< 1 Kings 5 >
1 Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
Et Hiram, roi de Tyr, envoya ses serviteurs, sachant que Salomon avait été oint à la place de David, son père; car Hiram avait aimé David tous les jours de sa vie.
2 Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
Salomon envoya aussi des messagers à Hiram, disant:
3 “Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Tu sais que David, mon père, n'a pu bâtir un temple au nom du Seigneur mon Dieu, à cause des guerres qui ont éclaté tout alentour, jusqu'à ce que le Seigneur eût abattu ses ennemis sous la plante de ses pieds.
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
Maintenant, le Seigneur mon Dieu m'a donné la paix tout alentour; il n'est point de complot contre moi ni de mauvais desseins.
5 Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Et voilà que j'ai résolu de bâtir un temple au nom du Seigneur mon Dieu, comme le Seigneur Dieu l'a dit à David mon père: C'est ton fils, que je mettrai sur le trône à ta place, qui bâtira un temple à mon nom.
6 “Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
Donne donc tes ordres, et que l'on coupe des arbres du Liban; voici mes serviteurs pour aider les tiens, et je te paierai le salaire de tes services comme tu le demanderas; car tu sais que parmi nous personne n'est aussi habile que les Sidoniens à travailler le bois.
7 Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
Or, Hiram fut grandement réjoui d'entendre ces paroles, et il dit: Béni soit aujourd'hui le Seigneur, qui a donné à David un fils aussi sage pour gouverner ce peuple nombreux.
8 Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
Puis, il envoya dire à Salomon: J'ai ouï toutes les choses au sujet desquelles tu as envoyé près de moi; je ferai tout ce que tu veux; cèdres et sapins,
9 Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
Mes serviteurs transporteront tout du Liban à la mer; on en formera des radeaux jusqu'au lieu que tu m'indiqueras; là, je les ferai délier, et tu les enlèveras, et tu feras tout ce que je désire en donnant des vivres à ma maison.
10 Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
Hiram donna donc à Salomon des cèdres, des sapins et tout ce qu'il voulut.
11 Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
Et Salomon donna à Hiram vingt mille mesures de froment pour alimenter sa maison, et vingt mille mesures d'huile battue; voilà ce que Salomon donna par an à Hiram.
12 Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
Or, le Seigneur avait donné à Salomon la sagesse comme il le lui avait dit. Et la paix régnait entre Hiram et Salomon, qui contractèrent entre eux une alliance.
13 Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
Le roi imposa une corvée à tout Israël, et il requit pour ce service trente mille hommes.
14 Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
Il les fit partir pour le Liban, dix mille par dix mille qui se relevaient mois par mois; ils passaient un mois au Liban et deux mois chez eux. Adoniram était à leur tête.
15 Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
Et Salomon employait soixante-dix mille hommes à transporter les matériaux, et quatre-vingt mille à tailler des pierres dans la montagne,
16 àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
Sans compter les conducteurs des travaux; il y en avait trois mille six cents habiles à ces sortes d'œuvres.
17 Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
Et l'on mit trois ans à préparer les pierres et les bois.
18 Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.
Et l'on mit trois ans à préparer les pierres et les bois.