< 1 Kings 3 >

1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
Salomon fit une alliance matrimoniale avec Pharaon, roi d'Égypte. Il prit la fille de Pharaon et l'amena dans la cité de David jusqu'à ce qu'il ait fini de construire sa propre maison, la maison de Yahvé et la muraille autour de Jérusalem.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
Cependant, le peuple sacrifiait sur les hauts lieux, car il n'y avait pas encore de maison construite au nom de Yahvé.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Salomon aimait l'Éternel et suivait les lois de David, son père, sauf qu'il offrait des sacrifices et brûlait des parfums sur les hauts lieux.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Le roi alla à Gabaon pour y sacrifier, car c'était le grand haut lieu. Salomon offrit mille holocaustes sur cet autel.
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
À Gabeon, Yahvé apparut en songe à Salomon, la nuit, et Dieu lui dit: « Demande ce que je dois te donner. »
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
Salomon dit: « Tu as montré à ton serviteur David, mon père, une grande bonté, parce qu'il a marché devant toi dans la vérité, dans la droiture et dans la droiture de cœur avec toi. Tu as gardé pour lui cette grande bonté, en lui donnant un fils pour s'asseoir sur son trône, comme c'est le cas aujourd'hui.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
Maintenant, Yahvé mon Dieu, tu as établi ton serviteur comme roi à la place de David, mon père. Je ne suis qu'un petit enfant. Je ne sais ni sortir ni entrer.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
Ton serviteur est au milieu de ton peuple que tu as choisi, un grand peuple, qui ne peut être ni dénombré ni compté pour la multitude.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Donne donc à ton serviteur un cœur compréhensif pour juger ton peuple, afin que je puisse discerner le bien du mal; car qui est capable de juger ton grand peuple? »
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
Cette demande plut à l'Éternel, car Salomon avait demandé cette chose.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Dieu lui dit: « Parce que tu as demandé cela, et que tu n'as pas demandé pour toi une longue vie, ni la richesse pour toi-même, ni la vie de tes ennemis, mais que tu as demandé pour toi l'intelligence pour discerner la justice,
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
voici, j'ai fait selon ta parole. Voici, je t'ai donné un cœur sage et compréhensif, de sorte qu'il n'y a eu personne comme toi avant toi, et qu'après toi, il n'y aura personne comme toi.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
Je t'ai aussi donné ce que tu n'as pas demandé, la richesse et la gloire, de sorte qu'il n'y aura pas de roi comme toi pendant toute ta vie.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
Si tu marches dans mes voies, pour observer mes lois et mes commandements, comme a marché ton père David, j'allongerai tes jours. »
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Salomon se réveilla; et voici, c'était un rêve. Il vint à Jérusalem, se plaça devant l'arche de l'alliance de Yahvé, offrit des holocaustes et des sacrifices de paix, et fit un festin pour tous ses serviteurs.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Alors deux femmes qui se prostituaient vinrent auprès du roi et se présentèrent devant lui.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
L'une d'elles dit: « Oh, mon seigneur, cette femme et moi habitons dans une même maison. J'ai accouché d'un enfant avec elle dans la maison.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
Le troisième jour après mon accouchement, cette femme a aussi accouché. Nous étions ensemble. Il n'y avait pas d'étranger avec nous dans la maison, seulement nous deux dans la maison.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
L'enfant de cette femme mourut pendant la nuit, parce qu'elle était couchée sur lui.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
Elle s'est levée à minuit, a pris mon fils à côté de moi, pendant que ton serviteur dormait, et l'a mis dans son sein; elle a mis son enfant mort dans mon sein.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
Lorsque je me levai le matin pour allaiter mon enfant, voici qu'il était mort; mais lorsque je l'eus regardé le matin, voici que ce n'était pas mon fils que j'avais porté. »
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
L'autre femme a dit: « Non! Mais celui qui vit est mon fils, et celui qui est mort est ton fils. » Le premier dit: « Non! Mais le mort est ton fils, et le vivant est mon fils. » Ils se disputèrent ainsi devant le roi.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
Alors le roi dit: « L'un dit: C'est mon fils qui vit, et ton fils est le mort; et l'autre dit: Non! Mais ton fils est le mort, et mon fils est le vivant. »
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
Le roi dit: « Apportez-moi une épée. » Ils apportèrent donc une épée devant le roi.
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Le roi dit: « Divisez l'enfant vivant en deux, donnez-en la moitié à l'un et la moitié à l'autre. »
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Alors la femme à qui appartenait l'enfant vivant parla au roi, car son cœur se languissait de son fils, et elle dit: « Oh, mon seigneur, donne-lui l'enfant vivant, et ne le tue en aucun cas! ». Mais l'autre a dit: « Il ne sera ni à moi ni à toi. Divise-le. »
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Le roi répondit: « Donne à la première femme l'enfant vivant, et ne le tue surtout pas. Elle est sa mère. »
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
Tout Israël apprit le jugement que le roi avait rendu, et ils craignirent le roi, car ils virent que la sagesse de Dieu était en lui pour faire justice.

< 1 Kings 3 >