< 1 Kings 4 >
1 Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
Le Roi Salomon donc fut Roi sur tout Israël.
2 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
Et ceux-ci étaient les principaux Seigneurs de sa [cour]; Hazaria fils de Tsadok Sacrificateur;
3 Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
Elihoreph et Ahija enfants de Sisa, Secrétaires; Jéhosaphat fils d'Ahilud, commis sur les Registres;
4 Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
Bénaja fils de Jéhojadah avait la charge de l'armée; et Tsadok et Abiathar étaient les Sacrificateurs;
5 Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
Hazaria fils de Nathan avait la charge de ceux qui étaient commis sur les vivres; et Zabul fils de Nathan était le principal officier; [et] le favori du Roi;
6 Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
et Ahisar était le grand-maître de la maison; et Adoniram fils de Habda, [était] commis sur les tributs.
7 Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
Or Salomon avait douze commissaires sur tout Israël, qui faisaient les provisions du Roi et de sa maison; et chacun avait un mois de l'année pour le pourvoir de vivres.
8 Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
Et ce sont ici leurs noms. Le fils de Hur [était commis] sur la montagne d'Ephraïm;
9 Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
Le fils de Déker sur Makath, sur Sahalbim, sur Beth-sémes, sur Elon de Beth-hanan;
10 Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
Le fils de Hésed sur Arubboth, [et] il avait Soco et tout le pays de Hépher;
11 Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
Le fils d'Abinadab avait toute la contrée de Dor; il eut Taphath fille de Salomon pour femme;
12 Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
Bahana fils d'Ahilud avait Tahanac et Méguiddo, et tout [le pays] de Beth-séan qui est vers le chemin tirant vers Tsarthan au dessous de Jizréhel, depuis Beth-séan jusqu'à Abelmeholah, [et] jusqu'au delà de Jokmeham;
13 Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
Le fils de Guéber [était commis] sur Ramoth de Galaad, [et] il avait les bourgs de Jaïr fils de Manassé en Galaad; il avait aussi toute la contrée d'Argob en Basan, soixante grandes villes murées, et [garnies] de barres d'airain;
14 Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
Ahinadab fils de Hiddo [était commis] sur Mahanajim;
15 Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
Ahimahats, qui avait pour femme Basemath fille de Salomon, [était commis] sur Nephthali;
16 Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
Bahana fils de Cusaï [était commis] sur Aser, et sur Haloth;
17 Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
Jéhosaphat fils de Paruah, sur Issacar;
18 Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
Simhi fils d'Ela, sur Benjamin;
19 Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
Guéber fils d'Uri, sur le pays de Galaad, [qui avait été] du pays de Sihon Roi des Amorrhéens, et de Hog Roi de Basan; et il était seul commis sur ce pays-là.
20 Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
Juda et Israël étaient en grand nombre, comme le sable qui est sur le bord de la mer, tant ils étaient en grand nombre; ils mangeaient et buvaient, et se réjouissaient.
21 Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
Et Salomon dominait sur tous les Royaumes, depuis le fleuve jusqu'au pays des Philistins, et jusqu'à la frontière d'Egypte; et ils lui apportaient des présents, et lui furent [assujettis] tout le temps de sa vie.
22 Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
Or les vivres de Salomon pour chaque jour étaient trente Cores de fine farine, et soixante d'autre farine;
23 Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
Dix bœufs gras, et vingt bœufs des pâturages, et cent moutons; sans les cerfs, les daims, les buffles, et les volailles engraissées.
24 Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
Car il dominait sur toutes les contrées de deçà le fleuve, depuis Tiphsah jusqu'à Gaza, sur tous les Rois qui étaient deçà le fleuve, et il était en paix [avec tous les pays] d'alentour, de tous côtés.
25 Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
Et Juda et Israël habitaient en assurance chacun sous sa vigne et sous son figuier, depuis Dan jusqu'à Beer-sebah, durant tout le temps de Salomon.
26 Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
Salomon avait aussi quarante mille places à tenir des chevaux, et douze mille hommes de cheval.
27 Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
Or ces commis-là pourvoyaient de vivres le Roi Salomon, et tous ceux qui s'approchaient de la table du Roi Salomon, chacun en son mois, et ils ne [les] laissaient manquer de rien.
28 Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
Ils faisaient aussi venir de l'orge et de la paille pour les chevaux et pour les genets, aux lieux où ils étaient, chacun selon la charge qu'il en avait.
29 Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
Et Dieu donna de la sagesse à Salomon; et une fort grande intelligence, et une étendue d'esprit aussi grande que celle du sable qui est sur le bord de la mer.
30 Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
Et la sagesse de Salomon était plus grande que la sagesse de tous les Orientaux, et que toute la sagesse des Egyptiens.
31 Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
Il était même plus sage que quelque homme que ce fût, plus qu'Ethan Ezrahite, qu'Héman, que Calcol, et que Dardah, les fils de Mahol; et sa réputation se répandit dans toutes les nations d'alentour.
32 Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
Il prononça trois mille paraboles, et fit cinq mille cantiques.
33 Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
Il a aussi parlé des arbres, depuis le cèdre qui est au Liban, jusqu'à l'hysope qui sort de la muraille; il a aussi parlé des bêtes, des oiseaux, des reptiles, et des poissons.
34 Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.
Et il venait des gens d'entre tous les peuples pour entendre la sagesse de Salomon; [et] de la part de tous les Rois de la terre qui avaient entendu parler de sa sagesse.