< 1 Kings 3 >
1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
Sógorságot szerze azután Salamon a Faraóval, az Égyiptombeli királylyal; és elvevé a Faraó leányát, és hozá Dávidnak városába, míg elvégezé az ő házának és az Úr házának építését és Jeruzsálemnek kőfalát köröskörül.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
De a nép áldozik vala a magas helyeken; mert nem építtetett vala ház az Úr nevének mind ez ideig.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Szereté pedig Salamon az Urat, járván Dávidnak, az ő atyjának parancsolatiban, kivéve, hogy a magas helyeken áldozott, és ott tömjénezett.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
És mikor Gibeonba ment a király, hogy ott áldozzék, mert ott volt a nagy magaslat, és Salamon azon az oltáron áldozott égőáldozatul ezer barmot:
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
Megjelenék Gibeonban az Úr Salamonnak azon éjjel álmában, és monda az Isten: Kérj, a mit akarsz, hogy adjak néked.
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
És monda Salamon: Te a te szolgáddal, az én atyámmal, Dáviddal nagy irgalmasságot cselekedtél, a miképen ő is járt előtted híven, igazán és hozzád egyenes szívvel, és megtartottad néki ezt a nagy irgalmasságot, hogy néki fiat adtál, a ki az ő királyi székében ül, a mint e mai napon megtetszik.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
És most, óh én Uram Istenem, te tetted a te szolgádat királylyá, Dávid, az én atyám helyett. Én pedig kicsiny gyermek vagyok, nem tudok kimenni és bejönni.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
És a te szolgád a te néped között van, a melyet te magadnak választottál, nagy nép ez, a mely meg nem számláltathatik, meg sem írattathatik a sokaság miatt.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Adj azért a te szolgádnak értelmes szívet, hogy tudja ítélni a te népedet, és tudjon választást tenni a jó és gonosz között; mert kicsoda kormányozhatja ezt a te nagy népedet?
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
És tetszék e beszéd az Úrnak, hogy Salamon ilyen dolgot kért.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Monda azért az Isten néki: Mivelhogy ezt kérted tőlem, és nem kértél magadnak hosszú életet, sem nem kértél gazdagságot, sem pedig nem kérted a te ellenségidnek lelkét; hanem bölcseséget kértél az ítélettételre:
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
Ímé a te beszéded szerint cselekszem, ímé adok néked bölcs és értelmes szívet, úgy hogy hozzád hasonló nem volt te előtted, és utánad sem támad olyan, mint te.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
Sőt még a mit nem kértél, azt is megadom néked, gazdagságot és dicsőséget: úgy hogy a királyok között nem lesz hozzád hasonló senki minden te idődben.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
És ha az én útaimon járándasz, megőrizvén az én végzéseimet és parancsolatimat, a miképen járt a te atyád, Dávid: meghosszabbítom életed idejét.
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
És mikor felserkent Salamon, ímé álom volt. És méne Jeruzsálembe, és álla az Úr szövetségének ládája elé, és áldozék egészen égőáldozatokat, és készíte hálaáldozatokat, és szerze nagy lakomát minden szolgáinak.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Abban az időben jött a királyhoz két parázna asszony, és megálla ő előtte.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
És monda az egyik asszony: Kérlek uram, én és ez az asszony egy házban laktunk, és szültem ő nála abban a házban.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
És harmadnappal az én szülésem után, ez az asszony is szült, és együtt valánk, senki idegen nem volt velünk a házban, hanem csak mi ketten valánk abban a házban.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
És ennek az asszonynak éjszaka meghalt a fia: mert ráfeküdt.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
És felkelt éjfélkor, és elvitte az én fiamat mellőlem, mert a te szolgálóleányod aludt, és azt maga mellé fekteté, míg az ő meghalt fiát én mellém fektette.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
Mikor pedig hajnalban felkeltem, hogy megszoptassam az én fiamat: ímé, megholt; de reggel jól megnézegetvén, látám, hogy az nem az én fiam, a kit én szültem.
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
Monda pedig a másik asszony: Nem úgy van, az én fiam az, a ki él, a te fiad pedig az, a ki meghalt. Amaz viszont monda: Nem, hanem a te fiad az, a ki meghalt, és az én fiam az, a ki él. És ekképen versengettek a király előtt.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
Akkor monda a király: Ez azt mondja: Ez az én fiam, a ki él, és a te fiad az, a ki meghalt; amaz meg ezt mondja: Semmiképen nem, hanem a te fiad az, a ki meghalt, és az én fiam az, a ki él.
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
És monda a király: Hozzatok nékem kardot! És mikor oda hozák a kardot a király elé,
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Monda a király: Vágjátok két részre az eleven gyermeket, és adjátok az egyik részt egyiknek, a másikat pedig a másiknak.
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Ekkor monda az az asszony, a kié vala az élő gyermek, a királynak, mert megindult szíve gyermekén: Kérlek, uram, adjátok néki az élő gyermeket, és ne öljétek meg őt. A másik pedig azt mondja vala. Se enyim, se tied ne legyen; vágjátok ketté.
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Akkor felele a király, és monda: Adjátok amannak az élő gyermeket, és meg ne öljétek azt, mert az az ő anyja.
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
És mikor hallotta az egész Izráel ezt az ítéletet, a melyet tett vala a király, félék a királynak orczáját, mert látták, hogy Isten bölcsesége van az ő szívében az ítélettételre.