na ithuĩ o ta ũrĩa aarĩ hamwe na maithe maitũ; aroaga gũtũtiganĩria o na kana gũtũtirika.
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
Arotũma ngoro ciitũ imũcookerere, tũthiiage na njĩra ciake ciothe, na tũmenyagĩrĩre maathani make, na kĩrĩra kĩa watho wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho make marĩa aaheire maithe maitũ.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
Na rĩrĩ, ciugo ici ciakwa, iria hooete ndĩ mbere ya Jehova, irokuhĩrĩria Jehova Ngai witũ mũthenya na ũtukũ, nĩguo atiiragĩrĩre maũndũ ma ndungata yake na andũ ake a Isiraeli, kũringana na mabataro ma o mũthenya,
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
nĩgeetha andũ othe a thĩ mamenye atĩ Jehova nĩwe Ngai, na gũtirĩ ũngĩ take.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
No ngoro cianyu no nginya ciĩheane biũ kũrĩ Jehova Ngai witũ, mũtũũrage kũringana na kĩrĩra kĩa watho wake wa kũrũmĩrĩrwo, na gwathĩkĩra maathani make, ta ũrĩa kũrĩ rĩu.”
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Hĩndĩ ĩyo mũthamaki na andũ othe a Isiraeli makĩruta magongona hau mbere ya Jehova.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
Solomoni nĩarutĩire Jehova igongona rĩa ũiguano ta ũũ: ngʼombe ngiri mĩrongo ĩĩrĩ na igĩrĩ, na ngʼondu na mbũri ngiri igana rĩa mĩrongo ĩĩrĩ. Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki na andũ a Isiraeli othe makĩamũra hekarũ ya Jehova.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
Mũthenya o ro ũcio mũthamaki nĩamũrire gĩcigo gĩa gatagatĩ kĩa nja ĩrĩa ĩrĩ mbere ya hekarũ ya Jehova, na akĩrutĩra igongona rĩa njino ho, na rĩa mũtu na rĩa maguta ma igongona rĩa ũiguano, tondũ kĩgongona gĩa gĩcango kĩrĩa kĩarĩ mbere ya Jehova gĩtingĩaiganĩire magongona ma njino, na magongona ma mũtu na maguta ma magongona ma ũiguano.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Solomoni agĩkorwo na gĩathĩ hĩndĩ ĩyo arĩ hamwe na andũ a Isiraeli, maarĩ kĩũngano kĩnene, andũ kuuma Lebo-Hamathu nginya Karũũĩ ka Misiri. Magĩkũngũĩra gĩathĩ kĩu mbere ya Jehova Ngai witũ mĩthenya mũgwanja, na mĩthenya ĩngĩ mũgwanja, yothe yarĩ mĩthenya ikũmi na ĩna.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
Mũthenya ũrĩa warũmĩrĩire akĩĩra andũ acio mainũke. Makĩrathima mũthamaki magĩcooka makĩinũka makenete na maiguĩte wega ngoro, nĩ ũndũ wa maũndũ mothe mega marĩa Jehova ekĩte nĩ ũndũ wa ndungata yake Daudi na nĩ ũndũ wa andũ ake a Isiraeli.

< 1 Kings 8 >