< 1 Kings 3 >

1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
Nake Solomoni akĩgĩa ngwatanĩro na Firaũni, mũthamaki wa bũrũri wa Misiri, na akĩhikia mwarĩ. Akĩmũrehe itũũra inene rĩa Daudi, nginya rĩrĩa aarĩkirie gwaka nyũmba yake ya ũthamaki, na hekarũ ya Jehova, na rũthingo rũrĩa rwathiũrũrũkĩirie Jerusalemu.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
Na rĩrĩ, andũ no maarutagĩra magongona kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru, tondũ gũtiarĩ hekarũ yaakĩirwo rĩĩtwa rĩa Jehova hĩndĩ ĩyo.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Solomoni nĩonanirie wendo wake kũrĩ Jehova nĩ ũndũ wa gũthiĩ na mĩthiĩre ya kĩrĩra na watho wa ithe Daudi, tiga rĩrĩ, nĩarutagĩra magongona na agacinĩra ũbumba kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Mũthamaki agĩthiĩ Gibeoni kũruta magongona, nĩgũkorwo kũu nĩkuo kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru gwekĩrĩirwo mũno, na Solomoni akĩrutĩra magongona ngiri ĩmwe ma njino kĩgongona-inĩ kĩu.
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
Nakuo kũu Gibeoni Jehova akiumĩrĩra Solomoni ũtukũ kĩroto-inĩ, nake Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Hooya o kĩrĩa gĩothe ũngĩenda ngũhe.”
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
Nake Solomoni agĩcookia atĩrĩ, “Nĩwonirie baba Daudi ndungata yaku ũtugi mũnene, tondũ aarĩ mwĩhokeku harĩ we, na aarĩ mũthingu, na mũrũngĩrĩru ngoro-inĩ. Nĩũthiĩte na mbere kũmuonia ũtugi ũcio mũnene, na nĩũmũheete mũriũ wa gũikarĩra gĩtĩ gĩake kĩa ũnene ũmũthĩ.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
“Na rĩrĩ, Wee Jehova Ngai wakwa nĩũtuĩte ndungata yaku mũthamaki handũ ha baba Daudi. No niĩ ndĩ o mwana mũnini na ndirĩ na ũmenyo wa kũruta wĩra wakwa.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
Ndungata yaku ĩrĩ haha gatagatĩ ka andũ aya wee wĩthuurĩire, nao nĩ andũ aingĩ matangĩgereka na matangĩtarĩka.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Nĩ ũndũ ũcio he ndungata yaku ngoro ĩrĩ na ũmenyo wa gũthamakĩra andũ aku, na gũkũũrana wega na ũũru. Tondũ-rĩ, nũũ ũngĩhota gũthamakĩra andũ aya aku aingĩ ũũ?”
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
Jehova nĩakenire nĩ ũndũ wa Solomoni kũmũũria ũndũ ũcio.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Nĩ ũndũ ũcio Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Kuona ũguo nĩguo wahooya, na ndũnahooya ũingĩhĩrio matukũ ma gũtũũra muoyo, kana ũtonga waku wee mwene, o na kana thũ ciaku iniinwo, no wahooya ũmenyo wa kũrũgamĩrĩra kĩhooto-rĩ,
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
nĩngwĩka o ũguo wahooya. Nĩngũkũhe ngoro ĩ na ũũgĩ na gũkũũrana, nĩguo gũtuĩke atĩ gũtirĩ kwagĩa mũndũ ũngĩ tawe, na gũtirĩ hĩndĩ gũkaagĩa ũngĩ tawe.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
O na ningĩ nĩngũkũhe maũndũ marĩa ũtanahooya, na nĩmo ũtonga hamwe na gĩtĩĩo, nĩgeetha matukũ marĩa mothe ũgũtũũra muoyo, gũtikanagĩe mũthamaki ũngĩ ũiganaine nawe.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
Na ũngĩthiiaga na mĩthiĩre yakwa, na wathĩkagĩre kĩrĩra na watho wakwa, ta ũrĩa thoguo Daudi eekire, nĩngakũhe matukũ maingĩ ma gũtũũra muoyo.”
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo Solomoni agĩũkĩra toro, akĩmenya atĩ kĩu kĩarĩ kĩroto. Agĩcooka Jerusalemu, agĩthiĩ mbere ya ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, na akĩruta igongona rĩa njino na rĩa ngwatanĩro. Ningĩ akĩrugithĩria andũ othe a nyũmba ya mũthamaki iruga.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Thuutha ũcio andũ-a-nja eerĩ a maraya magĩũka kũrĩ mũthamaki, makĩrũgama mbere yake.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
Ũmwe wao akiuga atĩrĩ, “Mwathi wakwa, mũndũ-wa-nja ũyũ na niĩ tũikaraga nyũmba ĩmwe. Na nĩndĩraciarire mwana arĩ ho.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
Mĩthenya ĩtatũ thuutha wa gũciara mwana, mũndũ-wa-nja ũyũ o nake araciara mwana. Tũraarĩ o ithuĩ eerĩ; gũtirarĩ mũndũ ũngĩ thĩinĩ wa nyũmba ĩyo, tiga o ithuĩ ithuerĩ.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
“Ũtukũ-rĩ, mũndũ-wa-nja ũyũ arakomera mwana wake, arakua.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
Nĩ ũndũ ũcio arookĩra ũtukũ gatagatĩ, areheria mwana wakwa harĩ niĩ, rĩrĩa niĩ ndungata yaku ndĩrarĩ toro. Aramũiga gĩthũri-inĩ gĩake, na araiga mũrũwe gĩthũri-inĩ gĩakwa arĩ mũkuũ.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
Rũciinĩ rũrũ rũngĩ, ngĩũkĩra nĩguo nyongithie mwana wakwa, ndĩrona nĩ mũkuũ! No rĩrĩa ndĩramũrorire wega na ũtheri wa rũciinĩ, ndĩrona atĩ ũcio ti mwana ũrĩa ndaciarĩte.”
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
Mũndũ-wa-nja ũcio ũngĩ akiuga atĩrĩ, “Aca! Ũyũ ũrĩ muoyo nĩwe mwana wakwa; ũyũ mũkuũ nĩwe waku.” No ũcio wa mbere akĩrega biũ, akiuga atĩrĩ, “Aca! Ũyũ mũkuũ nĩwe waku, na ũyũ ũrĩ muoyo nĩwe wakwa.” Nĩ ũndũ ũcio magĩkararania mbere ya mũthamaki.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
Mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Ũyũ aroiga atĩrĩ, ‘Mwana wakwa nĩwe ũrĩ muoyo na waku nĩwe mũkuũ,’ o rĩrĩa ũrĩa ũngĩ aroiga atĩrĩ, ‘Aca! Ũyũ mũkuũ nĩwe waku, na wakwa nĩ ũyũ ũrĩ muoyo.’”
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
Ningĩ mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Ndeherai rũhiũ rwa njora.” Nĩ ũndũ ũcio makĩrehera mũthamaki rũhiũ rwa njora.
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Nake agĩathana, akiuga atĩrĩ: “Mwana ũyũ ũrĩ muoyo nĩatinanio maita meerĩ, nuthu ĩheo mũndũ-wa-nja ũmwe, na nuthu ĩyo ĩngĩ ĩheo mũndũ-wa-nja ũcio ũngĩ.”
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Mũndũ-wa-nja ũrĩa mwana wake aarĩ muoyo akĩringwo nĩ tha nĩ ũndũ wa mwana wake, akĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Ndagũthaitha mwathi wakwa, mũnengere mwana ũyũ ũrĩ muoyo, tiga kũmũũraga!” No ũcio ũngĩ akiuga atĩrĩ, “Ndegũtuĩka waku kana wakwa. Nĩatinanio maita meerĩ!”
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Nake mũthamaki agĩtua ciira atĩrĩ, “Nengerai mũndũ-wa-nja ũyũ wa mbere mwana ũyũ ũrĩ muoyo. Mũtikamũũrage; nĩwe nyina.”
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
Rĩrĩa andũ othe a Isiraeli maiguire ũrĩa mũthamaki aatua ciira ũcio, magĩĩtigĩra mũthamaki tondũ nĩmoonire aarĩ na ũũgĩ mũingĩ kuuma kũrĩ Ngai wa gũtua ciira na kĩhooto.

< 1 Kings 3 >