< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Thanne alle the gretter men in birthe in Israel, with the princes of lynagis, and the duykis of meynees of the sones of Israel, weren gaderid to kyng Salomon, in to Jerusalem, that thei schulden bere the arke of boond of pees of the Lord fro the citee of Dauid, that is, fro Syon.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
And al Israel cam to gidere in the moneth Bethanym, in the solempne dai; thilke is the seuenthe moneth.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
And alle the elde men of Israel camen; and the preestis token the arke,
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
and baren the arke of the Lord, and the tabernacle of boond of pees, and alle vessels of the seyntuarye, that weren in the tabernacle; and the preestis and dekenes baren tho.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Sotheli kyng Salomon, and al the multitude of Israel, that camen togidere to hym, yede with hym bifor the arke; and thei offriden scheep and oxis, with out gessyng and noumbre.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
And prestis brouyten the arke of boond of pees of the Lord in to his place, in to Goddis answerynge place of the temple, in to the hooli of hooli thingis, vndur the wengis of cherubyns.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Forsothe cherubyns spredden forth wengis ouer the place of the arke; and hiliden the arke, and the barris therof aboue.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
And whanne the barris stoden forth, and the hiynesse of tho apperiden with out the seyntuarye, bifor `Goddis answerynge place, tho apperyden no ferther with outforth; whiche barris also weren there `til in to present day.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Forsothe in the arke is noon other thing, no but twei tablis of stoon, whiche tablis Moyses in Oreb hadde put in the ark, whanne the Lord made boond of pees with the sones of Israel, whanne thei yeden out of the loond of Egipt.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
Forsothe it was doon whanne the preestis hadden go out of the seyntuarie, a cloude fillide the hows of the Lord;
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
and the preestis myyten not stonde and mynystre, for the cloude; for whi the glorye of the Lord hadde fillid the hows of the Lord.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Thanne Salomon seide, The Lord seide, that he wolde dwelle in a cloude.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Y bildynge haue bildid an hows in to thi dwelling place, in to thi moost stidefast trone with outen ende.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
And the kyng turnede his face, and blesside al the chirche in Israel; for al the chirche of Israel stood.
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
And Salomon seide, Blessid be the Lord God of Israel, that spak with his mouth to Dauid, my fadir, and performyde in hise hondis, and seide,
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Fro the dai in which Y ledde my puple Israel out of Egipt, Y chees not a citee of alle the lynagis of Israel, that an hows schulde be bildid, and my name schulde be there; but Y chees Dauid, that he schulde be ouer my puple Israel.
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
And Dauid, my fadir, wolde bilde an hows to the name of the Lord God of Israel.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
And the Lord seide to Dauid, my fadir, That thou thouytist in thin herte to bilde an hows to my name, thou didist wel, tretynge this same thing in soule;
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
netheles thou schalt not bilde an hows to me, but thi sone, that schal go out of thi reynes, he schal bilde an hows to my name.
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
The Lord hath confermyd his word, which he spak; and Y stood for Dauid, my fadir, and Y sat on the trone of Israel, as the Lord spak; and Y haue bildid an hows to the name of the Lord God of Israel.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
And Y haue ordeyned there a place of the arke, in which arke the boond of pees of the Lord is, which he smoot with oure fadris, whanne thei yeden out of the lond of Egipt.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Forsothe Salomon stood bifoor the auter of the Lord, in the siyt of the chirch of Israel; and he helde forth hise hondis ayens heuene,
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
and seide, Lord God of Israel, no God in heuene aboue, nether on erthe bynethe, is lijk thee, which kepist couenaunt and mercy to thi seruauntis, that goon bifor thee in al her herte;
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
and thou kepist to Dauid, my fadir, thi seruaunt, tho thingis whiche thou hast spoke to him; bi mouth thou hast spoke, and bi hondis thou hast fillid, as this day preueth.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Now therfor, Lord God of Israel, kepe thou to thi seruaunt Dauid, my fadir, tho thingis whiche thou spakist to hym, and seidist, A man of thee schal not be taken awei bifor me, which man schal sitte on the trone of Israel, so netheles if thi sones kepen thi weye, that thei go bifor me, as thou yedist in my siyt.
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
And now, Lord God of Israel, thi wordis be maad stidfast, whiche thou spakist to thi seruaunt Dauid, my fadir.
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
Therfor whether it is to gesse, that God dwellith verily on erthe; for if heuene, and heuene of heuenes moun not take thee, how myche more this hows, which Y bildid to thee, `mai not take thee.
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
But, my Lord God, biholde thou to the preiere of thi seruaunt, and to the bisechyngis of hym; here thou the `ympne, ether preysing, and preiere, which thi seruaunt preieth bifor thee to day;
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
that thin iyen be openyd on this hows bi niyt and dai, on the hows, of which thou seidist, My name schal be there; that thou here the preier, which thi seruaunt preieth to thee in this place; that thou here the bisechyng of thi seruaunt,
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
and of thi puple Israel, what euer thing he preieth in this place, and here thou in the place of thi dwellyng in heuene; and whanne thou hast herd, thou schalt be mercyful.
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
If a man synneth ayens a man, and hath ony ooth, bi which he is holdun boundun, and cometh for the ooth in to thin hows, bifor thin auter, thou schalt here in heuene,
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
and thou schalt do, and thou schalt deme thi seruauntis; and thou schalt condempne the wickid man, and schalt yelde his weie on his heed, and thou schalt iustifie the iust man, and schalt yelde to hym vp his riytfulnesse.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
If thi puple Israel fleeth hise enemyes, for he schal do synne to thee, and thei doen penaunce, and knoulechen to thi greet name, and comen, and worschipen, and bisechen thee in this hows,
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
here thou in heuene, and foryyue thou the synne of thi puple; and thou schalt lede hem ayen in to the lond, which thou hast youe to the fadris of hem.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
If heuene is closid, and reyneth not for the synnes of hem, and thei preyen in this place, and doen penaunce to thi name, and ben conuertid fro her synnes for her turment,
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
here thou hem in heuene, and foryyue thou the synnes of thi seruauntis, and of thi puple Israel, and schewe thou to hem good weie, bi which thei schulen go, and yyue thou reyn to hem on the lond, which thou hast youe to hem in to possessioun.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
If hungur risith in the lond, ether pestilence is, ether corrupt eyr is, ether rust, ether locuste, ether myldew, and his enemy turmentith hym, and bisegith the yatis, al wounde, al sikenesse, al cursyng,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
and wichyng of yuel, that bifallith to ech man of thi puple Israel, if ony man knowith the wounde of his herte, and holdith forth hise hondis in this hows,
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
thou schalt here in heuene, in the place of thi dwellyng, and thou schalt do mercy, and thou schalt do that thou yyue to ech man vpe alle hise weies, as thou seest his herte; for thou aloone knowist the herte of alle the sones of men,
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
that thei drede thee in alle daies in whiche thei lyuen on the face of the lond, which thou hast youe to oure fadrys.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Ferthermore and whanne an alien, which is not of thi puple Israel, cometh fro a fer lond for thi name; for thi grete name, and thi strong hond,
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
and thin arm `holdun forth schal be herd euery where; therfor whanne he cometh, and preieth in this place,
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
thou schalt here in heuene, in the firmament of thi dwellyng place, and thou schalt do alle thingis, for whiche the alien clepith thee, that alle puplis of londis lerne to drede thi name, as thi puple Israel doith, and preue, that thi name is clepid on this hows, which Y bildide.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
If thi puple goith out to batel ayens hise enemyes, bi the weie whidir euer thou sendist hem, thei schulen preye thee ayens the weie of the citee which thou hast chose, and ayens the hows which Y bildide to thi name,
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
and thou schalt here in heuene the preyeris of hem, and the bisechyngis of hem, and thou schalt make the doom of hem.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
That if thei synnen to thee, for no man is that synneth not, and thou art wrooth, and bitakist hem to her enemyes, and thei ben led prisoneris in to the lond of enemyes,
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
fer ether nyy, and thei doon penaunce in her herte in the place of prisonyng, and ben conuertid, and bisechen in her prisonyng, and seien, We han synned, we han do wickidli, we han do vnfeithfuli;
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
and thei turnen ayen to thee in al her herte and al her soule, in the lond of her enemyes, to which thei ben led prisoneris, and thei preyen thee ayens the weie of her lond which thou hast youe to her fadris, and of the citee which thou hast chose, and of the temple which Y bildide to thi name, thou schalt here in heuene,
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
in the firmament of thi seete, the preiers of hem, and the bisechingis of hem, and thou shalt make the doom of hem;
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
and thou schalt be merciful to thi puple, that synnede to thee, and to alle the wickidnessis, bi whiche thei trespassiden ayens thee; and thou schalt do merci bifor tho men, that hadden hem prisoneris, that tho men do mercy to hem.
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
For it is thi puple, and thin erytage, whiche thou leddist out of the lond of Egipt, fro the myddis of yrone furneis;
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
that thin yyen be opyn to the bisechyng of thi seruaunt, and of thi puple Israel; and thou schalt here hem in alle thingis, for whiche thei clepen thee.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
For thou hast departid hem to thee in to heritage fro alle the puplis of erthe, as thou spakist bi Moyses, thi seruaunt, whanne thou, Lord God, leddist oure fadris out of Egipt.
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
Forsothe it was don, whanne Salomon, preiynge the Lord, hadde fillid al this preier and bisechyng, he roos fro the siyt of the auter of the Lord; for he hadde set fast euer either kne to the erthe, and hadde holde forth the hondis to heuene.
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
Therfor he stood, and blesside al the chirche of Israel, and seide with greet vois,
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
Blessid be the Lord God of Israel, that yaf reste to his puple Israel, bi alle thingis whiche he spak; a word felde not doun, sotheli nether oon, of alle goodis whiche he spak bi Moises, his seruaunt.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Oure Lord God be with vs, as he was with oure fadris, and forsake not vs, nether caste awey;
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
but bowe he oure hertis to hym silf, that we go in alle hise weies, and kepe hise comaundementis, and cerymonyes, and domes, whiche euere he comaundide to oure fadris.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
And these wordis of me, bi whiche Y preiede bifor the Lord, be neiyynge to oure Lord God bi dai and niyt, that he make doom to his seruaunt, and to his puple Israel bi alle daies;
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
and alle the puplis of erthe wite, that the Lord hym silf is God, and noon `is ouer `with out hym.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Also oure herte be perfit with oure Lord God, that we go in hise domes, and kepe hise comaundementis, as and to dai.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Therfor the kyng, and al Israel with hym, offriden sacrifices bifor the Lord.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
And Salomon killide pesible sacrifices, whiche he offride to the Lord; of oxis two and twenti thousynde, and of scheep sixe score thousynde; and the king and the sones of Israel halewiden the temple of the Lord.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
In that dai the kyng halewide the myddil of the greet street, that was bifor the hows of the Lord; for he made there brent sacrifice, and sacrifice, and the innere fatnesse of pesible thingis; for the brasun auter that was bifor the Lord, was to litil, and myyte not take the brent sacrifice, and the sacrifice, and the ynnere fatnesse of pesible thingis.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
Therfor Salomon made in that tyme a solempne feeste, and al Israel with hym, a grete multitude, fro the entryng of Emath `til to the stronde of Egipt, bifor oure Lord God, in seuene daies and seuene daies, that is, fourtene daies.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
And in the eiythe day he delyueryde the puplis, whiche blessiden the kyng, and yeden forth in to her tabernaclis, and weren glade and of ioyful herte on alle the goodis whiche God hadde do to Dauid, his seruaunt, and to Israel, his puple.

< 1 Kings 8 >