< 1 Kings 22 >
1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
І прожили́ вони три роки, і не було війни між Сирією та між Ізраїлем.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
І сталося третього року, і зійшов Йосафа́т, цар Юдин, до Ізраїлевого царя.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
І сказав Ізраїлів цар до своїх слуг: „Чи ви знаєте, що ґілеадський Рамот — наш? А ми мовчимо́, замість того, щоб забрати його з руки сирійського царя“.
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
І сказав він до Йосафа́та: „Чи ти пі́деш зо мною на війну до ґілеадського Рамоту?“А Йосафа́т відказав: „Я — як ти, народ мій — як народ твій, мої коні — як твої коні!“
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
І сказав Йосафа́т до Ізраїлевого царя: „Вивідай зараз слово Господнє!“
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
І зібрав Ізраїлів цар пророків, близько чотирьох сотень чоловіка, та й сказав до них: „Чи йти мені на війну на ґілеадський Рамот, чи занеха́ти?“А ті відказали: „Іди, а Господь дасть його в цареву руку“.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
І сказав Йосафа́т: „Чи нема тут іще Господнього пророка, — і ви́відаємо від нього“.
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
І сказав Ізраїлів цар до Йосафата: „ Є ще один муж, щоб від нього вивідати Господа. Та я нена́виджу його, бо він не пророкує на мене добре, а тільки зле. Це Міхей, син Їмлин“. А Йосафа́т відказав: „Нехай цар не говорить так!“
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
І покликав Ізраїлів цар одного є́внуха, і сказав: „Приведи скоріш Міхея, Їмлиного сина!“
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
І цар Ізраїлів та цар Юдин сиділи кожен на троні своїм, повби́рані в ша́ти при вході до брами Самарії, а всі пророки пророкували перед ними.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
А Седекія, Кенаанин син, зробив собі залізні ро́ги й сказав: „Так сказав Господь: Оцим будеш побивати сиріян аж до ви́гублення їх!“
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
І всі пророки пророкували так, говорячи: Виходь до ґілеадського Рамоту, і пощастить тобі, — і Господь дасть його в цареву руку“.
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
А той послане́ць, що пішов покликати Міхея, говорив до нього, кажучи: „Ось слова тих пророків, — одноусто звіщають цареві добро. Нехай же буде слово твоє, як слово кожного з них, і ти говори́тимеш добре“.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
І сказав Міхей: „ Як живий Господь, — те, що скаже мені Госпо́дь, я те говоритиму!“
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
І прийшов він до царя, а цар сказав до нього: „Міхе́ю, — чи пі́демо на війну́ до ґілеа́дського Рамо́ту, чи занеха́ємо?“А той відказав йому: „Вийди, і пощастить тобі, — і Господь дасть у цареву руку“.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
І сказав йому цар: „Аж скільки разі́в я заприсягав тебе, що ти не говоритимеш мені нічо́го, тільки правду в Ім'я́ Господа?“
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
А той відказав: „Я бачив усього Ізраїля, розпоро́шеного по гора́х, немов ове́ць, що не мають пастуха́. І сказав Господь: Немає в них пана, — нехай ве́рнуться з миром кожен до дому свого“.
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
І сказав Ізраїлів цар до Йосафа́та: „Чи ж не казав я тобі, — він не буде пророкувати мені доброго, а тільки лихе́?“
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
А Міхей відказав: „Тому́ послухай Господнього слова: Бачив я Господа, що сидів на престолі Своїм, а все небесне ві́йсько стояло при Ньому з прави́ці Його та з ліви́ці Його.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
І сказав Господь: Хто́ намовить Ахава, і він вийде й упаде в ґілеадському Рамоті? І говорив той так, а той говорив так.
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
І вийшов дух, і став перед Господнім лицем та й сказав: Я намо́влю його! І сказав йому Господь: Чим?
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
А той відказав: Я вийду й стану духом неправди в устах усіх його пророків. А Господь сказав: Ти намовиш, а також переможеш; вийди та й зроби так!
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
А тепер оце Господь дав духа неправди в уста всіх оцих пророків, а Господь говорив на тебе лихе́“...
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
І підійшов Седекія, Кенаанин син, і вдарив Міхея по щоці та й сказав: „Кудою це перейшов Дух Господній від мене, щоб говорити з тобою?“
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
А Міхей сказав: „Ось ти побачиш це, коли вбіжиш до найдальшої кімна́ти, щоб схова́тися“.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
І сказав Ізраїлів цар: „Візьми Міхея, і відведи до Амона, начальника міста, та до Йоаша, царевого сина,
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
та й скажеш: Отак сказав цар: Посадіть оцього до в'язни́чного дому, і давайте йому їсти скупо хліба й скупо води, аж поки я не верну́ся з миром“.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
А Міхей відказав: „Якщо справді ве́рнешся ти з миром, то не говорив Господь через мене!“І до того сказав: „Слухайте це, всі наро́ди!“
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
І вийшов Ізраїлів цар та Йосафа́т, цар Юдин, до ґілеадського Рамо́ту.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
І сказав Ізраїлів цар до Йосафата: „Я переберу́ся, і піду́ на бій, а ти вбери свої царські шати!“І перебрався Ізраїлів цар, і пішов на бій.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
А сирійський цар наказав керівника́м своїх колесни́ць, тридцятьом і двом, говорячи: „Не бу́дете воювати з мали́м та з великим, а тільки з самим Ізраїлевим царем“.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
І сталося, як керівники́ колесни́ць побачили Йосафа́та, то вони сказали: „Це дійсно Ізраїлів цар!“І зайшли на нього, щоб воювати, а Йосафа́т закричав.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
І сталося, як керівники́ колесни́ць побачили, що це не Ізраїлів цар, то поверну́ли від нього.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
А один чоловік зне́хотя натягнув лука, та й ударив Ізраїлевого царя між підв'яза́нням пояса та між па́нцерем. А той сказав своєму візникові: „Поверни назад, і виведи мене з табо́ру, бо я ране́ний“...
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
І знявся бій того дня, а цар був поста́влений на колесни́ці проти Сирії, і помер уве́чорі. І кров із рани текла в колесни́цю.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
А як сонце захо́дило, нісся крик у табо́рі такий: „Кожен — до міста свого́, і кожен — до кра́ю свого́!“
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
І помер цар, і був приве́зений до Самарії. І поховали царя в Самарії.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
І полоска́ли колесни́цю над ставом у Самарії, і пси лиза́ли його кров, а блудни́ці мили своє тіло, за словом Господнім, що Він говорив.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
А решта Ахавових діл, і все, що́ він зробив був, і дім зо слоно́вої кости, що він збудував, і всі міста́, які він побудува́в, — отож вони написані в Книзі Хроніки Ізраїлевих царів.
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
І спочив Ахав із батька́ми своїми, а замість нього зацарюва́в син його Ахазія.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
А Йосафа́т, Асин син, зацарював над Юдою в четвертому році Ахава, царя Ізраїлевого.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Йосафат був віку тридцяти й п'яти літ, коли він зацарював, і двадцять і п'ять літ царював в Єрусалимі. А ім'я́ його матері — Азува, дочка́ Шілхи.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
І ходив він усією дорогою батька свого Аси, і не збо́чував із неї, щоб чинити добре в Господніх оча́х. Тільки па́гірки не були пони́щені, — народ іще прино́сив жертви й кадив на па́гірках.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
І Йосафат замирив з Ізраїлевим царем.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
А решта Йосафатових діл та лица́рськість його, що́ він чинив був та як воював, — отож вони написані в Книзі Хроніки Юдиних царів.
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
А решту блудоді́їв, що позостава́лися за днів його батька Аси, він вигубив із Кра́ю.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
А царя не було в Едомі, — був намісник царів.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
А Йосафат наробив був таршіських кораблі́в, щоб піти до Офіру по золото, та не пішов, бо порозбива́лися кораблі при Ецйон-Ґевері.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Тоді сказав Ахазія, син Ахавів, до Йосафата: „Нехай пі́дуть на корабля́х мої раби з рабами твоїми“. Та Йосафат не захотів.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
І спочив Йосафат із своїми батьками. І був він похо́ваний в Місті Давида, свого батька, а замість нього зацарював син його Єгорам.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Ахазія, Ахавів син, зацарював над Ізраїлем у Самарії, в сімнадцятому році Йосафата, Юдиного царя, і царював над Ізраїлем два роки.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
І робив він лихе́ в Господніх оча́х, і ходив дорогою ба́тька свого́ й дорогою своєї матері, та дорогою Єровоама, Неватового сина, що вводив у гріх Ізраїля.
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
І служив він Ваалові, і вклоня́вся йому, та й гніви́в Го́спода, Бога Ізраїлевого, — усе так, як робив його ба́тько.