< 1 Kings 22 >

1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
Három évig maradtak úgy, hogy nem volt háború Arám és Izraél között.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
Volt pedig a harmadik évben, lement Jehósáfát; Jehúda királya, Izraél királyához.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
És szólt Izraél királya a szolgáihoz: Tudjátok-e, hogy mienk Bámót-Gileád, mi meg vesztegelünk és nem vesszük azt el Arám királyának kezéből!
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
És szólt Jehósáfáthoz: Elmész-e velem a háborúba Rámót Gileádba? Szólt Jehósáfát Izraél királyához: Én úgy mint te, népem úgy mint a te néped, lovaim úgy mint a te lovaid!
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Majd szólt Jehósáfát Izraél királyához: Kérdezd csak meg az Örökkévaló igéjét.
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Erre összegyűjtötte Izraél királya a prófétákat, mintegy négyszáz embert és szólt hozzájuk: Elmenjek-e háborúba Rámót Gileád ellen vagy abbahagyjam-e? Mondták: Menj föl; adni fogja az Úr a királynak kezébe.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
De mondta Jehósáfát: Nincs-e itt még prófétája az Örökkévalónak, hogy ő tőle kérdezhessük?
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
Szólt Izraél királya Jehósáfáthoz: Még van egy férfiú, akitől megkérdezhetjük az Örökkévalót, de én gyűlölöm őt, mert nem szokott jót prófétálni felőlem, hanem rosszat: Míkhájehú, Jimla fia. Erre szólt Jehósáfát: Ne mondjon ilyent a király.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
Szólított tehát Izraél királya egy udvari tisztet és mondta: Hamar hívd Míkhájehút, Jimla fiát!
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Izraél királya pedig meg Jehósáfát, Jehúda királya ültek, ki-ki a trónján ruhákba öltözve a szérűn, Sómrón kapujának bejáratán és mind a próféták prófétáltak előttük.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
És készített magának Cidkija, Kenáana fia vasszarvakat éa mondta: Így szól az Örökkévaló: Ezekkel döföd le Arámot, míg meg nem semmisíted.
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Mind a próféták is ekképpen prófétáltak, mondván: Vonulj föl Rámót-Gileádba s légy szerencsés, és adja az Örökkévaló a király kezébe.
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
A követ pedig, aki ment hívni Míkhájehút, beszélt hozzá, mondván: Lám csak, a próféták egyhangúlag jót beszéltek a királyhoz, legyen, kérlek, a te szavad mint azok egyikének szava, hogy jót beszélj.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
De mondta Míkhájehú: Él az Örökkévaló, bizony amit majd szól hozzám az Örökkévaló, azt fogom beszélni.
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Erre odament a királyhoz, és szólt hozzá a király: Míkhájehú, elmenjünk-e a háborúba Rámót-Gileád ellen avagy abba hagyjuk? Szólt hozzá: Vonulj föl és légy szerencsés, és adja az Örökkévaló a király kezébe.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Ekkor szólt hozzá a király: Még hányszor eskesselek meg téged, hogy csupán igazat beszélj hozzám az Örökkévaló nevében?
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Mondta: Láttam egész Izraélt elszéledve a hegyeken mint juhok, melyeknek nincs pásztoruk; és szólt az Örökkévaló: nincsen ezeknek uruk, menjenek vissza, kiki a házába békében!
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
Ekkor szólt Izraél királya Jehósáfáthoz: Nemde mondtam neked, nem fog ez rólam jót prófétálni, hanem rosszat!
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
És szólt: Azért halljad az Örökkévaló igéjét. Láttam az Örökkévalót, ülve a trónján és az égnek egész serege áll mellette jobbjáról és baljáról.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
És mondta az Örökkévaló: Ki beszélné rá Achábot, hogy felvonuljon és elessék Rámót-Gileádban? És szólt az egyik így, a másik meg amúgy szólt.
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
Erre kilépett egy szellem, az Örökkévaló elé állt és mondta: Én beszélem rá! És szólt hozzá az Örökkévaló: Mivel?
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Mondta: Kimegyek és leszek hazug szellemmé mind az ő prófétáinak szájában. És mondta: Rá fogod beszélni és győzni is fogsz; menj ki és cselekedjél ekképpen!
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Most tehát íme adott az Örökkévaló hazug szellemet mind e prófétáid szájába, holott az Örökkévaló veszedelmet mondott ki reád.
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Erre odalépett Cidkijáhú Kenáana fia és arcul ütötte Míkhájehút éa mondta: Mely úton szállt el az Örökkévaló szelleme én tőlem, hogy veled beszéljen?
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Mondta Míkhájehú: Ám majd látod ama napon, midőn szobából szobába mész, hogy elrejtőzzél.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
Ekkor szólt Izraél királya: Vedd Míkhájehút és vezesd vissza Ámónhoz, a város nagyjához és Jóáshoz, a király fiához;
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
és mondjad: így szól a király: vessétek ezt a fogházba éa adjatok neki enni szűken kenyeret és szűken vizet, míg megjövök békében.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
Ekkor szólt Míkhájehú: Ha békében vissza fogsz térni, nem az Örökkévaló beszélt általam. És szólt: Halljátok ti népek mind!
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
Fölvonult tehát Izraél királya meg Jehósáfát, Jehúda királya Rámót-Gileádba.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
És szólt Izraél királya Jehósáfáthoz: Elmásítván magamat megyek a harcba, te meg öltsd föl a magad ruháit. És elmásította magát Izraél királya és a harcba ment.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
Arám királya azonban megparancsolta volt az ő szekérhada harminckét vezérének, mondván: Ne harcoljatok kicsinnyel naggyal, hanem egyedül Izraél királyával.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
És volt, amint meglátták a szekérhad vezérei Jehósáfátot, azt mondták: bizony Izraél királya az és odatértek feléje, hogy harcoljanak vele. Ekkor fölsikoltott Jehósáfát.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
És volt, amint látták a szekérhad vezérei, hogy nem Izraél királya az, elfordultak tőle.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
Egy ember pedig jóhiszemben meghúzta az íjat éa találta Izraél királyát a kapcsok és a páncél közt. Erre azt mondta szekérhajtójának: Fordítsd meg kezedet és vigy ki a táborból, mert megsebesültem.
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
És nekihevesedett a harc ama napon, a király pedig állva maradt a kocsiban Arámmal szemben; de este meghalt és ömlött a sebnek vére a kocsi öblébe.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
S naplementekor bejárta a tábort a riadás, mondván: Kiki városába, kiki országába:
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
Meghalt a király, mentek Sómrónba és eltemették a királyt Sómrónban.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
És lemosták a kocsit Sómrón tavánál, akkor fölnyalták a kutyák az ő vérét s a paráznanők abban fürödtek, az Örökkévaló szava szerint, melyet szólt.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Achábnak egyéb dolgai pedig és mind az amit cselekedett, az elefántcsontház, melyet épített, és mind a városok, melyeket épített, hiszen meg vannak írva Izraél királyai történetének könyvében.
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És feküdt Acháb ősei mellé; és király lett helyette fia, Achazjáhú.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
Jehósáfát, Ásza fia pedig király lett Jehúda fölött Acháb, Izraél királya negyedik évében.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Jehósáfát harmincöt éves volt, midőn király lett és huszonöt évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve pedig Azúba, Silchi leánya.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
És járt atyjánal Ászának minden útja szerint, nem tért le arról, cselekedvén azt ami helyes az Örökkévaló szemeiben. Csak a magaslatok nem szűntek meg, a nép még áldozott és füstölögtetett a magaslatokon.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
Békésen élt Jehósáfát Izraél királyával.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Jehósáfát egyéb dolgai pedig és hőstettei, melyeket végzett éa amit harcolt, hiszen meg vannak írva Jehúda királyai történetének könyvében.
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
A szentelt férfiak maradékát pedig, mely megmaradt atyjának, Ászának napjaiban, kipusztította az országból.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
Nem volt király Edómban, helytartó volt a király.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
Jehósáfát Tarsís-hajókat készített, hogy Ófírba menjenek aranyért, de nem mentek, mert összetörtek a hajók Ecjón-Géberben.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Akkor szólt Achazjáhú, Acháb fia Jehósáfáthoz: Menjenek szolgáim a te szolgáiddal a hajókon; de Jehósáfát nem akarta.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És feküdt Jehósáfát ősei mellé és eltemették ősei mellé, őse Dávid városában. És király lett helyette fia, Jehórám.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Achazjáhú, Acháb fia király lett Izraél fölött Sómrónban Jehósáfátnak, Jehúda királyának tizenhetedik évében, és uralkodott Izraél fölött két évig.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
És azt tette, ami rossz az Örökkévaló szemeiben; járt atyja útján és anyja útján és Járobeámnak, Nebát fiának útján, aki vétkezésre indította Izraélt.
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Szolgált a Báalnak és leborult előtte; és bosszantotta az Örökkévalót, Izraél Istenét, mind a szerint, ahogy cselekedett az atyja.

< 1 Kings 22 >