< 1 Kings 22 >

1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
Nebylo pak za tři léta války mezi Syrskými a Izraelskými.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
I stalo se léta třetího, přijel Jozafat král Judský k králi Izraelskému.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
Mluvil pak byl král Izraelský služebníkům svým: Víte-li, že naše bylo Rámot Galád, a my zanedbáváme vzíti ho zase z moci krále Syrského?
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
Pročež řekl Jozafatovi: Potáhneš-li se mnou na vojnu proti Rámot Galád? Odpověděl Jozafat králi Izraelskému: Jako jsem já, tak jsi ty, jako lid můj, tak lid tvůj, jako koni moji, tak koni tvoji.
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Řekl také Jozafat králi Izraelskému: Vzeptej se dnes medle na slovo Hospodinovo.
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
I shromáždil král Izraelský proroků okolo čtyř set mužů a řekl jim: Mám-li táhnouti na vojnu proti Rámot Galád, či tak nechati? I řekli: Táhni, nebo dá je Pán v ruku krále.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Tedy řekl Jozafat: Což není zde již žádného proroka Hospodinova, abychom se ho zeptali?
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
Na to řekl král Izraelský Jozafatovi: Ještěť jest muž jeden, skrze něhož bychom se mohli poraditi s Hospodinem, ale já ho nenávidím, proto že mi dobrého neprorokuje, než zlé, Micheáš syn Jemlův. Ale Jozafat řekl: Nechť tak nemluví král.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
Protož povolav král Izraelský komorníka jednoho, řekl: Přiveď sem rychle Micheáše syna Jemlova.
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
(Mezi tím král Izraelský a Jozafat král Judský, jeden každý na stolici své, odění jsouce rouchem, seděli v placu u vrat brány Samařské, a všickni proroci prorokovali před nimi.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
Sedechiáš pak syn Kenanův udělal sobě byl rohy železné a řekl: Takto praví Hospodin: Těmito trkati budeš Syrské, dokudž nepohubíš jich.
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Takž podobně i jiní všickni proroci prorokovali, řkouce: Jeď do Rámot Galád, a šťastněť se povede; nebo dá je Hospodin v ruku královu.)
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
V tom posel ten, kterýž šel, aby zavolal Micheáše, mluvil jemu, řka: Aj, nyní slova proroků jedněmi ústy předpovídají dobré věci králi. Medle, buď řeč tvá jako řeč kterého z nich, a mluv dobré věci.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
Tedy řekl Micheáš: Živť jest Hospodin, že což mi koli řekne Hospodin, to mluviti budu.
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
A když přišel k králi, řekl jemu král: Micheáši, máme-li jeti na vojnu proti Rámot Galád, či tak nechati? Kterýž řekl jemu: Jeď a šťastněť se povede, nebo dá je Hospodin v ruku krále.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
I řekl jemu král: I kolikrátž tě mám přísahou zavazovati, abys mi nemluvil než pravdu ve jménu Hospodinovu?
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Protož řekl: Viděl jsem všecken lid Izraelský rozptýlený po horách jako ovce, kteréž nemají pastýře; nebo řekl Hospodin: Nemají pána tito, navrať se jeden každý do domu svého v pokoji.
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
I řekl král Izraelský Jozafatovi: Zdaližť jsem neřekl, že mi nebude prorokovati dobrého, ale zlé?
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
Řekl dále: Z té příčiny slyš slovo Hospodinovo: Viděl jsem Hospodina sedícího na stolici své, a všecko vojsko nebeské stojící po pravici jeho i po levici jeho.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
I řekl Hospodin: Kdo oklamá Achaba, aby vytáhl a padl u Rámot Galád? A když pravil ten toto, a jiný pravil jiné,
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
Tožť vyšel jakýsi duch, a postaviv se před Hospodinem, řekl: Já ho oklamám. Hospodin pak řekl jemu: Jakým způsobem?
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Odpověděl: Vyjdu a budu duchem lživým v ústech všech proroků jeho. Kterýžto řekl: Oklamáš a dovedeš toho; vyjdiž a učiň tak.
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Protož, aj, jižtě dal Hospodin ducha lživého v ústa všech proroků tvých těchto, ješto však Hospodin mluvil zlé proti tobě.
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Tedy přistoupiv Sedechiáš syn Kenanův, dal Micheášovi poliček a řekl: Kudyže odšel duch Hospodinův ode mne, aby mluvil tobě?
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Odpověděl Micheáš: Aj, uzříš v ten den, když vejdeš do nejtajnějšího pokoje, abys se skryl.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
I řekl král Izraelský: Jmi Micheáše, a doveď ho k Amonovi knížeti města, a k Joasovi synu královu.
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
A řekneš: Takto praví král: Dejte tohoto do žaláře, a dávejte mu jísti maličko chleba a maličko vody, dokudž se nenavrátím v pokoji.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
Ale Micheáš řekl: Jestliže ty se navrátíš v pokoji, tedyť nemluvil skrze mne Hospodin. Přes to řekl: Slyštež to všickni lidé!
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
A tak táhl král Izraelský, a Jozafat král Judský proti Rámot Galád.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
I řekl král Izraelský Jozafatovi: Změním já se, když půjdu k bitvě, ale ty oblec se v roucho své. I změnil se král Izraelský a jel k bitvě.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
Král pak Syrský přikázal třidcíti dvěma svým hejtmanům nad vozy, a řekl: Nebojujte proti malému ani proti velikému, než proti samému králi Izraelskému.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
I stalo se, když uzřeli hejtmané nad vozy Jozafata, řekli: Jistě král Izraelský jest. I obrátili se proti němu, aby bojovali. Tedy zkřikl Jozafat.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
V tom když uzřeli hejtmané nad vozy, že on není král Izraelský, obrátili se od něho.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
Muž pak jeden střelil z lučiště náhodou, a postřelil krále Izraelského, kdež se pancíř spojuje. Pročež řekl vozkovi svému: Obrať se a vyvez mne z vojska, nebo jsem nemocen.
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
I rozmohla se bitva v ten den. Král pak stál na voze proti Syrským; potom umřel u večer, a tekla krev z rány do vozu.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
I volal biřic po vojště, když již slunce zapadlo, řka: Jeden každý do města svého, a jeden každý do země své navrať se.
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
Umřel tedy král a dovezen jest do Samaří, i pochovali ho v Samaří.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
A když pohřížen byl vůz v rybníku Samařském, střebali psi krev jeho, též když umývali zbroj jeho, vedlé řeči Hospodinovy, kterouž byl mluvil.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Jiné pak věci Achabovy, a cožkoli činil, i jaký dům z kostí slonových vystavěl, i všecka města, kteráž vzdělal, o tom zapsáno jest v knize o králích Izraelských.
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A tak usnul Achab s otci svými, a kraloval Ochoziáš syn jeho místo něho.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
Jozafat pak syn Azy počal kralovati nad Judou léta čtvrtého Achaba, krále Izraelského.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
A byl Jozafat ve třidcíti pěti letech, když počal kralovati, a dvadceti pět let kraloval nad Jeruzalémem, jehož matky jméno bylo Azuba, dcera Silchi.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
I chodil po vší cestě Azy otce svého, aniž se od ní uchýlil, čině, což dobrého bylo před oblíčejem Hospodinovým. Toliko poněvadž výsostí nezkazili, ještě lid obětoval a kadil na těch výsostech.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
Všel také v pokoj král Jozafat s králem Izraelským.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Jiné pak věci Jozafatovy, i síla jeho, kterouž prokazoval a kterouž bojoval, zapsány jsou v knize o králích Judských.
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
Ten ostatky ohyzdných sodomářů, kteříž ještě pozůstali za dnů Azy otce jeho, vyplénil z země.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
Tehdáž nebylo žádného krále v zemi Idumejské, hejtmana měli místo krále.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
I nadělal Jozafat lodí mořských, aby jeli do Ofir pro zlato. Ale nejeli, nebo polámaly se lodí v Aziongaber.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Řekl byl také Ochoziáš syn Achabův Jozafatovi: Nechť jedou služebníci moji s služebníky tvými na lodech. Ale Jozafat nechtěl.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I usnul Jozafat s otci svými, a pochován jest s otci svými v městě Davida otce svého; kraloval pak Joram syn jeho místo něho.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Ochoziáš syn Achabův počal kralovati nad Izraelem v Samaří, léta sedmnáctého Jozafata krále Judského, a kraloval nad Izraelem dvě létě.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
Nebo činil zlé věci před oblíčejem Hospodinovým, a chodil po cestě otce svého a po cestě matky své, i po cestě Jeroboáma syna Nebatova, kterýž přivodil k hřešení lid Izraelský.
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Sloužil také Bálovi a klaněl se jemu, čímž popudil k hněvu Hospodina Boha Izraelského vedlé toho všeho, což činil otec jeho.

< 1 Kings 22 >