< 1 Kings 4 >

1 Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
Tak więc król Salomon był królem nad całym Izraelem.
2 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
A oto jego dostojnicy: Azariasz, syn Sadoka, kapłan.
3 Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
Elichoref i Achiasz, synowie Sziszy, pisarze; Jehoszafat, syn Achiluda, kronikarz.
4 Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
Benajasz, syn Jehojady, dowódca wojska; Sadok i Abiatar, kapłani.
5 Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
Azariasz, syn Natana, przełożony namiestników, Zabud, syn Natana, naczelny dostojnik, przyjaciel króla.
6 Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
Achiszar, przełożony dworu, i Adoniram, syn Abdy, odpowiedzialny za daninę.
7 Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
Salomon miał też dwunastu namiestników nad całym Izraelem, którzy zaopatrywali króla i cały jego dwór w żywność. Każdy z nich przez jeden miesiąc w roku miał dostarczać żywność.
8 Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
A oto ich imiona: syn Chura – na górze Efraim;
9 Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
Syn Dekara – w Makas, Szaalbim – w Bet-Szemesz i Elon-Bet-Chanan;
10 Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
Syn Cheseda – w Arubot, do niego [należało] Soko i cała ziemia Chefer;
11 Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
Syn Abinadaba – nad całym obszarem Dor; jego żoną była Tafat, córka Salomona.
12 Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
Baana, syn Achiluda, [do którego należały] Tanak i Megiddo oraz całe Bet-Szean, które leży przy Sartan pod Jizreelem, od Bet-Szean aż do Abel-Mechola, aż poza Jokmeam.
13 Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
Syn Geber – w Ramot-Gilead, do niego należały wsie Jaira, syna Manassesa, które [leżą] w Gileadzie. Do niego też należała kraina Argob, która [jest] w Baszanie – sześćdziesiąt wielkich miast mających mury i brązowe rygle.
14 Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
Achinadab, syn Iddo – w Machanaim.
15 Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
Achimaas – w Neftalim; on też pojął za żonę Basemat, córkę Salomona.
16 Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
Baana, syn Chuszaia – w Aszer i Alot.
17 Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
Jehoszafat, syn Paruacha – w Issacharze.
18 Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
Szimei, syn Eli – w Beniaminie.
19 Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
Geber, syn Uriego – w ziemi Gilead, ziemi Sichona, króla Amorytów, i Oga, króla Baszanu. Był on jedynym namiestnikiem tej ziemi.
20 Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
A Juda i Izrael [byli] tak liczni jak piasek nad morzem. Jedli, pili i radowali się.
21 Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
A Salomon panował nad wszystkimi królestwami od rzeki aż do ziemi Filistynów, aż do granicy Egiptu. Płaciły one daninę i służyły Salomonowi po wszystkie dni jego życia.
22 Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
Wyżywienie dla Salomona na jeden dzień wynosiło trzydzieści kor najlepszej mąki i sześćdziesiąt kor zwykłej mąki.
23 Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
Dziesięć tucznych wołów, dwadzieścia wołów z pastwiska, sto owiec, nie licząc jeleni, saren, danieli i tucznego drobiu.
24 Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
Panował bowiem nad całym obszarem z tej strony rzeki, od Tifsach aż do Gazy, nad wszystkimi królami z tej strony rzeki. I miał pokój ze wszystkich stron dokoła.
25 Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
Juda i Izrael mieszkali bezpiecznie, każdy pod swoją winoroślą i pod swoim drzewem figowym, od Dan aż do Beer-Szeby, po wszystkie dni Salomona.
26 Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
Salomon miał też czterdzieści tysięcy koni w stajniach do swoich rydwanów i dwanaście tysięcy jeźdźców.
27 Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
Namiestnicy, każdy w swoim miesiącu, zaopatrywali w żywność króla Salomona i wszystkich, którzy przychodzili do stołu króla Salomona, tak że niczego nie brakowało.
28 Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
Także jęczmień i słomę dla koni i mułów sprowadzali na to miejsce, gdzie [one] przebywały, każdy według swojego obowiązku.
29 Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
A Bóg dał Salomonowi mądrość i bardzo wielkie zrozumienie oraz przestronność serca jak piasek, który jest na brzegu morskim.
30 Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
I mądrość Salomona była większa od mądrości wszystkich narodów wschodnich i od wszelkiej mądrości Egiptu.
31 Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
Był mądrzejszy niż wszyscy ludzie, niż Etan Ezrachita, Heman, Kalkol i Darda, synowie Machola. Był sławny wśród wszystkich okolicznych narodów.
32 Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
Wypowiedział trzy tysiące przysłów, a jego pieśni było tysiąc pięć.
33 Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
Wypowiadał się też o drzewach, [poczynając] od cedru na Libanie aż do hizopu, który wyrasta z muru. Mówił też o zwierzętach, ptakach, płazach i rybach.
34 Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.
Przychodzili więc [ludzie] ze wszystkich narodów, aby słuchać mądrości Salomona, od wszystkich królów ziemi, którzy słyszeli o jego mądrości.

< 1 Kings 4 >