< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Lorsqu'au bout de vingt ans, Salomon eut achevé de bâtir le temple du Seigneur et son palais, il rassembla dans Sion tous les anciens d'Israël pour enlever de la ville de David (la même que Sion) l'arche de l'alliance du Seigneur,
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
Au mois d'Athanin;
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
Et les prêtres transportèrent l'arche,
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
Ainsi que le tabernacle du témoignage, et les objets consacrés dans le tabernacle du témoignage.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Et le roi et tout Israël, devant l'arche, sacrifiaient des brebis et des bœufs en quantité innombrable.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Les prêtres introduisirent l'arche à sa place, dans l'oracle du temple, dans le Saint des saints, sous les ailes des chérubins.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Car les chérubins déployaient leurs ailes au-dessus de l'emplacement de l'arche, et ils en couvraient l'arche et ses leviers.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
Ces leviers étaient dressés, et leurs extrémités se voyaient dès l'entrée du Saint des saints devant l'oracle, mais on ne pouvait les voir du dehors.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Il n'y avait rien dans l'arche sinon les deux tables de pierre, les tables de l'alliance que Moïse y avait déposées sur le mont Horeb, et sur lesquelles le Seigneur avait écrit son alliance avec les fils d'Israël lorsqu'ils revenaient de la terre d'Égypte.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
Or, quand les prêtres sortirent du Saint des saints il advint qu'une nuée remplit le temple.
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
Et les prêtres ne purent y demeurer, ni faire le service divin, à cause de la nuée; car la gloire du Seigneur avait rempli le temple.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Et les prêtres ne purent y demeurer, ni faire le service divin, à cause de la nuée; car la gloire du Seigneur avait rempli le temple.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Et les prêtres ne purent y demeurer, ni faire le service divin, à cause de la nuée; car la gloire du Seigneur avait rempli le temple.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
Alors, le roi se retourna vers le peuple, et il bénit tout Israël, et toute l'Église d'Israël était restée debout.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Et il dit: Béni soit aujourd'hui le Seigneur Dieu d'Israël, qui, de sa bouche, a parlé concernant David mon père, et qui de ses mains a rempli ses promesses, disant:
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Depuis le jour où j'ai tiré de l'Égypte mon peuple Israël, je n'ai choisi en Israël ni ville, ni tribu, pour qu'on bâtit un temple où résidât mon Nom; puis, j'ai choisi Jérusalem pour que mon nom y réside, et j'ai choisi David pour qu'il soit sur mon peuple Israël.
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Or, mon père avait en son cœur la pensée de bâtir un temple au nom du Seigneur Dieu d'Israël.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
Et le Seigneur dit à David, mon père: En récompense de ce que la pensée t'est venue au cœur de bâtir un temple à mon nom, tu as fait de belles actions, parce que cette pensée était en ton cœur.
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Néanmoins, tu ne bâtiras point ce temple, mais ton fils, qui sortira de toi, le bâtira à mon nom.
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Le Seigneur a relevé la parole qu'il avait dite, j'ai été suscité à la place de David mon père; et je me suis assis sur le trône d'Israël, comme l'avait dit le Seigneur; et j'ai bâti un temple au nom du Seigneur Dieu d'Israël.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
J'y ai préparé un emplacement pour l'arche qui renferme l'alliance du Seigneur avec nos pères, tandis qu'il les ramenait de la terre d'Égypte.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Ensuite, Salomon se tint devant l'autel du Seigneur et devant toute l'Église d'Israël; il étendit les deux mains vers le ciel,
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
Et il dit: Seigneur Dieu d'Israël, il n'est point au ciel ni sur la terre de Dieu tel que vous, gardant alliance et miséricorde pour le serviteur qui marche de tout son cœur devant vous.
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
Vous avez gardé cette alliance et cette miséricorde, pour votre serviteur David; car vous avez parlé de votre bouche, et de vos mains vous avez rempli vos promesses; comme il se voit aujourd'hui.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Maintenant, Seigneur Dieu d'Israël, gardez pour votre serviteur David, mon père, cette parole que vous lui avez dite: Il ne manquera jamais d'hommes de ton sang pour être assis sur le trône d'Israël devant ma face, pourvu que les enfants observent leurs voies, et qu'ils marchent à mes yeux comme toi-même as marché.
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Maintenant, Seigneur Dieu d'Israël, que votre promesse à David mon père, votre serviteur, soit confirmée.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
Est-il donc croyable que Dieu réside sur la terre parmi les hommes? Si le ciel et le ciel des cieux ne peuvent vous contenir, combien moins encore ce temple que j'ai bâti à votre nom?
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
O Seigneur Dieu d'Israël, ayez égard à ma demande; écoutez aujourd'hui la prière que vous fait votre serviteur.
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
Que vos yeux soient ouverts nuit et jour sur ce temple, sur ce lieu dont vous avez dit: C'est là que sera mon nom; et écoutez-y la prière que vous y fait nuit et jour votre serviteur.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Oui, vous écouterez la prière de votre serviteur et de votre peuple Israël, toutes les fois qu'ils prieront en ce lieu; vous les entendrez du lieu que vous habitez au ciel; et vous agirez, et vous serez indulgent.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
Quelque péché qu'un homme ait commis contre son prochain, même quand il aura songé à le maudire, s'il vient, s'il se confesse, dans le temple devant votre autel,
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
Du haut du ciel vous l'entendrez et vous agirez, et vous jugerez le peuple d'Israël, de telle sorte que l'inique sera considéré comme inique; que vous ferez retomber sur sa tête son égarement dans ses voies, que le juste sera justifié, et que vous le rétribuerez selon son équité.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
Lorsque votre peuple Israël tombera devant ses ennemis parce qu'il aura péché contre vous, ils se convertiront, ils rendront gloire au nom du Seigneur; ils prieront, et ils supplieront en votre temple:
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
Alors, du haut du ciel vous les écouterez, vous leur remettrez leurs péchés, et vous les ramènerez dans la terre que vous avez donnée à leurs pères.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Lorsque vous aurez fermé le ciel, et qu'il n'y aura plus de pluie parce que les fils d'Israël auront péché contre vous, ils prieront en ce lieu; ils rendront gloire au nom du Seigneur, et ils détesteront leurs péchés, après que vous les aurez humiliés,
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
Et du haut du ciel vous les écouterez, et vous remettrez les péchés de vos serviteurs, de votre peuple; vous leur montrerez la bonne voie qu'ils doivent suivre, et vous accorderez de la pluie à la terre que vous avez donnée pour héritage à votre peuple.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
Lorsqu'il y aura famine, lorsqu'il y aura mortalité par suite de la chaleur brûlante ou du ravage des sauterelles, lorsqu'il y aura rouille des blés, lorsqu'un ennemi opprimera le peuple en l'une de ses villes, lorsqu'il y aura partout accident et peine,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
Toute prière, toute supplication que l'homme vous fera dans le temple les mains étendues, après avoir reconnu la plaie de son cœur,
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
Vous l'écouterez du haut du ciel, du lieu où est votre demeure; vous serez miséricordieux, vous agirez et vous rétribuerez l'homme selon sa voie, selon ce que vous aurez vu dans son cœur, car vous seul connaissez le cœur de tous les fils des hommes.
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
Ainsi auront-ils crainte de vous tout le temps qu'ils vivront en la terre que vous avez donnée à nos pères.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Lorsque l'étranger qui n'est point de votre peuple,
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
Entrera aussi et priera dans ce lieu,
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
Du haut du ciel, du lieu où est votre demeure, vous accomplirez tout ce que vous aura demandé l'étranger, afin que tous les peuples connaissent votre nom, qu'ils aient crainte de vous comme le peuple d'Israël, et qu'ils sachent que votre nom est invoqué dans ce temple que j'ai bâti.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
Si votre peuple va en guerre contre ses ennemis dans une voie où vous lui ferez prendre la fuite, il invoquera le nom du Seigneur en se tournant vers la ville que vous vous êtes choisie, et vers le temple que j'ai bâti à votre nom,
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
Et, du haut du ciel, vous écouterez sa demande et sa prière, et vous rendrez sur lui votre jugement.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
Ils pècheront contre vous, car il n'est point d'homme qui ne pèche, et vous les emmènerez, vous les livrerez à leurs ennemis, et les captifs seront conduits en une terre voisine ou lointaine.
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
Et, dans la terre où on les aura conduits, ils convertiront leurs cœurs, ils se repentiront dans le lieu de leur exil, et ils vous prieront, disant: Nous avons péché, nous avons été déréglés et iniques.
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
Et ils reviendront à vous de tout leur cœur, de toute leur âme, en la demeure de leurs ennemis où vous les aurez transportés; et ils vous prieront, tournés vers la terre que vous avez donnée à leurs pères, vers la ville que vous vous êtes choisie, et vers ce temple que j'ai bâti au nom du Seigneur.
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
Et du haut du ciel, du lieu où est votre demeure, vous les écouterez,
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
Vous leur remettrez leurs iniquités, leurs péchés contre vous, et toutes leurs prévarications; vous leur accorderez d'exciter la compassion des ennemis qui les retiendront en captivité, et ceux-ci leur feront miséricorde.
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
Car c'est votre peuple, c'est votre héritage, que vous avez tiré de la terre d'Égypte, du milieu d'une fournaise de fer.
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
Que vos yeux, que vos oreilles, restent ouverts à la prière que vous fait votre serviteur, à la prière que vous fait votre peuple Israël; écoutez-les en toutes les choses pour lesquelles ils vous invoqueront.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Car c'est vous qui les avez mis à part, entre tous les autres peuples, pour être votre héritage, comme vous l'aviez promis à Moïse, lorsque vous avez ramené nos pères de la terre d'Égypte, Seigneur, ô Seigneur.
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
Lorsque Salomon eut achevé toute cette prière, cette oraison au Seigneur, il se tint debout après s'être agenouillé devant l'autel du Seigneur; puis, les mains étendues vers le ciel,
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
Debout, il bénit à haute voix toute l'Église d'Israël, et il dit:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
Béni soit aujourd'hui le Seigneur qui a donné la paix à Israël son peuple, selon tout ce qu'il avait dit! Nulle de ses paroles ne s'est trouvée en défaut parmi toutes les bonnes paroles qu'il avait dites par la bouche de Moïse, son serviteur.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Puisse le Seigneur Dieu être avec nous comme il a été avec nos pères, puisse-t-il ne nous jamais abandonner, et ne nous point détourner
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
D'incliner vers lui nos cœurs, de marcher dans toutes ses voies et d'observer tous ses commandements, tous les préceptes qu'il a donnés à nos pères.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
Puissent ces prières que je viens de faire ici devant le Seigneur notre Dieu être près de lui nuit et jour, qu'elles donnent la justice à votre serviteur, et à votre peuple Israël, à jamais.
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
Afin que tous les peuples de la terre sachent que le Seigneur Dieu est le seul Dieu, et qu'il n'y a point d'autre Dieu que lui.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Puissent nos cœurs être parfaits devant le Seigneur notre Dieu, marcher saintement dans ses préceptes, et observer ses commandements, comme aujourd'hui.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Ensuite, le roi et tous les fils d'Israël immolèrent des victimes devant le Seigneur.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
Et le roi Salomon sacrifia des hosties pacifiques et les offrit au Seigneur: vingt-deux mille bœufs, cent vingt mille brebis; puis, le roi et tous les fils d'Israël firent la dédicace du temple du Seigneur.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
Ce jour-là, le roi consacra le milieu du parvis devant la façade du temple; car c'est là qu'il fit les holocaustes et les sacrifices, et qu'il brûla la graisse des hosties pacifiques, parce que l'autel d'airain dressé devant le Seigneur était trop petit pour suffire aux holocaustes et aux hosties pacifiques.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
Et le roi Salomon, ce jour-là, commença la fête, et avec lui tout Isarël, une immense assemblée accourue depuis les gorges d'Emath jusqu'au fleuve d'Égypte, devant le Seigneur notre Dieu, au temple qu'on lui avait bâti; ils mangeaient, buvaient et se réjouissaient devant le Seigneur notre Dieu, pendant sept jours.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
Et le huitième jour, Salomon congédia le peuple, et ils bénirent le roi. Et chacun s'en retourna en sa demeure plein de joie, le cœur pénétré des biens que le Seigneur avait accordés à David son serviteur, ainsi qu'à Israël son peuple.

< 1 Kings 8 >