< 1 Kings 3 >

1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
HOOHUI ae la o Solomona me Parao ke alii o Aigupita, a lawe ae la oia i ke kaikamahine a Parao, a lawe mai ia ia i ke kulanakauhale o Davida, a paa ia ia kona hale iho, a me ka hale o Iehova, a me ka pa o Ierusalema a puni.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
Mohai aku la nae na kanaka ma na wahi kiekie, no ka mea, aole i kukuluia ka hale no ka inoa o Iehova a hiki ia mau la.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Ua aloha aku no hoi o Solomona ia Iehova, e hele ana ma na kauoha a Davida kona makuakane, mohai aku la nae oia a kuni aku la hoi i ka mea ala ma na wahi kiekie.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Hele aku la ke alii i Gibeona e kaumaha aku malaila, no ka mea, he wahi kiekie nui no hoi ia; hookahi tausani mohaikuni ka Solomona i mohai ai ma kela kuahu.
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
A ma Gibeona i ikeia'ku ai o Iehova e Solomona, ma ka moe uhane i ka po, a olelo mai la ke Akua, E noi mai oe i ka'u mea e haawi aku ai ia oe.
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
I aku la o Solomona, Nui mai la kou lokomaikai i kau kauwa ia Davida ko'u makuakane, e like me kona hele ana imua ou ma ka oiaio, a me ka pololei, a me ke kupono o ka naau ia oe; a ua malama hoi oe i keia lokomaikai nui nona, i kou haawi ana mai i keiki nana e noho maluna o kona nohoalii, me neia i keia la.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
Ano hoi e Iehova ko'u Akua, ua hoolilo mai oe i kau kauwa nei i alii ma kahi o Davida ko'u makuakane: he keiki uuku wale no au: aole ike au i ka hele aku, aole hoi i ka hoi mai.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
A iwaeua konu kau kauwa nei o kou poe kanaka, au i koho mai ai, he lahuikanaka nui aole hiki ke helu, aole e pau i ka heluia no ka lehulehu loa.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Nolaila, e haawi mai oe i naauao i kau kauwa nei e hoomalu i kou poe kanaka, i hiki ia'u ke hookaawale mawaena o ka pono a me ka hewa; no ka mea, owai la ka mea e hiki ia ia ke hooponopono i kou lahuikanaka he nui loa me neia.
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
Pono iho la ka olelo imua o ka Haku, o ko Solomona noi ana i keia mea.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Olelo mai la ke Akua ia ia, No kou noi ana mai i keia mea, aole i noi mai i na la he nui nou, aole hoi i noi mai i waiwai nui nou, aole hoi i noi mai e make kou poe enemi; aka, ua noi mai oe i naauao nou i ike i ka hooponopono;
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
Eia hoi, ua hana no au e like me kau olelo; eia no hoi, ua haawi aku au i ka naau akamai a me ka ike nou, i ole mea i like ai me oe mamua ou, aole hoi mahope aku ou e ku mai ai kekahi e like me oe.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
A ua haawi hou aku au ia oe i ka mea au i noi ole mai ai, i ka waiwai nui, a me ka hanohano, i ole mea like me oe iwaeua o na lii i kou mau la a pau.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
A ina e hele oe ma ko'u mau aoao, a e malama mai i ko'u mau kanawai, a me ka'u mau kauoha, e like me ka hele ana o Davida kou makuakane, alaila e hooloihi aku au i kou mau la.
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Ala ae la o Solomona, aia hoi, he moe uhane. A hele mai la ia i Ierusalema, a ku iho la imua o ka pahuberita o ka Haku, a kaumaha aku la i na mohaikuni, a kaumaha aku la i na mohaihoomalu, a hana hoi ia i ka ahaaina na kana mau kauwa a pau.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Alaila hele mai la na wahine moe kolohe elua i ke alii, a ku mai la laua imua ona.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
A olelo aku la kekahi wahine, E kuu haku, e noho ana maua me keia wahine ma ka hale hookahi, a hanau keiki au me ia iloko o ka hale.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
Eia kekahi, i ke kolu o ka la mahope mai o ko'u hanau ana, hanau mai la keia wahine kekahi; aohe mea e me maua iloko o ka hale, o maua wale no ka iloko o ka hale.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
Make iho la ke keiki a keia wahine i ka po, no ka mea, ua moe ae oia nei maluna ona.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
A ala ae la ia i ka waena o ka po, a lawe aku la i ka'u keiki mai kuu aoao aku, i ka wa i hiamoe ai kau kauwawahine, a hoomoe iho ia ia ma kona poli, a hoomoe mai la hoi i kana keiki make ma ko'u poli.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
A i kuu ala ana i kakahiaka e hanai i kuu keiki i ka waiu, aia hoi, ua make; aka, i ko'u nana ana ia ia i ke ao, aia hoi, aole ia o ka'u keiki a'u i hanau ai.
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
A olelo ae la kekahi wahine, Aole, aka, na'u no ke keiki ola, a nau ke keiki make; a olelo ae keia, Aole, aka, nau ke keiki make, a na'u no hoi ke keiki ola. Pela no i olelo ai ua mau wahine la imua o ke alii.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
I mai la ke alii, ke i mai nei kekahi, Na'u keia keiki ka mea ola, a nau ke keiki make; a ke i mai nei keia, Aole, aka, nau ke keiki make, a na'u no ke keiki ola.
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
Olelo mai la hoi ke alii, E lawe mai i ka pahikaua ia'u. A lawe aku la lakou i ka pahikaua ma ke alo o ke alii.
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Kauoha mai la ke alii, E mahele i ke keiki ola i elua, a e haawi i kekahi hapalua i kekahi, a i kekahi hapalua i kekahi.
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Alaila olelo aku ka wahine nana ke keiki ola i ke alii, no ka mea, ua hu ke aloha o kona naau i kana keiki, i aku la hoi ia, E kuu haku, e haawi i ke keiki ola ia ia nei, aole loa e pepehi ia ia. Aka, olelo mai kela, Aole ia ia'u, aole hoi ia oe, e mahele ae ia ia.
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Kauoha mai la ke alii, i mai la, E haawi aku i ke keiki ola ia ia la, aole loa e hoomake ia ia; oia kona makuwahine.
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
A lohe ae la ka Iseraela a pau i ka hooponopono ana a ke alii i hana'i, a weliweli lakou imua o ke alii; no ka mea, ua ike lakou, o ke akamai o ke Akua ka iloko ona e hooponopono ai.

< 1 Kings 3 >