< 1 Kings 5 >

1 Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
Hiram, roi de Tyr, envoya ses serviteurs vers Salomon, car il avait appris qu'on l'avait oint comme roi à la place de son père, et Hiram avait toujours aimé David.
2 Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
Salomon envoya dire à Hiram:
3 “Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
« Tu sais que David, mon père, n'a pu bâtir une maison au nom de l'Éternel, son Dieu, à cause des guerres qui l'ont entouré de toutes parts, jusqu'à ce que l'Éternel ait mis ses ennemis sous la plante de ses pieds.
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
Mais maintenant, l'Éternel, mon Dieu, m'a donné du repos de tous côtés. Il n'y a plus d'ennemi ni d'événement mauvais.
5 Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Voici, j'ai l'intention de bâtir une maison au nom de l'Éternel, mon Dieu, comme l'Éternel l'a dit à David, mon père: « Ton fils, que je mettrai à ta place sur ton trône, bâtira la maison de mon nom ».
6 “Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
Maintenant, ordonne que l'on coupe pour moi des cèdres du Liban. Mes serviteurs seront avec tes serviteurs, et je te donnerai un salaire pour tes serviteurs, selon tout ce que tu diras. Car vous savez qu'il n'y a personne parmi nous qui sache couper le bois comme les Sidoniens. »
7 Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
Lorsque Hiram entendit les paroles de Salomon, il se réjouit grandement et dit: « Béni soit aujourd'hui Yahvé, qui a donné à David un fils sage pour gouverner ce grand peuple. »
8 Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
Hiram envoya dire à Salomon: « J'ai entendu le message que tu m'as envoyé. Je ferai tout ce que tu désires en ce qui concerne le bois de cèdre et le bois de cyprès.
9 Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
Mes serviteurs les feront descendre du Liban jusqu'à la mer. Je les transformerai en radeaux pour qu'ils aillent par mer jusqu'au lieu que tu m'auras indiqué, je les ferai briser là et tu les recevras. Tu accompliras mon désir, en donnant de la nourriture à ma famille. »
10 Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
Hiram donna à Salomon du bois de cèdre et du bois de cyprès, selon tout son désir.
11 Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
Salomon donna à Hiram vingt mille cors de blé pour la nourriture de sa maison, et vingt cors d'huile pure. Salomon donna cela à Hiram année par année.
12 Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
Yahvé donna à Salomon de la sagesse, comme il le lui avait promis. La paix régna entre Hiram et Salomon, et tous deux conclurent un traité ensemble.
13 Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
Le roi Salomon leva une levée sur tout Israël, et la levée fut de trente mille hommes.
14 Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
Il les envoya au Liban, à raison de dix mille par mois par cours: un mois ils étaient au Liban, et deux mois à la maison; et Adoniram était à la tête des hommes soumis au travail forcé.
15 Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
Salomon avait soixante-dix mille personnes qui portaient des fardeaux, et quatre-vingt mille qui taillaient des pierres dans les montagnes,
16 àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
sans compter les chefs de Salomon qui étaient chargés de l'ouvrage: trois mille trois cents qui dirigeaient le peuple qui travaillait à l'ouvrage.
17 Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
Le roi donna des ordres, et l'on tailla de grosses pierres, des pierres de prix, pour poser les fondements de la maison avec des pierres travaillées.
18 Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.
Les bâtisseursde Salomon, les bâtisseurs de Hiram et les Gébalites les taillèrent et préparèrent le bois et les pierres pour construire la maison.

< 1 Kings 5 >