< 1 Kings 3 >

1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
Şi Solomon s-a înrudit prin căsătorie cu Faraon, împăratul Egiptului, şi a luat pe fiica lui Faraon şi a adus-o în cetatea lui David, până avea să termine de zidit casa lui şi casa DOMNULUI şi zidul Ierusalimului de jur împrejur.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
Numai că poporul sacrifica pe înălţimi, deoarece nu era zidită o casă numelui DOMNULUI până în acele zile.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Şi Solomon îl iubea pe DOMNUL, umblând în statutele lui David, tatăl său, numai că sacrifica şi ardea tămâie pe înălţimi.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Şi împăratul a mers la Gabaon pentru a sacrifica acolo, pentru că aceasta era înălţimea cea mare; o mie de ofrande arse a oferit Solomon pe acel altar.
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
La Gabaon, DOMNUL i-a apărut lui Solomon într-un vis noaptea; şi Dumnezeu a spus: Cere ce doreşti să îţi dau.
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
Şi Solomon a spus: Tu ai arătat servitorului tău David, tatăl meu, mare milă, conform umblării lui înaintea ta în adevăr şi în dreptate şi în integritate a inimii faţă de tine; şi ai păstrat pentru el această mare bunătate, că i-ai dat un fiu să şadă pe tronul său, aşa cum este în această zi.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
Şi acum, DOAMNE Dumnezeul meu, tu l-ai făcut pe servitorul tău împărat în locul lui David, tatăl meu; şi eu sunt doar un copil mic; nu ştiu cum să ies sau să intru.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
Şi servitorul tău este în mijlocul poporului tău pe care l-ai ales, un popor mare, care nu poate fi numărat nici socotit din cauza mulţimii lui.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Dă de aceea servitorului tău o inimă care înţelege pentru a judeca pe poporul tău, ca să discern între bine şi rău, pentru că cine poate judeca pe acest mare popor al tău?
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
Şi vorbirea i-a plăcut DOMNULUI, că Solomon a cerut acest lucru.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Şi Dumnezeu i-a spus: Pentru că ai cerut acest lucru şi nu ai cerut pentru tine viaţă lungă, nici nu ai cerut bogăţii pentru tine, nici nu ai cerut viaţa duşmanilor tăi, ci ai cerut pentru tine înţelegere pentru a discerne judecata,
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
Iată, am făcut conform cuvintelor tale; iată, ţi-am dat o inimă înţeleaptă şi care înţelege, astfel încât nu a fost nimeni ca tine înaintea ta, nici nu se va ridica după tine vreunul ca tine.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
Şi ţi-am dat de asemenea ceea ce nu ai cerut: deopotrivă bogăţii şi onoare, astfel încât nu va fi nimeni printre împăraţi ca tine în toate zilele tale.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
Şi dacă vei umbla în căile mele, pentru a păzi statutele mele şi poruncile mele, precum David, tatăl tău, a umblat, atunci îţi voi lungi zilele.
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Şi Solomon s-a trezit; şi, iată, acesta a fost un vis. Şi a venit la Ierusalim şi a stat în picioare înaintea chivotului legământului DOMNULUI şi a oferit ofrande arse şi a oferit ofrande de pace şi a făcut un ospăţ tuturor servitorilor săi.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Atunci au venit acolo două femei curve, la împărat, şi au stat în picioare înaintea lui.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
Şi o femeie a spus: O domnul meu, eu şi femeia aceasta locuiam într-o singură casă; şi eu am născut un copil cu ea în casă.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
Şi s-a întâmplat, a treia zi după ce am născut, că a născut şi această femeie; şi noi eram împreună; nu era niciun străin cu noi în casă, în afară de noi amândouă în casă.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
Şi copilul acestei femei a murit noaptea, pentru că ea s-a culcat pe el.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
Şi ea s-a sculat la miezul nopţii şi a luat pe fiul meu de lângă mine pe când roaba ta dormea şi l-a culcat la sânul ei şi l-a culcat pe copilul ei mort la sânul meu.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
Şi după ce m-am sculat dimineaţa să alăptez pe copilul meu, iată, era mort; dar când m-am uitat atent la el dimineaţa, iată, nu era fiul meu, pe care îl născusem.
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
Şi cealaltă femeie a spus: Ba nu, ci fiul meu este cel viu şi cel mort este fiul tău. Şi aceasta a spus: Nu; ci fiul tău este cel mort şi cel viu este fiul meu. Astfel vorbeau ele înaintea împăratului.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
Atunci a spus împăratul: Una spune: Acesta este fiul meu care trăieşte şi fiul tău este cel mort; şi cealaltă spune: Ba nu; ci fiul tău este cel mort şi fiul meu este cel viu.
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
Şi împăratul a spus: Aduceţi-mi o sabie. Şi au adus o sabie înaintea împăratului.
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Şi împăratul a spus: Tăiaţi pe copilul cel viu în două şi daţi jumătate uneia şi jumătate celeilalte.
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Atunci a vorbit împăratului femeia al căreia era copilul cel viu, pentru că tânjea în adâncurile ei după fiul ei, şi a spus: O domnul meu, dă-i ei copilul cel viu şi nicidecum să nu îl ucizi. Dar cealaltă a spus: Să nu fie nici al meu nici al tău, tăiaţi-l.
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Atunci împăratul a răspuns şi a zis: Daţi-i celei dintâi copilul cel viu şi nicidecum să nu îl ucideţi, ea este mama lui.
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
Şi tot Israelul a auzit de judecata pe care împăratul o judecase; şi s-au temut de împărat, pentru că au văzut că înţelepciunea lui Dumnezeu era în el, pentru a face judecată.

< 1 Kings 3 >