< 1 Kings 22 >

1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
Şi Siria şi Israel au stat trei ani fără război.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
Şi s-a întâmplat în al treilea an, că Iosafat, împăratul lui Iuda, a coborât la împăratul lui Israel.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
Şi împăratul lui Israel a spus servitorilor săi: Ştiţi că Ramot în Galaad este al nostru şi noi am tăcut şi nu l-am luat din mâna împăratului Siriei?
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
Şi i-a spus lui Iosafat: Vei merge cu mine la luptă la Ramot-Galaad? Şi Iosafat i-a spus împăratului lui Israel: Eu sunt precum tu eşti, poporul meu ca poporul tău, caii mei precum caii tăi.
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Şi Iosafat i-a spus împăratului lui Israel: Întreabă, te rog, cuvântul DOMNULUI astăzi.
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Atunci împăratul lui Israel a adunat pe profeţi, cam patru sute de bărbaţi şi le-a spus: Să merg împotriva Ramot-Galaadului la luptă, sau să îl las în pace? Iar ei au spus: Urcă-te; fiindcă DOMNUL îl va da în mâna împăratului.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Şi Iosafat a spus: Nu mai este aici un profet al DOMNULUI în afară de aceştia, ca să îl întrebăm?
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
Şi împăratul lui Israel i-a spus lui Iosafat: Este încă un bărbat, Micaia, fiul lui Imla, prin care noi putem întreba pe DOMNUL; dar îl urăsc, pentru că nu profeţeşte binele referitor la mine, ci răul. Şi Iosafat a spus: Să nu spună împăratul astfel.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
Atunci împăratul lui Israel a chemat un ofiţer şi a spus: Grăbeşte aici pe Micaia, fiul lui Imla.
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Şi împăratul lui Israel şi Iosafat, împăratul lui Iuda, au şezut fiecare pe tronul său, îmbrăcaţi cu robele lor, într-un loc gol la intrarea porţii Samariei; şi toţi profeţii profeţeau înaintea lor.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
Şi Zedechia, fiul lui Chenaana, îşi făcuse coarne de fier; şi spunea: Astfel spune DOMNUL: Cu acestea vei împunge pe sirieni până îi vei mistui.
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Şi toţi profeţii au profeţit astfel, spunând: Urcă-te la Ramot-Galaad şi prosperă, pentru că DOMNUL îl va da în mâna împăratului.
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
Şi mesagerul care mersese să îl cheme pe Micaia i-a vorbit, spunând: Iată acum, cuvintele profeţilor declară binele împăratului cu o singură gură; să fie cuvântul tău, te rog, ca şi cuvântul unuia dintre ei şi vorbeşte ceea ce este bine.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
Şi Micaia a spus: Precum DOMNUL trăieşte: ce DOMNUL îmi va spune, aceea voi vorbi.
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Astfel el a venit la împărat. Şi împăratul i-a spus: Micaia, să mergem împotriva Ramot-Galaadului la luptă, sau să îl lăsăm în pace? Iar el i-a răspuns: Du-te şi prosperă, pentru că DOMNUL îl va da în mâna împăratului.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Şi împăratul i-a spus: De câte ori să te conjur că nu îmi vei spune decât ce este adevărat în numele DOMNULUI?
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Iar el a spus: Am văzut tot Israelul împrăştiat pe dealuri, ca oi care nu au păstor; şi DOMNUL a zis: Aceştia nu au stăpân; să se întoarcă fiecare om la casa lui în pace.
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
Şi împăratul lui Israel i-a spus lui Iosafat: Nu ţi-am zis eu că nu profeţeşte binele referitor la mine, ci numai răul?
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
Iar el a spus: Ascultă tu de aceea cuvântul DOMNULUI: Am văzut pe DOMNUL şezând pe tronul său şi toată oştirea cerurilor stând în picioare la dreapta lui şi la stânga lui.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
Şi DOMNUL a zis: Cine va convinge pe Ahab să se urce şi să cadă la Ramot-Galaad? Şi unul spunea într-un fel şi un altul spunea într-alt fel.
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
Şi a ieşit un duh şi a stat în picioare înaintea DOMNULUI şi a zis: Eu îl voi convinge.
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Şi DOMNUL i-a spus: Cum? Iar el a zis: Voi ieşi şi voi fi un duh de minciună în gura tuturor profeţilor lui. Iar el a spus: Să îl convingi şi învingi de asemenea; ieşi şi fă astfel.
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
De aceea acum, iată, DOMNUL a pus un duh de minciună în gura tuturor acestor profeţi ai tăi şi DOMNUL a vorbit rău referitor la tine.
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Dar Zedechia, fiul lui Chenaana, s-a apropiat şi a lovit pe Micaia peste obraz şi a spus: Pe ce cale a plecat Duhul DOMNULUI de la mine pentru a-ţi vorbi ţie?
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Şi Micaia a zis: Iată, vei vedea în acea zi când vei intra în camera dinăuntru pentru a te ascunde.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
Şi împăratul lui Israel a spus: Ia pe Micaia şi du-l înapoi la Amon, guvernatorul cetăţii, şi la Ioas, fiul împăratului.
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
Şi să spui: Astfel zice împăratul: Puneţi pe acesta în închisoare şi hrăniţi-l cu pâinea chinuirii şi cu apa chinuirii, până mă întorc în pace.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
Şi Micaia a zis: Dacă te întorci cu adevărat în pace, DOMNUL nu a vorbit prin mine. Şi el a spus: Daţi ascultare, popoarelor, fiecare dintre voi.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
Astfel, împăratul lui Israel şi Iosafat, împăratul lui Iuda, s-au urcat la Ramot-Galaad.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
Şi împăratul lui Israel i-a spus lui Iosafat: Eu mă voi deghiza şi voi intra în bătălie; dar tu îmbracă-te cu robele tale. Şi împăratul lui Israel s-a deghizat şi a mers în bătălie.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
Dar împăratul Siriei poruncise celor treizeci şi două de căpetenii care conduceau carele sale, spunând: Nu vă luptaţi nici cu cel mic nici cu cel mare, în afară numai de împăratul lui Israel.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
Şi s-a întâmplat, când căpeteniile carelor l-au văzut pe Iosafat, că au spus: Negreşit acesta este împăratul lui Israel. Şi s-au abătut pentru a lupta împotriva lui; şi Iosafat a strigat.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
Şi s-a întâmplat, când căpeteniile carelor au priceput că acesta nu era împăratul lui Israel, că s-au întors de la a-l urmări.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
Şi un anumit om a tras cu arcul la întâmplare şi a lovit pe împăratul lui Israel între încheieturile armurii; de aceea el a spus conducătorului carului său: Întoarce-ţi mâna şi scoate-mă din oştire, pentru că sunt rănit.
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
Şi bătălia a crescut în acea zi; şi împăratul a stat în picioare în carul său împotriva sirienilor şi a murit seara; şi sângele curgea din rană în mijlocul carului.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
Şi pe la apusul soarelui s-a făcut o strigare prin toată oştirea, spunând: Fiecare om la cetatea sa şi fiecare om la ţara sa!
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
Astfel împăratul a murit şi a fost adus la Samaria; şi l-au îngropat pe împărat în Samaria.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
Şi unul spăla carul în iazul Samariei; şi câinii au lins sângele său; şi i-au spălat armura; conform cuvântului DOMNULUI pe care îl spusese.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Şi restul faptelor lui Ahab şi tot ce a făcut, şi casa de fildeş pe care a făcut-o, şi toate cetăţile pe care le-a construit, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraţilor lui Israel?
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Astfel, Ahab a adormit cu părinţii săi; şi Ahazia, fiul său, a domnit în locul său.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
Şi Iosafat, fiul lui Asa, a început să domnească peste Iuda în al patrulea an al lui Ahab, împăratul lui Israel.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Iosafat avea treizeci şi cinci de ani când a început să domnească şi a domnit douăzeci şi cinci de ani în Ierusalim. Şi numele mamei lui era Azuba, fiica lui Şilhi.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
Şi el a umblat în toate căile lui Asa, tatăl său; şi nu s-a abătut de la împlinirea lor, făcând ceea ce era drept în ochii DOMNULUI; totuşi înălţimile nu au fost îndepărtate, fiindcă poporul încă oferea şi ardea tămâie pe înălţimi.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
Şi Iosafat a făcut pace cu împăratul lui Israel.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Şi restul faptelor lui Iosafat şi puterea sa pe care a arătat-o şi cum s-a războit, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraţilor lui Iuda?
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
Şi rămăşiţa de sodomiţi, care rămăsese din zilele tatălui său, Asa, a alungat-o din ţară.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
Nu era atunci un împărat în Edom; un guvernator era împărat.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
Iosafat a făcut corăbiile din Tarsis să meargă la Ofir după aur; dar ele nu au mers; căci corăbiile s-au sfărâmat în Eţion-Gheber.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Atunci i-a spus Ahazia, fiul lui Ahab, lui Iosafat: Să meargă servitorii mei cu servitorii tăi în corăbii. Dar Iosafat a refuzat.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Şi Iosafat a adormit cu părinţii săi şi a fost îngropat cu părinţii săi în cetatea lui David, tatăl său; şi Ioram, fiul său, a domnit în locul său.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Ahazia, fiul lui Ahab, a început să domnească peste Israel în Samaria în anul al şaptesprezecelea al lui Iosafat, împăratul lui Iuda, şi a domnit doi ani peste Israel.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
Şi el a făcut ce este rău în ochii DOMNULUI şi a umblat în calea tatălui său şi în calea mamei sale şi în calea lui Ieroboam, fiul lui Nebat, care făcuse pe Israel să păcătuiască;
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Fiindcă a servit lui Baal şi i s-a închinat şi l-a provocat la mânie pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel, conform cu tot ce făcuse tatăl său.

< 1 Kings 22 >